< 1 Kings 16 >
1 Then the word of the Lord came to Jehu the son of Hanani against Baasa, saying:
Ó sì ṣe, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jehu ọmọ Hanani wá sí Baaṣa pé,
2 Forasmuch as I have exalted thee out of the dust, and made thee prince over my people Israel, and thou hast walked in the way of Jeroboam, and hast made my people Israel to sin, to provoke me to anger with their sins:
“Èmi ti gbé ọ ga láti inú erùpẹ̀ wá, mo sì fi ọ́ ṣe olórí Israẹli ènìyàn mi, ṣùgbọ́n ìwọ sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu, ó sì mú kí Israẹli ènìyàn mi dẹ́ṣẹ̀, láti mú mi bínú nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
3 Behold, I will cut down the posterity of Baasa, and the posterity of his house, and I will make thy house as the house of Jeroboam the son of Nabat.
Nítorí náà, èmi yóò mú Baaṣa àti ilé rẹ̀ kúrò, èmi yóò sì ṣe ilé rẹ̀ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati.
4 Him that dieth of Baasa in the city, the dogs shall eat: and him that dieth of his in the country, the fowls of the air shall devour.
Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Baaṣa tí ó bá kú ní ìlú, ẹyẹ ojú ọ̀run yóò sì jẹ àwọn tí ó kú ní oko.”
5 But the rest of the acts of Baasa and all that he did, and his battles, are they not written in the book of the words of the days of the kings of Israel?
Àti ìyókù ìṣe Baaṣa, ohun tí ó ṣe àti agbára rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
6 So Baasa slept with his fathers, and was buried in Thersa: and Ela his son reigned in his stead.
Baaṣa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní Tirsa. Ela ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
7 And when the word of the Lord came in the hand of Jehu the son of Hanani the prophet, against Baasa, and against his house, and against all the evil that he had done before the Lord, to provoke him to anger by the works of his hands, to become as the house of Jeroboam: for this cause he slew him, that is to say, Jehu the son of Hanani, the prophet.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì wá nípa ọwọ́ Jehu wòlíì ọmọ Hanani pẹ̀lú sí Baaṣa àti ilé rẹ̀, nítorí gbogbo búburú tí ó ti ṣe níwájú Olúwa, ní mímú un bínú nípa ohun tó ti ṣe àti wíwà bí ilé Jeroboamu, àti nítorí tí ó pa á run pẹ̀lú.
8 In the six and twentieth year of Asa king of Juda, Ela the son of Baasa reigned over Israel in Thersa two years.
Ní ọdún kẹrìndínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Ela ọmọ Baaṣa bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ní Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Tirsa ní ọdún méjì.
9 And his servant Zambri, who was captain of half the horsemen, rebelled against him: now Ela was drinking in Thersa, and drunk in the house of Arsa the governor of Thersa.
Simri, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, olórí ìdajì kẹ̀kẹ́ rẹ̀, dìtẹ̀ sí i. Ela sì wà ní Tirsa nígbà náà, ó sì mu àmupara ní ilé Arsa, ìríjú ilé rẹ̀ ni Tirsa.
10 And Zambri rushing in, struck him and slew him in the seven and twentieth year of Asa king of Juda, and he reigned in his stead.
Simri sì wọlé, ó sì kọlù ú, ó sì pa á ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa, ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
11 And when he was king and sat upon his throne, he slew all the house of Baasa, and he left not one thereof to piss against a wall, and all his kinsfolks and friends.
Bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, bí ó sì ti jókòó lórí ìtẹ́, ó lu gbogbo ilé Baaṣa pa, kò ku ọkùnrin kan sílẹ̀, bóyá ìbátan tàbí ọ̀rẹ́.
12 And Zambri destroyed all the house of Baasa, according to the word of the Lord, that he had spoken to Baasa in the hand of Jehu the prophet,
Bẹ́ẹ̀ ni Simri pa gbogbo ilé Baaṣa run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ sí Baaṣa nípa ọwọ́ Jehu wòlíì:
13 For all the sins of Baasa, and the sins of Ela his son, who sinned, and made Israel to sin, provoking the Lord the God of Israel with their vanities.
nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Baaṣa àti Ela ọmọ rẹ̀ ti ṣẹ̀ àti tí wọ́n ti mú Israẹli ṣẹ̀, tí wọ́n fi mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú, wọ́n mú u bínú nípa òrìṣà asán wọn.
14 But the rest of the acts of Ela, and all that he did, are they not written in the book of the words of the days of the kings of Israel?
Ìyókù ìṣe Ela àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
15 In the seven and twentieth year of Asa king of Juda, Zambri reigned seven days in Thersa: now the army was besieging Gebbethon a city of the Philistines.
Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, ni Simri jẹ ọba ọjọ́ méje ní Tirsa. Àwọn ọmọ-ogun sì dó ti Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini.
16 And when they heard that Zambri had rebelled, and slain the king, all Israel made Amri their king, who was general over Israel in the camp that day.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli tí ó dó tì gbọ́ wí pé Simri ti dìtẹ̀ sí ọba, ó sì ti pa á, wọ́n kéde Omri, olórí ogun, bí ọba lórí Israẹli ní ọjọ́ náà ní ibùdó.
