< Psalms 118 >
1 Give thanks to the LORD, for He is good; His loving devotion endures forever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
2 Let Israel say, “His loving devotion endures forever.”
Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
3 Let the house of Aaron say, “His loving devotion endures forever.”
Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
4 Let those who fear the LORD say, “His loving devotion endures forever.”
Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
5 In my distress I called to the LORD, and He answered and set me free.
Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
6 The LORD is on my side; I will not be afraid. What can man do to me?
Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
7 The LORD is on my side; He is my helper. Therefore I will look in triumph on those who hate me.
Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
8 It is better to take refuge in the LORD than to trust in man.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
9 It is better to take refuge in the LORD than to trust in princes.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
10 All the nations surrounded me, but in the name of the LORD I cut them off.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
11 They surrounded me on every side, but in the name of the LORD I cut them off.
Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
12 They swarmed around me like bees, but they were extinguished like burning thorns; in the name of the LORD I cut them off.
Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
13 I was pushed so hard I was falling, but the LORD helped me.
Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
14 The LORD is my strength and my song, and He has become my salvation.
Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
15 Shouts of joy and salvation resound in the tents of the righteous: “The right hand of the LORD performs with valor!
Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
16 The right hand of the LORD is exalted! The right hand of the LORD performs with valor!”
Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
17 I will not die, but I will live and proclaim what the LORD has done.
Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
18 The LORD disciplined me severely, but He has not given me over to death.
Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
19 Open to me the gates of righteousness, that I may enter and give thanks to the LORD.
Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
20 This is the gate of the LORD; the righteous shall enter through it.
Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
21 I will give You thanks, for You have answered me, and You have become my salvation.
Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
22 The stone the builders rejected has become the cornerstone.
Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
23 This is from the LORD, and it is marvelous in our eyes.
Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
24 This is the day that the LORD has made; we will rejoice and be glad in it.
Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
25 O LORD, save us, we pray. We beseech You, O LORD, cause us to prosper!
Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
26 Blessed is he who comes in the name of the LORD. From the house of the LORD we bless you.
Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
27 The LORD is God; He has made His light to shine upon us. Bind the festal sacrifice with cords to the horns of the altar.
Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
28 You are my God, and I will give You thanks. You are my God, and I will exalt You.
Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
29 Give thanks to the LORD, for He is good; His loving devotion endures forever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.