< Lamentations 3 >

1 I am the man who has seen affliction under the rod of God’s wrath.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 He has driven me away and made me walk in darkness instead of light.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Indeed, He keeps turning His hand against me all day long.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 He has worn away my flesh and skin; He has shattered my bones.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 He has besieged me and surrounded me with bitterness and hardship.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 He has made me dwell in darkness like those dead for ages.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 He has walled me in so I cannot escape; He has weighed me down with chains.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Even when I cry out and plead for help, He shuts out my prayer.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 He has barred my ways with cut stones; He has made my paths crooked.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 He is a bear lying in wait, a lion hiding in ambush.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 He forced me off my path and tore me to pieces; He left me without help.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 He bent His bow and set me as the target for His arrow.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 He pierced my kidneys with His arrows.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 I am a laughingstock to all my people; they mock me in song all day long.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 He has filled me with bitterness; He has intoxicated me with wormwood.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 He has ground my teeth with gravel and trampled me in the dust.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 My soul has been deprived of peace; I have forgotten what prosperity is.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 So I say, “My strength has perished, along with my hope from the LORD.”
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Remember my affliction and wandering, the wormwood and the gall.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Surely my soul remembers and is humbled within me.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Yet I call this to mind, and therefore I have hope:
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 Because of the loving devotion of the LORD we are not consumed, for His mercies never fail.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 They are new every morning; great is Your faithfulness!
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 “The LORD is my portion,” says my soul, “therefore I will hope in Him.”
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 The LORD is good to those who wait for Him, to the soul who seeks Him.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 It is good to wait quietly for the salvation of the LORD.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 It is good for a man to bear the yoke while he is still young.
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Let him sit alone in silence, for God has disciplined him.
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Let him bury his face in the dust— perhaps there is still hope.
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Let him offer his cheek to the one who would strike him; let him be filled with reproach.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 For the Lord will not cast us off forever.
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Even if He causes grief, He will show compassion according to His abundant loving devotion.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 For He does not willingly afflict or grieve the sons of men.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 To crush underfoot all the prisoners of the land,
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 to deny a man justice before the Most High,
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 to subvert a man in his lawsuit— of these the Lord does not approve.
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Who has spoken and it came to pass, unless the Lord has ordained it?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Do not both adversity and good come from the mouth of the Most High?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Why should any mortal man complain, in view of his sins?
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Let us examine and test our ways, and turn back to the LORD.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Let us lift up our hearts and hands to God in heaven:
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 “We have sinned and rebelled; You have not forgiven.”
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 You have covered Yourself in anger and pursued us; You have killed without pity.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 You have covered Yourself with a cloud that no prayer can pass through.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 You have made us scum and refuse among the nations.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 All our enemies open their mouths against us.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Panic and pitfall have come upon us— devastation and destruction.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Streams of tears flow from my eyes over the destruction of the daughter of my people.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 My eyes overflow unceasingly, without relief,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 until the LORD looks down from heaven and sees.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 My eyes bring grief to my soul because of all the daughters of my city.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Without cause my enemies hunted me like a bird.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 They dropped me alive into a pit and cast stones upon me.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 The waters flowed over my head, and I thought I was going to die.
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 I called on Your name, O LORD, out of the depths of the Pit.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 You heard my plea: “Do not ignore my cry for relief.”
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 You drew near when I called on You; You said, “Do not be afraid.”
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 You defend my cause, O Lord; You redeem my life.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 You have seen, O LORD, the wrong done to me; vindicate my cause!
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 You have seen all their malice, all their plots against me.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 O LORD, You have heard their insults, all their plots against me—
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 the slander and murmuring of my assailants against me all day long.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 When they sit and when they rise, see how they mock me in song.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 You will pay them back what they deserve, O LORD, according to the work of their hands.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Put a veil of anguish over their hearts; may Your curse be upon them!
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 You will pursue them in anger and exterminate them from under Your heavens, O LORD.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

< Lamentations 3 >