17 And Amri went up, and all Israel with him from Gebbethon, and they besieged Thersa.
Nígbà náà ni Omri àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ kúrò ní Gibetoni, wọ́n sì dó ti Tirsa.
18 And Zambri seeing that the city was about to be taken, went into the palace and burnt himself with the king’s house: and he died
Nígbà tí Simri sì ri pé a ti gba ìlú, ó sì wọ inú ààfin ilé ọba lọ, ó sì tẹ iná bọ ilé ọba lórí ara rẹ̀, ó sì kú,
19 In his sins, which he had sinned, doing evil before the Lord, and walking in the way of Jeroboam, and in his sin, wherewith he made Israel to sin.
nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀, ní ṣíṣe búburú níwájú Olúwa àti ní rírìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣe àti tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
20 But the rest of the acts of Zambri, and of his conspiracy and tyranny, are they not written in the book of the words of the days of the kings of Israel?
Ní ti ìyókù ìṣe Simri, àti ọ̀tẹ̀ rẹ̀ tí ó dì, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
21 Then were the people of Israel divided into two parts: one half of the people followed Thebni the son of Gineth, to make him king: and one half followed Amri.
Nígbà náà ní àwọn ènìyàn Israẹli dá sí méjì; apá kan wọn ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn, láti fi í jẹ ọba, apá kan tókù sì ń tọ Omri lẹ́yìn.
22 But the people that were with Amri, prevailed over the people that followed Thebni the son of Gineth: and Thebni died, and Amri reigned.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tí ń tọ Omri lẹ́yìn borí àwọn tí ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn. Bẹ́ẹ̀ ni Tibni kú, Omri sì jẹ ọba.
23 In the one and thirtieth year of Asa king of Juda, Amri reigned over Israel twelve years: in Thersa he reigned six years.
Ní ọdún kọkànlélọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Omri bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjìlá, ọdún mẹ́fà ní Tirsa.
24 And he bought the hill of Samaria of Semer for two talents of silver: and he built upon it, and he called the city which he built Samaria, after the name of Semer the owner of the hill.
Ó sì ra òkè Samaria lọ́wọ́ Ṣemeri ní tálẹ́ǹtì méjì fàdákà, ó sì kọ́ ìlú sórí rẹ̀, ó sì pe ìlú náà ní Samaria, nípa orúkọ Ṣemeri, orúkọ ẹni tí ó kọ́kọ́ ni òkè náà.
25 And Amri did evil in the sight of the Lord, and acted wickedly above all that were before him.
Ṣùgbọ́n Omri sì ṣe búburú níwájú Olúwa, Ó sì ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
26 And he walked in all the way of Jeroboam the son of Nabat, and in his sins wherewith he made Israel to sin: to provoke the Lord the God of Israel to anger with their vanities.
Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀, láti fi ohun asán wọn mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú.
27 Now the rest of the acts of Amri, and the battles he fought, are they not written in the book of the words of the days of the kings of Israel?
Ìyókù ìṣe àti ohun tí Omri ṣe, àti agbára rẹ tí ó fihàn, a kò ha kọ, wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
28 And Amri slept with his fathers, and was buried in Samaria, and Achab his son reigned in his stead.
Omri sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní Samaria. Ahabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
29 Now Achab the son of Amri reigned over Israel in the eight and thirtieth year of Asa king of Juda. And Achab the son of Amri reigned over Israel in Samaria two and twenty years.
Ní ọdún kejìdínlógójì Asa ọba Juda, Ahabu ọmọ Omri jẹ ọba ní Israẹli, o si jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún méjìlélógún.
30 And Achab the son of Amri did evil in the sight of the Lord above all that were before him.
Ahabu ọmọ Omri sì ṣe búburú ní ojú Olúwa ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
31 Nor was it enough for him to walk in the sins of Jeroboam the son of Nabat: but he also took to wife Jezabel daughter of Ethbaal king of the Sidonians. And he went, and served Baal, and adored him.
Ó sì ṣe bí ẹni pé ó ṣe ohun kékeré fún un láti máa rìn nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, ó sì mú Jesebeli, ọmọbìnrin Etibaali, ọba àwọn ará Sidoni ní aya, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ń sin Baali, ó sì bọ ọ́.
32 And he set up an altar for Baal in the temple of Baal, which he had built in Samaria,
Ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Baali nínú ilé Baali tí ó kọ́ sí Samaria.
33 And he planted a grove: and Achab did more to provoke the Lord the God of Israel, than all the kings of Israel that were before him.
Ahabu sì túnṣe ère òrìṣà Aṣerah, ó sì ṣe púpọ̀ láti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú ju èyí tí gbogbo ọba Israẹli tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ ti ṣe lọ.
34 In his days Hiel of Bethel built Jericho: in Abiram his firstborn he laid its foundations: and in his youngest son Segub he set up the gates thereof: according to the word of the Lord, which he spoke in the hand of Josue the son of Nun.
Ní ìgbà ayé Ahabu, Hieli ará Beteli kọ́ Jeriko. Ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀ ní Abiramu, àkọ́bí rẹ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn ibodè rẹ̀ kọ́ ní Segubu àbíkẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Joṣua ọmọ Nuni sọ.