< Psalms 92 >
1 A Psalm, a Song for the sabbath day. It is a good thing to give thanks unto Jehovah, And to sing praises unto thy name, O Most High;
Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
2 To show forth thy lovingkindness in the morning, And thy faithfulness every night,
láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
3 With an instrument of ten strings, and with the psaltery; With a solemn sound upon the harp.
lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
4 For thou, Jehovah, hast made me glad through thy work: I will triumph in the works of thy hands.
Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
5 How great are thy works, O Jehovah! Thy thoughts are very deep.
Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
6 A brutish man knoweth not; Neither doth a fool understand this:
Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
7 When the wicked spring as the grass, And when all the workers of iniquity do flourish; It is that they shall be destroyed for ever.
nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
8 But thou, O Jehovah, art on high for evermore.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
9 For, lo, thine enemies, O Jehovah, For, lo, thine enemies shall perish; All the workers of iniquity shall be scattered.
Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
10 But my horn hast thou exalted like [the horn of] the wild-ox: I am anointed with fresh oil.
Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
11 Mine eye also hath seen [my desire] on mine enemies, Mine ears have heard [my desire] of the evil-doers that rise up against me.
Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
12 The righteous shall flourish like the palm-tree: He shall grow like a cedar in Lebanon.
Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
13 They are planted in the house of Jehovah; They shall flourish in the courts of our God.
tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
14 They shall still bring forth fruit in old age; They shall be full of sap and green:
Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
15 To show that Jehovah is upright; He is my rock, and there is no unrighteousness in him.
láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”