< Proverbs 8 >

1 Does not wisdom call out, and understanding raise her voice?
Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta? Òye kò ha ń gbé ohùn rẹ sókè?
2 On the heights overlooking the road, at the crossroads she takes her stand.
Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ní ìkóríta, ní ó dúró;
3 Beside the gates to the city, at the entrances she cries out:
ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú, ní ẹnu ibodè ni ó ń kígbe sókè:
4 “To you, O men, I call out, and my cry is to the sons of men.
“Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè; mo gbé ohun mi sókè sí gbogbo ènìyàn.
5 O simple ones, learn to be shrewd; O fools, gain understanding.
Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n; ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹ gba òye.
6 Listen, for I speak of noble things, and the opening of my lips will reveal right.
Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye; Èmí ṣí ètè mi láti sọ ohun tí ó tọ́,
7 For my mouth will speak the truth, and wickedness is detestable to my lips.
ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́, nítorí ètè mi kórìíra ibi.
8 All the words of my mouth are righteous; none are crooked or perverse.
Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́, kò sí èyí tí ó jẹ́ ẹ̀tàn tàbí àyídáyidà níbẹ̀.
9 They are all plain to the discerning, and upright to those who find knowledge.
Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà; wọ́n jẹ́ aláìlẹ́gàn fún gbogbo ẹni tí ó ní ìmọ̀.
10 Receive my instruction instead of silver, and knowledge rather than pure gold.
Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà, ìmọ̀ dípò o wúrà àṣàyàn,
11 For wisdom is more precious than rubies, and nothing you desire compares with her.
nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ, kò sí ohun tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ tí a sì le fiwé e.
12 I, wisdom, dwell together with prudence, and I find knowledge and discretion.
“Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye; mo ní ìmọ̀ àti ọgbọ́n-inú.
13 To fear the LORD is to hate evil; I hate arrogant pride, evil conduct, and perverse speech.
Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi mo kórìíra ìgbéraga àti agídí, ìwà ibi àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
14 Counsel and sound judgment are mine; I have insight and strength.
Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi mo ní òye àti agbára.
15 By me kings reign, and rulers enact just laws;
Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso tí àwọn aláṣẹ sì ń ṣe òfin tí ó dára.
16 By me princes rule, and all nobles who govern justly.
Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso, àti gbogbo ọlọ́lá tí ń ṣàkóso ilẹ̀ ayé.
17 I love those who love me, and those who seek me early shall find me.
Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi, àwọn tí ó sì wá mi rí mi.
18 With me are riches and honor, enduring wealth and righteousness.
Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà, ọrọ̀ tí í tọ́jọ́ àti ìgbéga rere.
19 My fruit is better than gold, pure gold, and my harvest surpasses choice silver.
Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ; ohun tí mò ń mú wá ju àṣàyàn fàdákà lọ.
20 I walk in the way of righteousness, along the paths of justice,
Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo, ní ojú ọ̀nà òtítọ́,
21 bestowing wealth on those who love me and making their treasuries full.
mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi mo sì ń mú kí ilé ìṣúra wọn kún.
22 The LORD created me as His first course, before His works of old.
“Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀. Ṣáájú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àtijọ́;
23 From everlasting I was established, from the beginning, before the earth began.
a ti yàn mí láti ayérayé, láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ayé tó bẹ̀rẹ̀.
24 When there were no watery depths, I was brought forth, when no springs were overflowing with water.
Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi, nígbà tí kò tí ì sí ìsun tí ó ní omi nínú;
25 Before the mountains were settled, before the hills, I was brought forth,
kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn, ṣáájú àwọn òkè ni a ti bí mi,
26 before He made the land or fields, or any of the dust of the earth.
kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀ tàbí èyíkéyìí nínú eruku ayé.
27 I was there when He established the heavens, when He inscribed a circle on the face of the deep,
Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn, nígbà tí ó fi òsùwọ̀n àyíká sórí ibú omi,
28 when He established the clouds above, when the fountains of the deep gushed forth,
nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè tí ó sì fi orísun ibú omi sí ipò rẹ̀ láì le è yẹsẹ̀,
29 when He set a boundary for the sea, so that the waters would not surpass His command, when He marked out the foundations of the earth.
nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun kí omi má ba à kọjá ààlà àṣẹ rẹ̀, àti nígbà tí ó pààlà ìpìlẹ̀ ayé.
30 Then I was a skilled craftsman at His side, and His delight day by day, rejoicing always in His presence.
Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ mo kún fún inú dídùn lójoojúmọ́, mo ń yọ̀ nígbà gbogbo níwájú rẹ̀.
31 I was rejoicing in His whole world, delighting together in the sons of men.
Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá mo sì ní inú dídùn sí àwọn ọmọ ènìyàn.
32 Now therefore, my sons, listen to me, for blessed are those who keep my ways.
“Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi, ìbùkún ni fún àwọn tí ó pa ọ̀nà mi mọ́.
33 Listen to instruction and be wise; do not ignore it.
Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n; má ṣe pa á tì sápá kan.
34 Blessed is the man who listens to me, watching daily at my doors, waiting at the posts of my doorway.
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi, tí ń ṣọ́nà ní ẹnu-ọ̀nà mi lójoojúmọ́, tí ń dúró ní ẹnu-ọ̀nà mi.
35 For whoever finds me finds life and obtains the favor of the LORD.
Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè ó sì rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa.
36 But he who fails to find me harms himself; all who hate me love death.”
Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára gbogbo ẹni tí ó kórìíra mi fẹ́ ikú.”

< Proverbs 8 >