< Psalms 85 >

1 To the chief Musician. Of the sons of Korah. A Psalm. Thou hast been favourable, Jehovah, unto thy land; thou hast turned the captivity of Jacob:
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, Olúwa; ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.
2 Thou hast forgiven the iniquity of thy people; thou hast covered all their sin. (Selah)
Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. (Sela)
3 Thou hast withdrawn all thy wrath; thou hast turned from the fierceness of thine anger.
Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.
4 Bring us back, O God of our salvation, and cause thine indignation toward us to cease.
Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa, kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.
5 Wilt thou be angry with us for ever? wilt thou draw out thine anger from generation to generation?
Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé? Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?
6 Wilt thou not revive us again, that thy people may rejoice in thee?
Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́, pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?
7 Shew us thy loving-kindness, O Jehovah, and grant us thy salvation.
Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, Olúwa, kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.
8 I will hear what God, Jehovah, will speak; for he will speak peace unto his people, and to his godly ones: but let them not turn again to folly.
Èmi ó gbọ́ ohun tí Olúwa Ọlọ́run yóò wí; ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.
9 Surely his salvation is nigh them that fear him, that glory may dwell in our land.
Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.
10 Loving-kindness and truth are met together; righteousness and peace have kissed each other:
Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀; òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.
11 Truth shall spring out of the earth, and righteousness shall look down from the heavens.
Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.
12 Jehovah also will give what is good, and our land shall yield its increase.
Olúwa yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́, ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.
13 Righteousness shall go before him, and shall set his footsteps on the way.
Òdodo síwájú rẹ lọ o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.

< Psalms 85 >