< Job 40 >
1 And the Lord continued, and he said to Job:
Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
2 Will he who contends with God be so easily silenced? Certainly, he who argues with God must also respond to him.
“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
3 Then Job answered the Lord, saying:
Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
4 What could I possibly answer, since I have been speaking thoughtlessly? I will place my hand over my mouth.
“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
5 One thing I have spoken, which I wish I had not said; and another, to which I will add no more.
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
6 But the Lord, answering Job out of the whirlwind, said:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
7 Gird your waist like a man. I will question you, and you must answer me.
“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
8 Will you make my judgment null and void; and will you condemn me so that you may be justified?
“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
9 And do you have an arm like God, or a voice like thunder?
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
10 Envelop yourself with splendor, and raise yourself up on high, and be glorious, and put on splendid garments.
Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
11 Scatter the arrogant with your wrath, and, when you see all the arrogant, humble them.
Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
12 Look down upon each of the arrogant and confound them, and crush the impious in their place.
Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Hide them in the dust together and plunge their faces into the pit.
Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
14 Then I will confess that your right hand is able to save you.
Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
15 Behold, the behemoth, whom I created along with you, eats hay like an ox.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16 His strength is in his lower back, and his power is in the center of his abdomen.
Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17 He draws up his tail like a cedar; the sinews of his thighs have been drawn together.
Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
18 His bones are like pipes of brass; his cartilage is like plates of iron.
Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19 He is the beginning of the ways of God, who made him; he will use him as his sword.
Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 The mountains bring forth grass for him; all the beasts of the field will play there.
Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
21 He sleeps in the shadows, under the cover of branches, and in moist places.
Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
22 The shadows cover his shadow; the willows of the brook will encircle him.
Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
23 Behold, he will drink a river and not be amazed, and he has confidence that the Jordan could flow into his mouth.
Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
24 He will seize him through his eyes, as if with a hook, and he will bore through his nostrils, as if with stakes.
Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?