< Chronicles I 27 >
1 Now the sons of Israel according to their number, heads of families, captains of thousands and captains of hundreds, and scribes ministering to the king, and for every affair of the king according to [their] divisions, [for] every ordinance of coming in and going out monthly, for all the months of the year, one division of them [was] twenty-four thousand.
Wọ̀nyí ni ìwé àkójọ orúkọ àwọn ọmọ Israẹli, àwọn olórí àwọn ìdílé, àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn ìjòyè wọn. Tí ó n sin ọba nínú gbogbo ohun tí ó kan ìpín àwọn ọmọ-ogun tí ó wà lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn ní oṣooṣù ní gbogbo ọdún. Ìpín kọ̀ọ̀kan jẹ́ ẹgbàá méjìlá ọkùnrin.
2 And over the first division of the first month [was] Isboaz the son of Zabdiel: in his division [were] twenty-four thousand.
Ní ti alákòóso lórí ìpín kìn-ín-ní fún oṣù kìn-ín-ní jẹ́ Jaṣobeamu ọmọ Sabdieli àwọn ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ní ó wà ní abẹ́ ìpín tirẹ̀.
3 Of the sons of Tharez [one] was chief of all the captains of the host for the first month.
Ó jẹ́ ìran ọmọ Peresi àti olóyè fún gbogbo àwọn ìjòyè ológun fún oṣù kìn-ín-ní.
4 And over the division of the second month [was] Dodia the son of Ecchoc, and over his division [was] Makelloth also chief: and in his division [were] twenty and four thousand, chief men of the host.
Alákòóso fún ìpín àwọn ọmọ-ogun fún oṣù kejì jẹ́ Dodai ará Ahohi; Mikloti jẹ́ olórí ìpín tirẹ̀. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
5 The third for the third month [was] Banaias the son of Jodae the chief priest: and in his division [were] twenty and four thousand.
Olórí àwọn ọmọ-ogun ẹlẹ́ẹ̀kẹta fún oṣù kẹta jẹ́ Benaiah ọmọ Jehoiada àlùfáà. Ó jẹ́ olóyè, àwọn ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ní ó wà ní ìpín tirẹ̀.
6 This Banaeas [was] more mighty than the thirty, and over the thirty: and Zabad his son [was] over his division.
Èyí ni Benaiah náà tí ó jẹ́ ọkùnrin ńlá láàrín àwọn ọgbọ̀n àti lórí àwọn ọgbọ̀n. Ọmọ rẹ̀ Amisabadi jẹ́ alákòóso lórí ìpín tirẹ̀.
7 The fourth for the fourth month [was] Asael the brother of Joab, and Zabadias his son, and his brethren: and in his division [were] twenty and four thousand.
Ẹlẹ́ẹ̀kẹrin fún oṣù kẹrin, jẹ́ Asaheli arákùnrin Joabu: ọmọ rẹ̀ Sebadiah jẹ́ arọ́pò rẹ̀. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
8 The fifth chief for the fifth month [was] Samaoth the Jezraite: and in his division [were] twenty and four thousand.
Ẹ̀karùnún fún oṣù karùn-ún, jẹ́ olórí Ṣamhuti ará Israhi. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ní ó wà ní ìpín tirẹ̀.
9 The sixth for the sixth month [was] Hoduias the son of Ekkes the Thecoite: and in his division [were] twenty and four thousand.
Ẹ̀kẹfà fún oṣù kẹfà jẹ́ Ira ọmọ Ikẹsi, ará Tekoi. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
10 The seventh for the seventh month [was] Chelles of Phallus of the children of Ephraim: and in his division [were] twenty and four thousand.
Èkeje fún oṣù keje jẹ́ Helesi ará Peloni, ará Efraimu. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni o wà ní ìpín rẹ̀.
11 The eighth for the eighth month [was] Sobochai the Usathite, [belonging] to Zarai: and in his division [were] twenty and four thousand.
Ẹ̀kẹjọ fún oṣù kẹjọ jẹ́ Sibekai ará Huṣati, ará Sera ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
12 The ninth for the ninth month [was] Abiezer of Anathoth, of the land of Benjamin: and in his division [were] twenty and four thousand.
Ẹ̀kẹsànán fún oṣù kẹsànán jẹ́. Abieseri ará Anatoti, ará Benjamini ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
13 The tenth for the tenth month [was] Meera the Netophathite, [belonging] to Zarai: and in his division [were] twenty and four thousand.
Ẹ̀kẹwàá fún oṣù kẹwàá jẹ́ Maharai ará Netofa, ará Sera ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
14 The eleventh for the eleventh month [was] Banaias of Pharathon, of the sons of Ephraim: and in his division [were] twenty and four thousand.
Ìkọkànlá fún oṣù kọkànlá jẹ́ Benaiah ará Piratoni ará Efraimu ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
15 The twelfth for the twelfth month [was] Choldia the Netophathite, [belonging] to Gothoniel: and in his division [were] twenty and four thousand.
