< Obadia 1 >

1 Fweny mag Obadia. Magi e weche ma Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho kuom Edom. Wasewinjo wach; koa kuom Jehova Nyasaye. Jaote oseor ir ogendini mondo owach niya, “Chunguru, wadhi waked kode.”
Ìran ti Obadiah. Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu. Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, a sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé, “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”
2 “To neuru, abiro miyo udok matin e kind ogendini, bende ibiro chau ahinya.
“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí; ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
3 Sunga manie chunyu osewuondou, un mudak e kind lwendni, kendo ugero miechu kuonde motingʼore, un ma uwacho kendu niya, ‘En ngʼa manyalo dwokowa piny?’
Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ, ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta, tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga, ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé, ‘Ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
4 To kata obedo ni unyalo fuyo malo mabor ka ongo, kendo ugero kar daku maber e kind sulwe malo, to koa kuno abiro dwokou piny,” Jehova Nyasaye owacho.
Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì, bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,” ni Olúwa wí.
5 “Ka jokwoge obironu, jomecho mag otieno, to mano kaka masira malich ritou, donge gibiro kwalo mwandu magu kaka ginyalo? Ka jopon mzabibu obiro iru donge digiwe olemb mzabibu matin?
“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá, bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru, Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́, wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́? Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá, wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
6 To mano kaka Esau ibiro choko gigene kendo mwandune mopandi noyaki!
Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau, tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
7 Ogendini ma uriworugo biro sembou nyaka giko mar tongʼ; osiepeu biro wuondou ma lowu; kendo joma chamo chiembu biro ketonu obadho, to ok unufweny.”
Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ; àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”
8 Jehova Nyasaye wacho niya, “Odiechiengʼno donge abiro tieko jorieko mag Edom, jogo man-gi winjo e gode mag Esau?
Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà, Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run, àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
9 Jolweny magi, yaye Teman, biro bedo kod bwok kendo ji duto modak, e gode mag Esau ibiro negi.
A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, ìwọ Temani, gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
10 Nikech lweny mane utimone owadu Jakobo unubed gi wichkuot; mi nokethu nyaka chiengʼ.
Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ, ìtìjú yóò bò ọ, a ó sì pa ọ run títí láé.
11 Chiengʼ mane ichungʼ tenge ka joma moko donjo e dhorangeyene, kendo gigoyo ombulu ne Jerusalem, ne ichal mana kodgi.
Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan, ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ, tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ, tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu, ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
12 Ne ok onego ungʼigi kod achaya chiengʼ masichgi, bende ne ok onego ubed mamor chiengʼ mane ikethoe Juda, kata bedo gi ngʼayi chiengʼ chandruokgi.
Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ, ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda, ní ọjọ́ ìparun wọn ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
13 Ne ok onego udonj e dhorangeye mag joga chiengʼ mane masira omakogi, kata ngʼiyogi gachaya e thagruokgi, kata kawo mwandugi, e chiengʼ thagruokgi gi chiengʼ masichegi.
Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀ nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn. Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó, ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
14 Ne ok onego uchungʼ e akek yore, ka ugengʼone jogegi maringo, kendo ne ok onego uchiw jogegi motony e lwet wasikgi chiengʼ chandruokgi.
Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò. Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.
15 “Chiengʼ Jehova Nyasaye okayo machiegni ne ogendini duto, bende kaka isetimo e kaka notimni, timbeni nodwogi e wiyi iwuon.
“Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé lórí gbogbo àwọn kèfèrí. Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà; ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
16 Mana kaka ne umer ewi goda maler e kaka ogendini duto, biro metho ametha, ginimeth ametha ma ginichal joma onge.
Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí; wọn yóò mu ún ní àmutẹ́rùn wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò mu ún rí.
17 To ewi got mar Sayun tony nobedie, mi enobed kama ler, kendo od Jakobo nokaw girkeni mage.
Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni, wọn yóò sì jẹ́ mímọ́, àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn.
18 Od Jakobo nobed mach kendo od Josef mach nokaknie, od Esau nobed chuk mach, mi ginimoke moliel pep, onge ngʼat ma notony koa e od Esau.” Jehova Nyasaye osewacho.
Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko wọn yóò fi iná sí i, wọn yóò jo run. Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.” Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
19 Jo-Negev nokaw piny gode mag Esau, kendo joma odak e tiend gode nokaw piny jo-Filistia, ginikaw nyaka piny Efraim gi Samaria, eka jo-Benjamin nokaw piny Gilead.
Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau, àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní. Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria; Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
20 To oganda mar jo-Israel mane oter e twech e piny Kanaan, nokaw pinyno nyaka chop Zarefath, kendo jo-Jerusalem manie twech, e piny Sefarad biro kawo miech Negev.
Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati; àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní.
21 Jores noidhi ewi got mar Sayun, mi ginibed kod loch ewi gode mag Esau, kendo pinyruoth duto nobed e lwet Jehova Nyasaye.
Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau. Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

< Obadia 1 >