< Genesis 36 >
1 Now these are the generations of Esau (the same is Edom).
Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
2 Esau took his wives of the daughters of Canaan: Adah the daughter of Elon the Hittite, and Oholibamah the daughter of Anah, the daughter of Zibeon the Hivite,
Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
3 and Basemath Ishmael’s daughter, sister of Nebaioth.
Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
4 And Adah bare to Esau Eliphaz; and Basemath bare Reuel;
Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
5 and Oholibamah bare Jeush, and Jalam, and Korah: these are the sons of Esau, that were born unto him in the land of Canaan.
Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
6 And Esau took his wives, and his sons, and his daughters, and all the souls of his house, and his cattle, and all his beasts, and all his possessions, which he had gathered in the land of Canaan; and went into a land away from his brother Jacob.
Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
7 For their substance was too great for them to dwell together; and the land of their sojournings could not bear them because of their cattle.
Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
8 And Esau dwelt in mount Seir: Esau is Edom.
Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
9 And these are the generations of Esau the father of the Edomites in mount Seir:
Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
10 these are the names of Esau’s sons: Eliphaz the son of Adah the wife of Esau, Reuel the son of Basemath the wife of Esau.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
11 And the sons of Eliphaz were Teman, Omar, Zepho, and Gatam, and Kenaz.
Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
12 And Timna was concubine to Eliphaz Esau’s son; and she bare to Eliphaz Amalek: these are the sons of Adah, Esau’s wife.
Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
13 And these are the sons of Reuel: Nahath, and Zerah, Shammah, and Mizzah: these were the sons of Basemath, Esau’s wife.
Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
14 And these were the sons of Oholibamah the daughter of Anah, the daughter of Zibeon, Esau’s wife: and she bare to Esau Jeush, and Jalam, and Korah.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
15 These are the chiefs of the sons of Esau: the sons of Eliphaz the first-born of Esau: chief Teman, chief Omar, chief Zepho, chief Kenaz,
Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
16 chief Korah, chief Gatam, chief Amalek: these are the chiefs that came of Eliphaz in the land of Edom; these are the sons of Adah.
Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
17 And these are the sons of Reuel, Esau’s son: chief Nahath, chief Zerah, chief Shammah, chief Mizzah: these are the chiefs that came of Reuel in the land of Edom; these are the sons of Basemath, Esau’s wife.
Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
18 And these are the sons of Oholibamah, Esau’s wife: chief Jeush, chief Jalam, chief Korah: these are the chiefs that came of Oholibamah the daughter of Anah, Esau’s wife.
Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
19 These are the sons of Esau, and these are their chiefs: the same is Edom.
Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
20 These are the sons of Seir the Horite, the inhabitants of the land: Lotan and Shobal and Zibeon and Anah,
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
21 and Dishon and Ezer and Dishan: these are the chiefs that came of the Horites, the children of Seir in the land of Edom.
Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
22 And the children of Lotan were Hori and Heman; and Lotan’s sister was Timna.
Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
23 And these are the children of Shobal: Alvan and Manahath and Ebal, Shepho and Onam.
Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
24 And these are the children of Zibeon: Aiah and Anah; this is Anah who found the hot springs in the wilderness, as he fed the asses of Zibeon his father.
Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
25 And these are the children of Anah: Dishon and Oholibamah the daughter of Anah.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
26 And these are the children of Dishon: Hemdan and Eshban and Ithran and Cheran.
Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
27 These are the children of Ezer: Bilhan and Zaavan and Akan.
Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
28 These are the children of Dishan: Uz and Aran.
Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
29 These are the chiefs that came of the Horites: chief Lotan, chief Shobal, chief Zibeon, chief Anah,
Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
30 chief Dishon, chief Ezer, chief Dishan: these are the chiefs that came of the Horites, according to their chiefs in the land of Seir.
Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
31 And these are the kings that reigned in the land of Edom, before there reigned any king over the children of Israel.
Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
32 And Bela the son of Beor reigned in Edom; and the name of his city was Dinhabah.
Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
33 And Bela died, and Jobab the son of Zerah of Bozrah reigned in his stead.
Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
34 And Jobab died, and Husham of the land of the Temanites reigned in his stead.
Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
35 And Husham died, and Hadad the son of Bedad, who smote Midian in the field of Moab, reigned in his stead: and the name of his city was Avith.
Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
36 And Hadad died, and Samlah of Masrekah reigned in his stead.
Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
37 And Samlah died, and Shaul of Rehoboth by the River reigned in his stead.
Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
38 And Shaul died, and Baal-hanan the son of Achbor reigned in his stead.
Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
39 And Baal-hanan the son of Achbor died, and Hadar reigned in his stead: and the name of his city was Pau; and his wife’s name was Mehetabel, the daughter of Matred, the daughter of Me-zahab.
Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
40 And these are the names of the chiefs that came of Esau, according to their families, after their places, by their names: chief Timna, chief Alvah, chief Jetheth,
Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
41 chief Oholibamah, chief Elah, chief Pinon,
Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
42 chief Kenaz, chief Teman, chief Mibzar,
baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
43 chief Magdiel, chief Iram: these are the chiefs of Edom, according to their habitations in the land of their possession. This is Esau, the father of the Edomites.
Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.