< Numbers 3 >
1 Now these are the generations of Aaron and Moses in the day that Jehovah spoke with Moses in mount Sinai:
Ìwọ̀nyí ni ìdílé Aaroni àti Mose ní ìgbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní òkè Sinai.
2 And these are the names of the sons of Aaron: Nadab the firstborn, and Abihu, Eleazar, and Ithamar.
Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni nìwọ̀nyí, Nadabu ni àkọ́bí, Abihu, Eleasari àti Itamari.
3 These are the names of the sons of Aaron, the priests who were anointed, whom he consecrated to minister in the priest's office.
Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni ni ìwọ̀nyí, àwọn àlùfáà tí a fi òróró yàn, àwọn tí a fi joyè àlùfáà láti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
4 And Nadab and Abihu died before Jehovah when they offered strange fire before Jehovah in the wilderness of Sinai, and they had no sons. And Eleazar and Ithamar ministered in the priest's office in the presence of Aaron their father.
Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu ti kú níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n rú iná àjèjì níwájú Olúwa nínú ijù Sinai, àwọn méjèèjì kò sì ní ọmọ. Báyìí Eleasari àti Itamari ló ṣiṣẹ́ àlùfáà nígbà ayé Aaroni baba wọn.
5 And Jehovah spoke to Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
6 Bring the tribe of Levi near, and set them before Aaron the priest, that they may minister to him.
“Kó ẹ̀yà Lefi wá, kí o sì fà wọ́n fún Aaroni àlùfáà láti máa ràn án lọ́wọ́.
7 And they shall keep his charge, and the charge of the whole congregation before the tent of meeting, to do the service of the tabernacle.
Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní àgọ́ ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́.
8 And they shall keep all the furniture of the tent of meeting, and the charge of the sons of Israel, to do the service of the tabernacle.
Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú àgọ́ ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Israẹli nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́.
9 And thou shall give the Levites to Aaron and to his sons. They are wholly given to him on the behalf of the sons of Israel.
Fi ẹ̀yà Lefi jì Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn nìkan ni a fi fún Aaroni nínú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli.
10 And thou shall appoint Aaron and his sons, and they shall keep their priesthood. And the stranger who comes near shall be put to death.
Kí o sì yan Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ àlùfáà; àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ pípa ni kí ẹ pa á.”
11 And Jehovah spoke to Moses, saying,
Olúwa tún sọ fún Mose pé,
12 And I, behold, I have taken the Levites from among the sons of Israel instead of all the firstborn who opens the womb among the sons of Israel. And the Levites shall be mine,
“Báyìí èmi fúnra mi ti mú ẹ̀yà Lefi láàrín àwọn ọmọ Israẹli dípò gbogbo àkọ́bí ọkùnrin àwọn ọmọbìnrin Israẹli. Ti èmi ni àwọn ọmọ Lefi,
13 for all the firstborn are mine. On the day that I smote all the firstborn in the land of Egypt I hallowed to me all the firstborn in Israel, both man and beast. They shall be mine. I am Jehovah.
nítorí pé ti èmi ni gbogbo àkọ́bí. Ní ọjọ́ tí mo pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti ya gbogbo àkọ́bí sọ́tọ̀ ní Israẹli yálà ti ènìyàn tàbí ti ẹranko. Gbogbo wọn gbọdọ̀ jẹ́ ti èmi. Èmi ni Olúwa.”
14 And Jehovah spoke to Moses in the wilderness of Sinai, saying,
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose ní aginjù Sinai pé,
15 Number the sons of Levi by their fathers' houses, by their families. Thou shall number them, every male from a month old and upward.
“Ka àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè.”
16 And Moses numbered them according to the word of Jehovah, as he was commanded.
Mose sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
17 And these were the sons of Levi by their names: Gershon, and Kohath, and Merari.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
18 And these are the names of the sons of Gershon by their families: Libni and Shimei.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
19 And the sons of Kohath by their families: Amram, and Izhar, Hebron, and Uzziel.
Àwọn ìdílé Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
20 And the sons of Merari by their families: Mahli and Mushi. These are the families of the Levites according to their fathers' houses.
