< Psalms 46 >

1 For the choirmaster. Of the sons of Korah. According to Alamoth. A song. God is our refuge and strength, an ever-present help in times of trouble.
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Gẹ́gẹ́ bí ti alamoti. Orin. Ọlọ́run ni ààbò àti agbára wa ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ ní ìgbà ìpọ́njú.
2 Therefore we will not fear, though the earth is transformed and the mountains are toppled into the depths of the seas,
Nítorí náà àwa kì yóò bẹ̀rù, bí a tilẹ̀ ṣí ayé ní ìdí, tí òkè sì ṣubú sínú Òkun.
3 though their waters roar and foam and the mountains quake in the surge.
Tí omi rẹ̀ tilẹ̀ ń hó tí ó sì ń mì tí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ń mì pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀. (Sela)
4 There is a river whose streams delight the city of God, the holy place where the Most High dwells.
Odò ńlá kan wà tí ṣíṣàn rẹ̀ mú inú ìlú Ọlọ́run dùn, ibi mímọ́, níbi ti Ọ̀gá-ògo ń gbé.
5 God is within her; she will not be moved. God will help her when morning dawns.
Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀, kò ní yẹ̀: Ọlọ́run yóò ràn án lọ́wọ́ ní kùtùkùtù òwúrọ̀.
6 Nations rage, kingdoms crumble; the earth melts when He lifts His voice.
Àwọn orílẹ̀-èdè ń bínú, àwọn ilẹ̀ ọba ṣubú, ó gbé ohun rẹ̀ sókè, ayé yọ̀.
7 The LORD of Hosts is with us; the God of Jacob is our fortress.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa, Ọlọ́run Jakọbu ni ààbò wa.
8 Come, see the works of the LORD, who brings devastation upon the earth.
Ẹ wá wo iṣẹ́ Olúwa irú ahoro tí ó ṣe ní ayé.
9 He makes wars to cease throughout the earth; He breaks the bow and shatters the spear; He burns the shields in the fire.
O mú ọ̀tẹ̀ tán de òpin ilẹ̀ ayé ó ṣẹ́ ọrun, ó sì gé ọ̀kọ̀ sí méjì ó fi kẹ̀kẹ́ ogun jóná.
10 “Be still and know that I am God; I will be exalted among the nations, I will be exalted over the earth.”
Ẹ dúró jẹ́ẹ́, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ní Ọlọ́run. A ó gbé mi ga nínú àwọn orílẹ̀-èdè, a ó gbé mi ga ní ayé.
11 The LORD of Hosts is with us; the God of Jacob is our fortress.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa; Ọlọ́run Jakọbu sì ni ààbò wa.

< Psalms 46 >