< Psalms 21 >
1 To the chief Musician. A Psalm of David. The king shall joy in thy strength, Jehovah; and in thy salvation how greatly shall he rejoice.
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Háà! Olúwa, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ, àti ní ìgbàlà rẹ, yóò ti yọ̀ pẹ́ tó!
2 Thou hast given him his heart's desire, and hast not withholden the request of his lips. (Selah)
Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu rẹ̀. (Sela)
3 For thou hast met him with the blessings of goodness; thou hast set a crown of pure gold on his head.
Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà ìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.
4 He asked life of thee; thou gavest [it] him, length of days for ever and ever.
Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un, àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.
5 His glory is great through thy salvation; majesty and splendour hast thou laid upon him.
Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un; ìwọ sì jẹ́ kí iyì ọláńlá rẹ̀ wà lára rẹ.
6 For thou hast made him to be blessings for ever; thou hast filled him with joy by thy countenance.
Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un: ìwọ sì mú inú rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u rẹ̀.
7 For the king confideth in Jehovah: and through the loving-kindness of the Most High he shall not be moved.
Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa; nípasẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá-ògo tí kì í kùnà kì yóò sípò padà.
8 Thy hand shall find out all thine enemies; thy right hand shall find out those that hate thee.
Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí; ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò wá àwọn tí o kórìíra rẹ rí.
9 Thou shalt make them as a fiery furnace in the time of thy presence; Jehovah shall swallow them up in his anger, and the fire shall devour them:
Nígbà tí ìwọ bá yọ ìwọ yóò mú wọn dàbí iná ìléru. Olúwa yóò gbé wọn mì nínú ìbínú rẹ̀, àti pé iná rẹ̀ yóò jó wọn run.
10 Their fruit shalt thou destroy from the earth, and their seed from among the children of men.
Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀, àti irú-ọmọ wọn kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
11 For they intended evil against thee; they imagined a mischievous device, which they could not execute.
Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ wọ́n sì ń pète ìwà ìkà, wọn kì yóò ṣe àṣeyọrí.
12 For thou wilt make them turn their back; thou wilt make ready thy bowstring against their face.
Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà nígbà tí o bá pinnu láti ta wọ́n ní ọfà.
13 Be thou exalted, Jehovah, in thine own strength: we will sing and celebrate thy power.
Gbígbéga ni ọ́ Olúwa, nínú agbára rẹ; a ó kọrin, a ó yín agbára a rẹ̀.