Àwọn ìdílé Merari ni: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni ìdílé Lefi gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
21 Of Gershon was the family of the Libnites, and the family of the Shimeites. These are the families of the Gershonites.
Ti Gerṣoni ni ìdílé Libni àti Ṣimei; àwọn ni ìdílé Gerṣoni.
22 Those who were numbered of them, according to the number of all the males, from a month old and upward, even those who were numbered of them were seven thousand and five hundred.
Iye àwọn ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, jẹ́ ẹgbàata ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
23 The families of the Gershonites shall encamp behind the tabernacle westward.
Àwọn ìdílé Gerṣoni yóò pa ibùdó sí ìhà ìwọ̀-oòrùn lẹ́yìn àgọ́.
24 And the ruler of the fathers' house of the Gershonites shall be Eliasaph the son of Lael.
Olórí àwọn ìdílé Gerṣoni ni Eliasafu ọmọ Láélì.
25 And the charge of the sons of Gershon in the tent of meeting shall be the tabernacle, and the tent, the covering of it, and the screen for the door of the tent of meeting,
Iṣẹ́ àwọn ìdílé Gerṣoni nínú àgọ́ ìpàdé ni pé àwọn yóò máa tọ́jú àgọ́, ìbòrí àgọ́, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
26 and the hangings of the court, and the screen for the door of the court, which is by the tabernacle, and by the altar round about, and the cords of it for all the service thereof.
aṣọ títa ti àgbàlá, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, àwọn okùn rẹ̀ àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
27 And of Kohath was the family of the Amramites, and the family of the Izharites, and the family of the Hebronites, and the family of the Uzzielites. These are the families of the Kohathites.
Ti Kohati ní ìdílé Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli, wọ̀nyí ni ìran Kohati.
28 According to the number of all the males, from a month old and upward, there were eight thousand and six hundred, keeping the charge of the sanctuary.
Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbàá mẹ́rin ó lé ẹgbẹ̀ta, tí yóò máa ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́.
29 The families of the sons of Kohath shall encamp on the side of the tabernacle southward.
Àwọn ìdílé Kohati yóò pa ibùdó wọn sí ìhà gúúsù ní ẹ̀gbẹ́ àgọ́.
30 And the ruler of the fathers' house of the families of the Kohathites shall be Elizaphan the son of Uzziel.
Olórí àwọn ìdílé Kohati ni Elisafani ọmọ Usieli.
31 And their charge shall be the ark, and the table, and the lampstand, and the altars, and the vessels of the sanctuary with which they minister, and the screen, and all the service thereof.
Àwọn ni yóò máa tọ́jú àpótí ẹ̀rí, tábìlì, ọ̀pá fìtílà, àwọn pẹpẹ, gbogbo ohun èlò ibi mímọ́ tí à ń lò fún iṣẹ́ ìsìn, aṣọ títa àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
32 And Eleazar the son of Aaron the priest shall be ruler of the rulers of the Levites, with the oversight of those who keep the charge of the sanctuary.
Eleasari ọmọ Aaroni àlùfáà ni alákòóso gbogbo àwọn olórí ìdílé Lefi. Òun ni wọ́n yàn lórí gbogbo àwọn tí yóò máa tọ́jú ibi mímọ́.
33 Of Merari was the family of the Mahlites, and the family of the Mushites. These are the families of Merari.
Ti Merari ni ìran Mahili àti Muṣi, àwọn ni ìran Merari.
34 And those who were numbered of them, according to the number of all the males, from a month old and upward, were six thousand and two hundred.
Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, èyí tí wọ́n kà jẹ́ igba mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
35 And the ruler of the fathers' house of the families of Merari was Zuriel the son of Abihail. They shall encamp on the side of the tabernacle northward.
Olórí àwọn ìdílé ìran Merari ni Ṣurieli ọmọ Abihaili. Wọn yóò pa ibùdó wọn sí ìhà àríwá àgọ́.
36 And the appointed charge of the sons of Merari shall be the boards of the tabernacle, and the bars of it, and the pillars of it, and the sockets of it, and all the instruments of it, and all the service thereof,
Àwọn ìran Merari ni a yàn fún títọ́jú àwọn férémù àgọ́, ọ̀pá ìdábùú rẹ̀, òpó rẹ̀, ihò òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn.
