< 1 Kings 14 >
1 In that time Abijah, the son of Jeroboam, became ill.
Ní àkókò náà Abijah ọmọ Jeroboamu sì ṣàìsàn,
2 And Jeroboam said to his wife: “Rise up, and change clothing, so that you will not be recognized to be the wife of Jeroboam. And go to Shiloh, where the prophet Ahijah is, who said to me that I should reign over this people.
Jeroboamu sì wí fún aya rẹ̀ pé, “Lọ, sì pa ara rẹ dà, kí wọn kí ó má ba à mọ̀ ọ́n ní aya Jeroboamu. Nígbà náà ni kí o lọ sí Ṣilo. Ahijah wòlíì wà níbẹ̀; ẹni tí ó sọ fún mi pé, èmi yóò jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn yìí.
3 Also, take in your hand ten loaves, and dried bread, and a container of honey, and go to him. For he will reveal to you what will happen to this boy.”
Mú ìṣù àkàrà mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, àti àkàrà wẹ́wẹ́ àti ìgò oyin, kí o sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Òun yóò sì sọ fún ọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọkùnrin náà.”
4 The wife of Jeroboam did just as he had said. And rising up, she went away to Shiloh. And she arrived at the house of Ahijah. But he was unable to see, because his eyes had dimmed due to old age.
Bẹ́ẹ̀ ni aya Jeroboamu sì ṣe bí ó ti wí, ó sì lọ sí ilé Ahijah ní Ṣilo. Ahijah kò sì ríran; ojú rẹ̀ ti fọ́ nítorí ogbó rẹ̀.
5 Then the Lord said to Ahijah: “Behold, the wife of Jeroboam enters, so that she may consult you over her son, who is ill. You shall say one thing and another to her.” Therefore, as she was entering, not presenting herself to be who she was,
Ṣùgbọ́n Olúwa ti sọ fún Ahijah pé, “Kíyèsi i, aya Jeroboamu ń bọ̀ wá béèrè nípa ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí ó ṣàìsàn, báyìí báyìí ni kí ìwọ kí ó wí fún un. Nígbà tí ó bá dé, yóò ṣe ara rẹ̀ bí ẹlòmíràn.”
6 Ahijah heard the sound of her feet, entering through the door. And he said: “Enter, O wife of Jeroboam. Why do you pretend to be someone you are not? But I have been sent to you with harsh news.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí, nígbà tí Ahijah sì gbọ́ ìró ẹsẹ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Wọlé wá, aya Jeroboamu. Kí ló dé tí ìwọ fi ṣe ara rẹ bí ẹlòmíràn? A ti fi iṣẹ́ búburú rán mi sí ọ.
7 Go, and tell Jeroboam: ‘Thus says the Lord, the God of Israel: Although I exalted you from the midst of the people, and I granted to you to be the leader over my people Israel,
Lọ, sọ fún Jeroboamu pé báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi sì gbé ọ ga láti inú àwọn ènìyàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
8 and I tore the kingdom away from the house of David, and I gave it to you, yet you have not been like David, my servant, who kept my commandments, and who followed me with his whole heart, doing what was pleasing in my sight.
Mo fa ìjọba náà ya kúrò ní ilé Dafidi, mo sì fi fún ọ ṣùgbọ́n, ìwọ kò dàbí Dafidi ìránṣẹ́ mi, tí ó pa àṣẹ mi mọ́, tí ó sì tọ̀ mí lẹ́yìn tọkàntọkàn rẹ̀, láti ṣe kìkì èyí tí ó tọ́ ní ojú mi.
9 Instead, you have worked evil beyond all those who were before you. And you have made for yourself strange gods and molten images, so that you provoke me to anger. And you have cast me behind your back.
Ìwọ sì ti ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú rẹ lọ. Ìwọ sì ti ṣe àwọn ọlọ́run mìíràn fún ara rẹ, àwọn òrìṣà tí a gbẹ́; o sì ti mú mi bínú, o sì ti gbé mi sọ sí ẹ̀yìn rẹ.
10 For this reason, behold, I will lead evils over the house of Jeroboam, and I will strike down from Jeroboam that which urinates against a wall, and that which is lame, and that which is last in Israel. And I will cleanse that which remains of the house of Jeroboam, just as dung is usually cleaned away, until there is purity.
“‘Nítorí èyí, Èmi yóò mú ibi wá sí ilé Jeroboamu. Èmi yóò ké gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ Jeroboamu, àti ọmọ ọ̀dọ̀ àti òmìnira ní Israẹli. Èmi yóò mú ilé Jeroboamu kúrò bí ènìyàn ti ń kó ìgbẹ́ kúrò, títí gbogbo rẹ̀ yóò fi tán.
11 Those who will have died of Jeroboam in the city, the dogs will devour them. And those who will have died in the field, the birds of the heavens will devour them. For the Lord has spoken.’
Ajá yóò jẹ ẹni Jeroboamu tí ó bá kú ní ìlú, àti ẹni tí ó bá kú ní igbó ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ. Olúwa ti sọ ọ́!’
12 Therefore, you must rise up, and go to your house. And in the city, at the very entrance of your feet, the boy will die.
“Ní ti ìwọ, padà lọ ilé, nígbà tí o bá sì fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ ìlú, ọmọ náà yóò kú.
