< Job 6 >
1 Then Job answered and said,
Jobu sì dáhùn ó si wí pé,
2 Oh that my vexation were but weighed, And all my calamity laid in the balances!
“Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òsùwọ̀n, kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òsùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!
3 For now it would be heavier than the sand of the seas: Therefore have my words been rash.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn òkun lọ, nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé.
4 For the arrows of the Almighty are within me, The poison whereof my spirit drinketh up: The terrors of God do set themselves in array against me.
Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú, oró èyí tí ọkàn mi mú; ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.
5 Doth the wild ass bray when he hath grass? Or loweth the ox over his fodder?
Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko, tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀?
6 Can that which hath no savor be eaten without salt? Or is there any taste in the white of an egg?
A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀, tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin?
7 My soul refuseth to touch [them]; They are as loathsome food to me.
Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò, òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀.
8 Oh that I might have my request; And that God would grant [me] the thing that I long for!
“Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà; àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.
9 Even that it would please God to crush me; That he would let loose his hand, and cut me off!
Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run, tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.
10 And be it still my consolation, Yea, let me exult in pain that spareth not, That I have not denied the words of the Holy One.
Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀, àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí: nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.
11 What is my strength, that I should wait? And what is mine end, that I should be patient?
“Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí? Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?
12 Is my strength the strength of stones? Or is my flesh of brass?
Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí? Ẹran-ara mi í ṣe idẹ?
13 Is it not that I have no help in me, And that wisdom is driven quite from me?
Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi: ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?
14 To him that is ready to faint kindness [should be showed] from his friend; Even to him that forsaketh the fear of the Almighty.
“Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá, kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódùmarè sílẹ̀?
15 My brethren have dealt deceitfully as a brook, As the channel of brooks that pass away;
Àwọn ará mi dàbí odò tí kò ṣe gbẹ́kẹ̀lé bí ìṣàn omi odò, wọ́n sàn kọjá lọ.
16 Which are black by reason of the ice, [And] wherein the snow hideth itself:
Tí ó dúdú nítorí omi dídì, àti níbi tí yìnyín dídì gbé di yíyọ́.
17 What time they wax warm, they vanish; When it is hot, they are consumed out of their place.
Nígbàkígbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ sàn lọ, nígbà tí oòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.
18 The caravans [that travel] by the way of them turn aside; They go up into the waste, and perish.
Àwọn oníṣòwò yà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.
19 The caravans of Tema looked, The companies of Sheba waited for them.
Ẹgbẹ́ oníṣòwò Tema ń wá omi, àwọn oníṣòwò Ṣeba ń dúró dè wọ́n ní ìrètí.
20 They were put to shame because they had hoped; They came thither, and were confounded.
Wọ́n káàárẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e; wọ́n dé bẹ̀, wọ́n sì dààmú.
21 For now ye are nothing; Ye see a terror, and are afraid.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin dàbí wọn; ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.
22 Did I say, Give unto me? Or, Offer a present for me of your substance?
Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá, tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?
23 Or, Deliver me from the adversary’s hand? Or, Redeem me from the hand of the oppressors?
Tàbí, ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni, tàbí, ẹ rà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì’?
24 Teach me, and I will hold my peace; And cause me to understand wherein I have erred.
“Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́ kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti ṣìnà.
25 How forcible are words of uprightness! But your reproof, what doth it reprove?
Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tó ṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbáwí yín jásí?
26 Do ye think to reprove words, Seeing that the speeches of one that is desperate are as wind?
Ẹ̀yin ṣè bí ẹ tún ọ̀rọ̀ mi ṣe àti ohùn ẹnu tí ó dàbí afẹ́fẹ́ ṣe àárẹ̀.
27 Yea, ye would cast [lots] upon the fatherless, And make merchandise of your friend.
Àní ẹ̀yin ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìní baba, ẹ̀yin sì da iye lé ọ̀rẹ́ yín.
28 Now therefore be pleased to look upon me; For surely I shall not lie to your face.
“Nítorí náà, kí èyí kí ó tó fún yín. Ẹ má wò mi! Nítorí pé ó hàn gbangba pé, ní ojú yín ni èmi kì yóò ṣèké.
29 Return, I pray you, let there be no injustice; Yea, return again, my cause is righteous.
Èmi ń bẹ̀ yín, ẹ padà, kí ó má sì ṣe jásí ẹ̀ṣẹ̀; àní, ẹ sì tún padà, àre mi ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ yìí.
30 Is there injustice on my tongue? Cannot my taste discern mischievous things?
Àìṣedéédéé ha wà ní ahọ́n mi? Ǹjẹ́ ìtọ́wò ẹnu mi kò kúkú le mọ ohun ti ó burú jù?