< Joshua 12 >

1 And these are the kings of the land, whom the children of Israel smote, and of whose land they took possession across the Jordan, toward the sun-rising, from the river Arnon to mount Hermon, and all the plain on the east:
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
2 Sihon the king of the Amorites, who dwelt at Heshbon, [and] ruled from Aroer, which is upon the bank of the river Arnon, and from the middle of the ravine, and over half Gilead, as far as the river Jabbok, [which is] the border of the children of Ammon;
Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
3 and the plain as far as the sea of Chinneroth on the east, and as far as the sea of the plain, the salt sea, on the east, toward Beth-jeshimoth; and on the south, under the slopes of Pisgah;
Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
4 and the territory of Og the king of Bashan, of the residue of the giants, who dwelt at Ashtaroth and at Edrei,
Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
5 and ruled over mount Hermon, and over Salcah, and over all Bashan, as far as the border of the Geshurites and the Maachathites, and [over] half Gilead [as far as] the border of Sihon the king of Heshbon.
Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
6 Moses the servant of Jehovah and the children of Israel smote them, and Moses the servant of Jehovah gave it for a possession to the Reubenites, and to the Gadites, and to half the tribe of Manasseh.
Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
7 And these are the kings of the land whom Joshua and the children of Israel smote on this side the Jordan on the west, from Baal-Gad in the valley of Lebanon as far as the smooth mountain, which rises toward Seir. And Joshua gave it to the tribes of Israel for a possession according to their divisions,
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
8 in the mountain, and in the lowland, and in the plain, and on the hill-slopes, and in the wilderness, and in the south: the Hittites, and the Amorites, and the Canaanites, the Perizzites, the Hivites and the Jebusites:
ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
9 The king of Jericho, one; the king of Ai, which is beside Bethel, one;
Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
10 the king of Jerusalem, one; the king of Hebron, one;
ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
11 the king of Jarmuth, one; the king of Lachish, one;
ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
12 the king of Eglon, one; the king of Gezer, one;
ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
13 the king of Debir, one; the king of Geder, one;
ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
14 the king of Hormah, one; the king of Arad, one;
ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
15 the king of Libnah, one; the king of Adullam, one;
ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
16 the king of Makkedah, one; the king of Bethel, one;
ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
17 the king of Tappuah, one; the king of Hepher, one;
ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
18 the king of Aphek, one; the king of Lasharon, one;
ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
19 the king of Madon, one; the king of Hazor, one;
ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
20 the king of Shimron-meron, one; the king of Achshaph, one;
ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
21 the king of Taanach, one; the king of Megiddo, one;
ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
22 the king of Kedesh, one; the king of Jokneam on Carmel, one;
ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
23 the king of Dor in the upland of Dor, one; the king of Goim, at Gilgal, one;
ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
24 the king of Tirzah, one: all the kings thirty and one.
ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.

< Joshua 12 >