< Proverbs 6 >

1 [My] son, if you become surety for your friend, you shall deliver your hand to an enemy.
Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ, bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,
2 For a man's own lips become a strong snare to him, and he is caught with the lips of his own mouth.
bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ, tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté.
3 [My] son, do what I command you, and deliver yourself; for on your friend's account you are come into the power of evil [men]: faint not, but stir up even your friend for whom you are become surety.
Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ: lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀; bẹ aládùúgbò rẹ dáradára.
4 Give not sleep to your eyes, nor slumber with your eyelids;
Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́, tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.
5 that you may deliver yourself as a doe out of the toils, and as a bird out of a snare.
Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ, bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.
6 Go to the ant, O sluggard; and see, and emulate his ways, and become wiser than he.
Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ; kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!
7 For whereas he has no husbandry, nor any one to compel him, and is under no master,
Kò ní olùdarí, kò sí alábojútó tàbí ọba,
8 he prepares food for himself in the summer, and lays by abundant store in harvest. Or go to the bee, and learn how diligent she is, and how earnestly she is engaged in her work; whose labours kings and private men use for health, and she is desired and respected by all: though weak in body, she is advanced by honouring wisdom.
síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.
9 How long will you lie, O sluggard? and when will you awake out of sleep?
Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ? Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?
10 You sleep a little, and you rest a little, and you slumber a short [time], and you fold your arms over your breast a little.
Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀.
11 Then poverty comes upon you as an evil traveller, and lack as a swift courier: but if you be diligent, your harvest shall arrive as a fountain, and poverty shall flee away as a bad courier.
Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà àti àìní bí adigunjalè.
12 A foolish man and a transgressor goes in ways that are not good.
Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú, tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,
13 And the same winks with the eye, and makes a sign with his foot, and teaches with the beckonings of his fingers.
tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò, ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀ ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,
14 [His] perverse heart devises evils: at all times such a one causes troubles to a city.
tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀ ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.
15 Therefore his destruction shall come suddenly; overthrow and irretrievable ruin.
Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn; yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
16 For he rejoices in all things which God hates, and he is ruined by reason of impurity of soul.
Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra, ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i,
17 The eye of the haughty, a tongue unjust, hands shedding the blood of the just;
Ojú ìgbéraga, ahọ́n tó ń parọ́ ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,
18 and a heart devising evil thoughts, and feet hastening to do evil, —[are hateful to God].
ọkàn tí ń pète ohun búburú, ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,
19 An unjust witness kindles falsehoods, and brings on quarrels between brethren.
ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.
20 [My] son, keep the laws of your father, and reject not the ordinances of your mother:
Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́ má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.
21 but bind them upon your soul continually, and hang them as a chain about your neck.
Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.
22 Whenever you walk, lead this along and let it be with you; that it may talk with you when you wake.
Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ; nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ; nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.
23 For the commandment of the law is a lamp and a light; a way of life; reproof also and correction:
Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà, ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀, àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí ni ọ̀nà sí ìyè.
24 to keep you continually from a married woman, and from the calumny of a strange tongue.
Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú, kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.
25 Let not the desire of beauty overcome you, neither be you caught by your eyes, neither be captivated with her eyelids.
Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.
26 For the value of a harlot is as much as of one loaf; and a woman hunts for the precious souls of men.
Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan, ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.
27 Shall any one bind fire in his bosom, and not burn his garments?
Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?
28 or will any one walk on coals of fire, and not burn his feet?
Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná? Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?
29 So is he that goes in to a married woman; he shall not be held guiltless, neither any one that touches her.
Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya; kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.
30 It is not to be wondered at if one should be taken stealing, for he steals that when hungry he may satisfy his soul:
Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.
31 but if he should be taken, he shall repay sevenfold, and shall deliver himself by giving all his goods.
Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.
32 But the adulterer through lack of sense procures destruction to his soul.
Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú; ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni.
33 He endures both pain and disgrace, and his reproach shall never be wiped off.
Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀, ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.
34 For the soul of her husband is full of jealousy: he will not spare in the day of vengeance.
Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè, kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.
35 He will not forego [his] enmity for any ransom: neither will he be reconciled for many gifts.
Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn; yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.

< Proverbs 6 >