< Psalms 111 >

1 Hallelujah! I will give thanks to the LORD with all my heart in the council of the upright and in the assembly.
Ẹ máa yin Olúwa. Èmi yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi, ní àwùjọ àwọn olóòtítọ́, àti ní ìjọ ènìyàn.
2 Great are the works of the LORD; they are pondered by all who delight in them.
Iṣẹ́ Olúwa tóbi, àwọn tí ó ní inú dídùn, ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀.
3 Splendid and majestic is His work; His righteousness endures forever.
Iṣẹ́ rẹ̀ ni ọláńlá àti ògo: àti òdodo rẹ̀ dúró láéláé.
4 He has caused His wonders to be remembered; the LORD is gracious and compassionate.
Ó ti ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, láti máa rántí: Olúwa ni olóore-ọ̀fẹ́ àti pé ó kún fún àánú.
5 He provides food for those who fear Him; He remembers His covenant forever.
Ó ti fi oúnjẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀: òun ń rántí májẹ̀mú rẹ̀.
6 He has shown His people the power of His works by giving them the inheritance of the nations.
Ó ti fihan àwọn ènìyàn rẹ̀ agbára iṣẹ́ rẹ̀ láti fún wọn ní ilẹ̀ ìlérí ní ìní.
7 The works of His hands are truth and justice; all His precepts are trustworthy.
Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ jẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; gbogbo òfin rẹ̀ sì dájú.
8 They are upheld forever and ever, enacted in truth and uprightness.
Wọ́n dúró láé àti láé, ní òtítọ́ àti òdodo ni a ṣe wọ́n.
9 He has sent redemption to His people; He has ordained His covenant forever; holy and awesome is His name.
Ó rán ìràpadà sí àwọn ènìyàn rẹ̀: ó pàṣẹ májẹ̀mú rẹ̀ títí láé, mímọ́ àti ọ̀wọ̀ ni orúkọ rẹ̀.
10 The fear of the LORD is the beginning of wisdom; all who follow His precepts gain rich understanding. His praise endures forever!
Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìpilẹ̀ṣẹ̀ ọgbọ́n: òye dáradára ni yóò máa ṣe òfin rẹ̀, ìyìn rẹ̀ dúró láé.

< Psalms 111 >