< Job 28 >

1 “Surely there is a mine for silver and a place where gold is refined.
Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
2 Iron is taken from the earth, and copper is smelted from ore.
Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin, bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
3 Man puts an end to the darkness; he probes the farthest recesses for ore in deepest darkness.
Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn, ó sì ṣe àwárí ìṣúra láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
4 Far from human habitation he cuts a shaft in places forgotten by the foot of man. Far from men he dangles and sways.
Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè, àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
5 Food may come from the earth, but from below it is transformed as by fire.
Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá, àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná;
6 Its rocks are the source of sapphires, containing flecks of gold.
òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta safire, o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
7 No bird of prey knows that path; no falcon’s eye has seen it.
Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojú gúnnugún kò rí i rí.
8 Proud beasts have never trodden it; no lion has ever prowled over it.
Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
9 The miner strikes the flint; he overturns mountains at their base.
Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
10 He hews out channels in the rocks, and his eyes spot every treasure.
Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta, ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
11 He stops up the sources of the streams to bring what is hidden to light.
Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya, ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
12 But where can wisdom be found, and where does understanding dwell?
Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?
13 No man can know its value, nor is it found in the land of the living.
Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
14 The ocean depths say, ‘It is not in me,’ while the sea declares, ‘It is not with me.’
Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”; omi òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
15 It cannot be bought with gold, nor can its price be weighed out in silver.
A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
16 It cannot be valued in the gold of Ophir, in precious onyx or sapphire.
A kò le è fi wúrà Ofiri, tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta safire díye lé e.
17 Neither gold nor crystal can compare to it, nor jewels of fine gold be exchanged for it.
Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
18 Coral and quartz are unworthy of mention; the price of wisdom is beyond rubies.
A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi; iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
19 Topaz from Cush cannot compare to it, nor can it be valued in pure gold.
Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
20 From where then does wisdom come, and where does understanding dwell?
Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá? Tàbí níbo ni òye ń gbé?
21 It is hidden from the eyes of every living thing and concealed from the birds of the air.
A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo, ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
22 Abaddon and Death say, ‘We have heard a rumor about it.’
Ibi ìparun àti ikú wí pé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
23 But God understands its way, and He knows its place.
Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
24 For He looks to the ends of the earth and sees everything under the heavens.
Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
25 When God fixed the weight of the wind and measured out the waters,
láti dà òsùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fi òsùwọ̀n wọ́n omi.
26 when He set a limit for the rain and a path for the thunderbolt,
Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò, tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
27 then He looked at wisdom and appraised it; He established it and searched it out.
nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde; ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
28 And He said to man, ‘Behold, the fear of the Lord, that is wisdom, and to turn away from evil is understanding.’”
Àti fún ènìyàn ni ó wí pé, “Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”

< Job 28 >