< Zaburi 106 >
1 Pakuru Jehova Nyasaye! Gouru erokamano ne Jehova Nyasaye, nikech ober; kendo herane osiko manyaka chiengʼ.
Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
2 En ngʼa manyalo hulo gik madongo ma Jehova Nyasaye osetimo kata manyalo nyiso pakne duto?
Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
3 Ogwedh joma osiko koluwo adiera, joma osiko katimo gima kare.
Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
4 An bende parae, yaye Jehova Nyasaye, parae ka itimo ngʼwono ne jogi, bi ikonya ka iresogi,
Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
5 mondo an bende awinjie maber gi mwandu mimiyo jogi miyiero, mondo ayudie mor mar ogandani, kendo amiyi duongʼ kaachiel gi girkeni mari.
kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
6 Wasetimo richo mana kaka kwerewa bende notimo; wasetimo marach kendo wasetimo gik mamono.
Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
7 Kane kwerewa ni Misri, ne ok giparo matut kuom honni magi; bende ne wigi owil gi kechni mathoth, ne gingʼanyoni e dho nam, ma en Nam Makwar.
Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
8 Kata kamano noresogi nikech nyinge, mondo omi tekone maduongʼ ongʼere.
Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
9 Nokwero Nam Makwar, mi Nam Makwar notwo; kendo nomiyo gikalo kama tut mana ka gima ne giwuotho kama otwo.
O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
10 Noresogi e lwet joma ne kedo kodgi, adier, nowarogi e lwet wasigu.
O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
11 Pi noimo wasikgi; ma kata achiel kuomgi ne ok otony.
Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
12 Eka ne giyie gi singruok mage kendo ne gipake gi wer.
Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
13 To ma ok wigi nowil gi gik mane osetimo kendo ne ok girite mondo ongʼadnegi rieko.
Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
14 Wuoro mokalo tongʼ nomakogi e thim, kendo ne gitemo Nyasaye e piny motwo.
Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
15 Omiyo ne omiyogi gima negidwaro, to kata kamano nooronegi tuo machiyo del.
Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
16 Nyiego nomakogi gi Musa e kambi, kendo gi Harun, jatich mowal ni Jehova Nyasaye.
Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
17 Piny ne oyawore mi nomwonyo Dathan; piny noiko oganda joka Abiram.
Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
18 Mach nomuoch kuom joma luwogi; mach maliel mager nowangʼo joma timbegi richogo motiekogi pep.
Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
19 Negiloso nyaroya Horeb, mine gilamo kido molos gi chuma.
Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
20 Ne giwilo Duongʼ margi gi kido mar rwath machamo lum.
Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
21 Wigi nowil gi Nyasaye mane oresogi, Nyasaye mane osetimo gik madongo e piny Misri,
Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
22 Nyasaye mane osetimo honni e piny Ham kod timbe miwuoro e dho Nam Makwar.
iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
23 Emomiyo nowacho ni nobiro tiekogi ka dine Musa, ngʼate moyiero, we chungʼ kaywagore e nyime mondo ogengʼ mirimbe kik otiekgi.
Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
24 Bangʼe ne gichayo pinye ma jaber; nikech ne ok giyie singruokne ni en adier.
Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
25 Ne gingʼur ei hembegi kendo ne ok gitimo gik ma Jehova Nyasaye nochikogi.
Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
26 Emomiyo ne osingorenegi kosiemogi gi lwete nine obiro miyo gipodhi e thim,
Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
27 nonyisogi ni ne obiro miyo nyikwagi podhi e kind ogendini, kendo ni ne obiro keyogi e pinje duto.
láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
28 Ne giriwore kaachiel e lamo Baal mar jo-Peor, kendo negichamo misango michiwone nyiseche motho;
Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
29 omiyo ne giwangʼo i Jehova Nyasaye gi timbegi marichogo, mi masira nomakogi.
wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
30 Kata kamano Finehas nochungʼ kargi kendo noywagore ne Nyasaye, mi masirano ne ok otiekogi.
Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
31 Nyasaye nokwane kaka ngʼama kare nikech timneno, kendo ibiro kwane kamano nyaka tienge mabiro.
A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
32 Ne giwangʼo i Jehova Nyasaye, e dho sokni mag Meriba, mi timgino nokelone Musa chandruok;
Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
33 nimar negiketho chunye mi weche maricho nowuok e dhoge.
Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
34 Ne ok gitieko ogendini chutho kaka Jehova Nyasaye nosechikogi,
Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
35 to ne giriwore kodgi kendo negiluwo timbegi.
Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
36 Negilamo kido mag nyisechegi, ma bangʼe nolokorenegi obadho.
Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
37 Negichiwo yawuotgi gi nyigi kaka misango, kendo negichiwogi ne jochiende.
Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
38 Ne gichwero remo maonge ketho, remb yawuotgi gi nyigi, mane gichiwo kaka misango ne kido mag nyiseche mag Kanaan, mi piny nogak nikech rembgi.
Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
39 Negidoko mogak nikech gik mane gitimo; negibedo joma odwanyore, nikech timbegigo.
Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
40 Emomiyo Jehova Nyasaye nokecho gi joge kendo chunye noa kuom girkeni mare.
Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
41 Nochiwogi e lwet ogendini, mine gibet e bwo loch joma ne mon kodgi.
Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
42 Wasikgi nothirogi kendo negiketogi e bwo tekogi.
Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
43 Ne oresogi nyadi mangʼeny to kata kamano joge noketo chunygi ne ngʼanyo, mi richogi nochiwogi mi girumo.
Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
44 Kata kamano nokechogi e chandruokgi kane owinjo ywakgi;
Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
45 nikech noparo singruok mane otimo kodgi kendo noloko chunye nikech herane maduongʼ.
ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
46 Nochuno ji duto mane oketogi wasumbini mondo okechgi.
Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
47 Reswa, yaye Jehova Nyasaye ma Nyasachwa, kendo chokwa igolwa e dier ogendini, mondo wadwok erokamano ne nyingi maler kendo wabed mamor kwapaki.
Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
48 Pakuru Jehova Nyasaye, ma Nyasach Israel, mochwere manyaka chiengʼ. Ji duto mondo owach niya, “Amin!” Opak Jehova Nyasaye.
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!