13 And all of Israel will mourn him, and will bury him. For he alone of Jeroboam shall be brought into a sepulcher. For concerning him, there has been found a good word from the Lord, the God of Israel, in the house of Jeroboam.
Gbogbo Israẹli yóò sì ṣọ̀fọ̀ fún un, wọn yóò sì sin ín. Òun nìkan ni a ó sì sin nínú ẹni tí ń ṣe ti Jeroboamu, nítorí lọ́dọ̀ rẹ̀ nìkan ni a ti rí ohun rere díẹ̀ sípa Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní ilé Jeroboamu.
14 But the Lord has appointed for himself a king over Israel, who will strike down the house of Jeroboam, in this day and in this time.
“Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fúnra rẹ̀ lórí Israẹli tí yóò ké ilé Jeroboamu kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsin yìí.
15 And the Lord God shall strike Israel, just as a reed is usually shaken in the water. And he will uproot Israel from this good land, which he gave to their fathers. And he will winnow them beyond the river. For they have made for themselves sacred groves, so that they have provoked the Lord.
Olúwa yóò kọlu Israẹli, yóò sì dàbí koríko ti ń mì nínú omi. Yóò sì fa Israẹli tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò Eufurate, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère Aṣerah.
16 And the Lord will hand over Israel, because of the sins of Jeroboam, who has sinned and caused Israel to sin.”
Yóò sì kọ Israẹli sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀.”
17 And so, the wife of Jeroboam rose up, and she went away. And she arrived at Tirzah. And as she was entering the threshold of the house, the boy died.
Nígbà náà ni aya Jeroboamu sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tirsa. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.
18 And they buried him, and all of Israel mourned for him, in accord with the word of the Lord, which he spoke by the hand of his servant Ahijah, the prophet.
Wọ́n sì sin ín, gbogbo Israẹli sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ahijah wòlíì.
19 Now the rest of the words of Jeroboam, the manner in which he fought, and the manner in which he reigned, behold, these were written in the book of the words of the days of the kings of Israel.
Ìyókù ìṣe Jeroboamu, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jẹ ọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli.
20 And the days during which Jeroboam reigned were twenty-two years. And he slept with his fathers. And Nadab, his son, reigned in his place.
Jeroboamu sì jẹ ọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nadabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
21 Now Rehoboam, the son of Solomon, reigned in Judah. Rehoboam was forty-one years old when he had begun to reign. And he reigned for seventeen years in Jerusalem, the city that the Lord chose, out of all the tribes of Israel, so that he might place his name there. And the name of his mother was Naamah, an Ammonite.
Rehoboamu ọmọ Solomoni sì jẹ ọba ní Juda. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní ọdún mọ́kànlélógún ní Jerusalẹmu, ìlú tí Olúwa ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama, ará Ammoni.
22 And Judah did evil in the sight of the Lord, and they provoked him beyond all that their fathers had done, by their sins that they committed.
Juda sì ṣe búburú níwájú Olúwa nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí wọ́n ti dá, wọ́n sì mú u jowú ju gbogbo èyí tí baba wọn ti ṣe lọ.
23 For they, too, built for themselves altars, and statues, and sacred groves, upon every high hill and under every leafy tree.
Wọ́n sì tún kọ́ ibi gíga fún ara wọn, àti ère òkúta àti òpó Aṣerah lórí gbogbo òkè gíga, àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
24 Moreover, the effeminate were in the land, and they committed all the abominations of the peoples that the Lord had destroyed before the face of the sons of Israel.
Àwọn tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà wà ní ilẹ̀ náà, àwọn ènìyàn náà sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde kúrò níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
25 Then, in the fifth year of the reign of Rehoboam, Shishak, the king of Egypt, ascended against Jerusalem.
Ó sì ṣe ní ọdún karùn-ún Rehoboamu, Ṣiṣaki ọba Ejibiti kọlu Jerusalẹmu.
26 And he took away the treasures of the house of the Lord, and the royal treasures, and he plundered everything, including the shields of gold that Solomon had made.
Ó sì kó ìṣúra ilé Olúwa lọ àti ìṣúra ilé ọba. Gbogbo rẹ̀ ni ó kó lọ, pẹ̀lú asà wúrà tí Solomoni ti ṣe.
27 In place of these, king Rehoboam made shields of brass, and he delivered them into the hand of the commanders of the shield bearers, and of those who were keeping the night watch before the gate of the king’s house.
Rehoboamu ọba sì ṣe asà idẹ ní ipò wọn, ó sì fi wọ́n sí ọwọ́ olórí àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlẹ̀kùn ilé ọba.
28 And when the king entered into the house of the Lord, these were carried by those who held the office to go before him. And afterward, they carried them back to the armory of the shield bearers.
Nígbàkígbà tí ọba bá sì lọ sí ilé Olúwa, wọ́n á rù wọ́n, wọ́n á sì mú wọn padà sínú yàrá olùṣọ́.
29 Now the rest of the words of Rehoboam, and all that he did, behold, these were written in the book of the words of the days of the kings of Judah.
Ní ti ìyókù ìṣe Rehoboamu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda bí?
30 And there was war between Rehoboam and Jeroboam, during all the days.
Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní ọjọ́ wọn gbogbo.
31 And Rehoboam slept with his fathers, and he was buried with them in the city of David. And his mother’s name was Naamah, an Ammonite. And his son Abijam reigned in his place.
Rehoboamu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama; ará Ammoni. Abijah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.