< Psalms 132 >
1 A Canticle in steps. O Lord, remember David and all his meekness,
Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
2 how he swore to the Lord, how he made a vow to the God of Jacob:
Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
3 I shall not enter into the tabernacle of my house, nor climb into the bed where I lie down;
Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
4 I shall not give sleep to my eyes, nor slumber to my eyelids
Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
5 and rest to my temples, until I find a place for the Lord, a tabernacle for the God of Jacob.
títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
6 Behold, we heard of it in Ephrathah. We discovered it in the fields of the forest.
Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
7 We will enter into his tabernacle. We will adore in the place where his feet stood.
Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
8 Rise up, O Lord, into your resting place. You and the ark of your sanctification.
Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
9 Let your priests be clothed with justice, and let your saints exult.
Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
10 For the sake of your servant David, do not turn away the face of your Christ.
Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
11 The Lord has sworn the truth to David, and he will not disappoint: I will set upon your throne from the fruit of your lineage.
Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
12 If your sons will keep my covenant and these, my testimonies, which I will teach to them, then their sons will sit upon your throne even forever.
Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
13 For the Lord has chosen Zion. He has chosen it as his dwelling place.
Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
14 This is my resting place, forever and ever. Here I will dwell, for I have chosen it.
Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
15 When blessing, I will bless her widow. I will satisfy her poor with bread.
Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
16 I will clothe her priests with salvation, and her saints will rejoice with great joy.
Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
17 There, I will produce a horn to David. There, I have prepared a lamp for my Christ.
Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
18 I will clothe his enemies with confusion. But my sanctification will flourish over him.
Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.