Èkejìlá fún oṣù kejìlá jẹ́ Heldai ará Netofa láti ìdílé Otnieli. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
16 And over the tribes of Israel, the chief for Ruben [was] Eliezer the son of Zechri: for Symeon, Saphatias the son of Maacha:
Àwọn ìjòyè lórí àwọn ẹ̀yà tí Israẹli: lórí àwọn ará Reubeni: Elieseri ọmọ Sikri; lórí àwọn ọmọ Simeoni: Ṣefatia ọmọ Maaka;
17 for Levi, Asabias the son of Camuel: for Aaron, Sadoc:
lórí Lefi: Haṣabiah ọmọ Kemueli; lórí Aaroni: Sadoku;
18 for Juda, Eliab of the brethren of David: for Issachar, Ambri the son of Michael:
lórí Juda: Elihu arákùnrin Dafidi; lórí Isakari: Omri ọmọ Mikaeli;
19 for Zabulon, Samaeas the son of Abdiu: for Nephthali, Jerimoth the son of Oziel:
lórí Sebuluni: Iṣmaiah ọmọ Obadiah; lórí Naftali: Jerimoti ọmọ Asrieli;
20 for Ephraim, Ose the son of Ozia: for the half-tribe of Manasse, Joel the son of Phadaea:
lórí àwọn ará Efraimu: Hosea ọmọ Asasiah; lórí ààbọ̀ ẹ̀yà Manase: Joẹli ọmọ Pedaiah;
21 for the half-tribe of Manasse in the land of Galaad, Jadai the son of Zadaeas, for the sons of Benjamin, Jasiel the son of Abenner:
lórí ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ní Gileadi: Iddo ọmọ Sekariah; lórí Benjamini: Jaasieli ọmọ Abneri;
22 for Dan, Azariel the son of Iroab: these [are] the chiefs of the tribes of Israel.
lórí Dani: Asareeli ọmọ Jerohamu. Wọ̀nyí ni àwọn ìjòyè lórí ẹ̀yà Israẹli.
23 But David took not their number from twenty years old and under: because the Lord said that he would multiply Israel as the stars of the heaven.
Dafidi kò kọ iye àwọn ọkùnrin náà ní ogún ọdún sẹ́yìn tàbí dín nítorí Olúwa ti ṣe ìlérí láti ṣe Israẹli gẹ́gẹ́ bí iye ìràwọ̀ ojú ọ̀run.
24 And Joab the son of Saruia began to number the people, and did not finish the work, for there was hereupon wrath on Israel; and the number was not recorded in the book of the chronicles of king David.
Joabu ọmọ Seruiah bẹ̀rẹ̀ sí ní kà wọ́n, ṣùgbọ́n kò parí kíkà wọ́n nítorí, ìbínú dé sórí àwọn Israẹli nípasẹ̀ kíka iye àti iye náà, a kò kọ ọ́ sínú ìwé ìtàn ayé ti ọba Dafidi.
25 And over the king's treasures [was] Asmoth the son of Odiel; and over the treasures in the country, and in the towns, and in the villages, and in the towers, [was] Jonathan the son of Ozia.
Asmafeti ọmọ Adieli wà ní ìdí ilé ìṣúra ti ọba. Jonatani ọmọ Ussiah wà ní ìdí ilé ìṣúra ní iwájú agbègbè nínú àwọn ìlú, àwọn ìletò àti àwọn ilé ìṣọ́.
26 And over the husbandmen who tilled the ground [was] Esdri the son of Chelub.
Esri ọmọ Kelubu wà ní ìdí àwọn òṣìṣẹ́ lórí pápá, tí wọ́n ń ko ilẹ̀ náà.
27 And over the fields [was] Semei of Rael; and over the treasures of wine in the fields [was] Zabdi the son of Sephni.
Ṣimei ará Ramoti wà ní ìdí àwọn ọgbà àjàrà. Sabdi ará Sifmi wà ní ìdí mímú jáde ti èso àjàrà fún ọpọ́n ńlá tí a ń fi ọ̀tún èso àjàrà sí.
28 And over the oliveyards, and over the sycamores in the plain country [was] Ballanan the Gedorite; and over the stores of oil [was] Joas.
Baali-Hanani ará Gederi wà ní ìdí olifi àti àwọn igi sikamore ní apá ìhà ìwọ̀-oòrùn àwọn ní ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀. Joaṣi wà ní ìdí fífún ni ní òróró olifi.
29 And over the oxen pasturing in Saron [was] Satrai the Saronite; and over the oxen in the valleys [was] Sophat the son of Adli.
Ṣitrai ará Ṣaroni wà ní ìdí fífi ọwọ́ ẹran jẹ oko ní Ṣaroni. Ṣafati ọmọ Adlai wà ní ìdí àwọn ọ̀wọ́ ẹran ní àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀.
30 And over the camels [was] Abias the Ismaelite; and over the asses [was] Jadias of Merathon.
Obili ará Iṣmaeli wà ní ìdí àwọn ìbákasẹ. Jehdeiah ará Meronoti wà ní ìdí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
31 And over the sheep [was] Jaziz the Agarite. All these [were] superintendents of the substance of king David.
Jasisi ará Hagari wà ní ìdí àwọn agbo ẹran. Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn oníṣẹ́ tí wọ́n wà ní ìdí ẹrù ọba Dafidi.
32 And Jonathan, David's uncle by the father's side, [was] a counsellor, a wise man: and Jeel the son of Achami [was] with the king's sons.
Jonatani, arákùnrin Dafidi jẹ́ olùdámọ̀ràn, ọkùnrin onímọ̀ àti akọ̀wé. Jehieli ọmọ Hakmoni bojútó àwọn ọmọ ọba.
33 Achitophel [was] the king's counsellor: and Chusi the chief friend of the king.
Ahitofeli jẹ́ olùdámọ̀ràn ọba. Huṣai ará Arki jẹ́ ọ̀rẹ́ ọba.
34 And after this Achitophel Jodae the son of Banaeas [came] next, and Abiathar: and Joab [was] the king's commander-in-chief.
(Jehoiada ọmọ Benaiah àti nípasẹ̀ Abiatari jẹ ọba rọ́pò Ahitofeli.) Joabu jẹ́ olórí ọmọ-ogun ọba.