< Job 19 >

1 Then Job answered:
Ìgbà náà ni Jobu dáhùn, ó sì wí pé:
2 “How long will you torment me and crush me with your words?
“Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin ó fi máa fi ìyà jẹ mí, tí ẹ̀yin ó fi máa fi ọ̀rọ̀ yìí?
3 Ten times now you have reproached me; you shamelessly mistreat me.
Ìgbà mẹ́wàá ní yin yọ mi lénu ẹ̀yin ti ń gàn mí; ojú kò tì yín tí ẹ fi jẹ mí ní yà.
4 Even if I have truly gone astray, my error concerns me alone.
Kí a sì wí bẹ́ẹ̀ pé, mo ṣìnà nítòótọ́, ìṣìnà mi wà lára èmi tìkára mi.
5 If indeed you would exalt yourselves above me and use my disgrace against me,
Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ̀yin ó ṣògo si mi lórí nítòótọ́, tí ẹ ó sì máa fi ẹ̀gàn mi gún mí lójú,
6 then understand that it is God who has wronged me and drawn His net around me.
kí ẹ mọ̀ nísinsin yìí pé, Ọlọ́run ni ó bì mí ṣubú, ó sì nà àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.
7 Though I cry out, ‘Violence!’ I get no response; though I call for help, there is no justice.
“Kíyèsi, èmi ń kígbe pe, ‘Ọwọ́ alágbára!’ Ṣùgbọ́n a kò gbọ́ ti èmi; mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ìdájọ́.
8 He has blocked my way so I cannot pass; He has veiled my paths with darkness.
Ó ṣọgbà dí ọ̀nà mi tí èmi kò le è kọjá, Ó sì mú òkùnkùn ṣú sí ipa ọ̀nà mi.
9 He has stripped me of my honor and removed the crown from my head.
Ó ti bọ́ ògo mi, ó sì ṣí adé kúrò ní orí mi.
10 He tears me down on every side until I am gone; He uproots my hope like a tree.
Ó ti bà mí jẹ́ ní ìhà gbogbo, ẹ̀mí sì pin; ìrètí mi ni a ó sì fàtu bí igi.
11 His anger burns against me, and He counts me among His enemies.
Ó sì tiná bọ ìbínú rẹ̀ sí mi, ó sì kà mí sí bí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀tá rẹ̀.
12 His troops advance together; they construct a ramp against me and encamp around my tent.
Ẹgbẹ́ ogun rẹ̀ sì dàpọ̀ sí mi, wọ́n sì mọ odi yí mi ká, wọ́n sì yí àgọ́ mi ká.
13 He has removed my brothers from me; my acquaintances have abandoned me.
“Ó mú àwọn arákùnrin mi jìnà sí mi réré, àti àwọn ojúlùmọ̀ mi di àjèjì sí mi pátápátá.
14 My kinsmen have failed me, and my friends have forgotten me.
Àwọn alájọbí mi fàsẹ́yìn, àwọn ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi sì di onígbàgbé mi.
15 My guests and maidservants count me as a stranger; I am a foreigner in their sight.
Àwọn ará inú ilé mi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi kà mí sí àjèjì; èmi jásí àjèjì ènìyàn ní ojú wọn.
16 I call for my servant, but he does not answer, though I implore him with my own mouth.
Mo pe ìránṣẹ́ mi, òun kò sì dá mi lóhùn; mo fi ẹnu mi bẹ̀ ẹ́.
17 My breath is repulsive to my wife, and I am loathsome to my own family.
Ẹ̀mí mi ṣú àyà mi, àti òórùn mi ṣú àwọn ọmọ inú ìyá mi.
18 Even little boys scorn me; when I appear, they deride me.
Àní àwọn ọmọdékùnrin fi mí ṣẹ̀sín, mo dìde, wọ́n sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi.
19 All my best friends despise me, and those I love have turned against me.
Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi kórìíra mi, àwọn olùfẹ́ mi sì kẹ̀yìndà mí.
20 My skin and flesh cling to my bones; I have escaped by the skin of my teeth.
Egungun mi lẹ̀ mọ́ ara mi àti mọ́ ẹran-ara mi, mo sì yọ́ pẹ̀lú awọ eyín mi.
21 Have pity on me, my friends, have pity, for the hand of God has struck me.
“Ẹ ṣàánú fún mi, ẹ ṣàánú fún mi, ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, nítorí ọwọ́ Ọlọ́run ti bà mí.
22 Why do you persecute me as God does? Will you never get enough of my flesh?
Nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe lépa mi bí Ọlọ́run, tí ẹran-ara mi kò tẹ́ yín lọ́rùn?
23 I wish that my words were recorded and inscribed in a book,
“Háà! Ìbá ṣe pé a le kọ̀wé ọ̀rọ̀ mi nísinsin yìí, ìbá ṣe pé a le kọ ọ sínú ìwé!
24 by an iron stylus on lead, or chiseled in stone forever.
Kí a fi kálámù irin àti ti òjé kọ wọ́n sínú àpáta fún láéláé.
25 But I know that my Redeemer lives, and in the end He will stand upon the earth.
Nítorí èmi mọ̀ pé olùdáǹdè mi ń bẹ láààyè àti pe òun ni yóò dìde dúró lórí ilẹ̀ ní ìkẹyìn;
26 Even after my skin has been destroyed, yet in my flesh I will see God.
àti lẹ́yìn ìgbà tí a pa àwọ̀ ara mi run, síbẹ̀ láìsí ẹran-ara mi ni èmi ó rí Ọlọ́run,
27 I will see Him for myself; my eyes will behold Him, and not as a stranger. How my heart yearns within me!
ẹni tí èmi ó rí fún ara mi, tí ojú mi ó sì wo, kì sì í ṣe ti ẹlòmíràn; ọkàn mi sì dákú ní inú mi.
28 If you say, ‘Let us persecute him, since the root of the matter lies with him,’
“Bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa ó ti lépa rẹ̀ tó! Àti pé, gbogbo ọ̀rọ̀ náà ni a sá à rí ní ọwọ́ rẹ̀,’
29 then you should fear the sword yourselves, because wrath brings punishment by the sword, so that you may know there is a judgment.”
kí ẹ̀yin kí ó bẹ̀rù, nítorí ìbínú ní í mú ìjìyà wá nípa idà, kí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé ìdájọ́ kan ń bẹ.”

< Job 19 >