< Psalms 29 >

1 A Psalm of David. Ascribe to the LORD, O heavenly beings, ascribe to the LORD glory and strength.
Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
2 Ascribe to the LORD the glory due His name; worship the LORD in the splendor of His holiness.
Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
3 The voice of the LORD is over the waters; the God of glory thunders; the LORD is heard over many waters.
Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
4 The voice of the LORD is powerful; the voice of the LORD is majestic.
Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
5 The voice of the LORD breaks the cedars; the LORD shatters the cedars of Lebanon.
Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
6 He makes Lebanon skip like a calf, and Sirion like a young wild ox.
Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
7 The voice of the LORD strikes with flames of fire.
Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
8 The voice of the LORD shakes the wilderness; the LORD shakes the Wilderness of Kadesh.
Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
9 The voice of the LORD twists the oaks and strips the forests bare. And in His temple all cry, “Glory!”
Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
10 The LORD sits enthroned over the flood; the LORD is enthroned as King forever.
Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
11 The LORD gives His people strength; the LORD blesses His people with peace.
Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.

< Psalms 29 >