37 and the pillars of the court round about, and their sockets, and their pegs, and their cords.
Iṣẹ́ wọn tún ni títọ́jú àwọn òpó tó yí àgbàlá ká, ihò òpó rẹ̀, èèkàn àti okùn wọn.
38 And those who encamp before the tabernacle eastward, before the tent of meeting toward the sunrise, shall be Moses, and Aaron and his sons, keeping the charge of the sanctuary for the charge of the sons of Israel. And the stranger that comes near shall be put to death.
Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn ọmọ yóò pa àgọ́ ní ìdojúkọ ìwọ̀-oòrùn níwájú àgọ́ ìpàdé. Iṣẹ́ wọn ni láti máa mójútó iṣẹ́ ìsìn ibi mímọ́ àti láti máa ṣiṣẹ́ ìsìn fún àwọn ọmọ Israẹli. Àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ yàtọ̀ sí àwọn tí a yàn, pípa ni kí ẹ pa á.
39 All who were numbered of the Levites, whom Moses and Aaron numbered at the commandment of Jehovah, by their families, all the males from a month old and upward, were twenty-two thousand.
Àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Lefi tí a kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose àti Aaroni gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, pẹ̀lú gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún.
40 And Jehovah said to Moses, Number all the firstborn males of the sons of Israel from a month old and upward, and take the number of their names.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Ka gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli láti ọmọ oṣù kan ó lé kí o sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
41 And thou shall take the Levites for me (I am Jehovah) instead of all the firstborn among the sons of Israel, and the cattle of the Levites instead of all the firstlings among the cattle of the sons of Israel.
Kí o sì gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì gba gbogbo ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi fún mi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa.”
42 And Moses numbered, as Jehovah commanded him, all the firstborn among the sons of Israel.
Mose sì ka gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un.
43 And all the firstborn males according to the number of names, from a month old and upward, of those who were numbered of them, were twenty-two thousand two hundred and seventy-three.
Àpapọ̀ iye àwọn àkọ́bí ọkùnrin láti ọmọ oṣù kan ó lé, ní àkọsílẹ̀ orúkọ wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé ọ̀rìnlúgba ó dín méje.
44 And Jehovah spoke to Moses, saying,
Olúwa tún sọ fún Mose pé,
45 Take the Levites instead of all the firstborn among the sons of Israel, and the cattle of the Levites instead of their cattle. And the Levites shall be mine. I am Jehovah.
“Gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli àti ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi dípò ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Tèmi ni àwọn ọmọ Lefi. Èmi ni Olúwa.
46 And for the redemption of the two hundred and seventy-three of the firstborn of the sons of Israel, who are over and above the number of the Levites,
Nísinsin yìí, láti lè ra ọ̀rìnlúgba dín méje àkọ́bí àwọn Israẹli tó ju iye àwọn ọmọ Lefi lọ,
47 thou shall take five shekels apiece by the poll. According to the shekel of the sanctuary thou shall take them (the shekel is twenty gerahs),
ìwọ yóò gba ṣékélì márùn-ún lórí ẹni kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, èyí tí í ṣe ogún gera.
48 and thou shall give the money, with which the odd number of them is redeemed, to Aaron and to his sons.
Owó tí a fi ra àwọn àkọ́bí ọmọ Israẹli tó lé yìí, ni kí o kó fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀.”
49 And Moses took the redemption-money from those who were over and above those who were redeemed by the Levites.
Nígbà náà ni Mose gba owó ìràpadà àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi ti ra àwọn yòókù padà.
50 He took the money from the firstborn of the sons of Israel, a thousand three hundred and sixty-five shekels, according to the shekel of the sanctuary.
Mose sì gba egbèje ṣékélì ó dín márùndínlógójì gẹ́gẹ́ bí iye ṣékélì ibi mímọ́ lọ́wọ́ àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli.
51 And Moses gave the redemption-money to Aaron and to his sons, according to the word of Jehovah, as Jehovah commanded Moses.
Mose sì kó owó ìràpadà yìí fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.