< Lamentations 5 >

1 Remember, O Lord, what has happened to us: behold, and look on our reproach.
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Our inheritance has been turned away to aliens, our houses to strangers:
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 we are become orphans, we have no father, our mothers are as widows.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 We have drunk our water for money; our wood is sold to us [for a burden] on our neck:
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 we have been persecuted, we have laboured, we have had no rest.
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 Egypt gave the hand [to us], Assur to their own satisfaction.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Our fathers sinned, [and] are not: we have borne their iniquities.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Servants have ruled over us: there is none to ransom [us] out of their hand.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 We shall bring in our bread with [danger of] our lives, because of the sword of the wilderness.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Our skin is blackened like an oven; they are convulsed, because of the storms of famine.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 They humbled the women in Sion, the virgins in the cities of Juda.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Princes were hanged up by their hands: the elders were not honoured.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 The chosen men lifted up [the voice in] weeping, and the youths fainted under the wood.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 And the elders ceased from the gate, the chosen men ceased from their music.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 The joy of our heart has ceased; our dance is turned into mourning.
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 The crown has fallen [from] our head: yea, woe to us! for we have sinned.
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 For this has grief come; our heart is sorrowful: for this our eyes are darkened.
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 Over the mountain of Sion, because it is made desolate, foxes have walked therein.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 But thou, O Lord, shalt dwell for ever; thy throne [shall endure] to generation and generation.
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 Wherefore wilt thou utterly forget us, and abandon us a long time?
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Turn us, O Lord, to thee, and we shall be turned; and renew our days as before.
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 For thou hast indeed rejected us; thou hast been very wroth against us.
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.

< Lamentations 5 >