< Kwan 25 >

1 Kane oyudo jo-Israel odak Shitim, chwo nochako terore gi monde jo-Moab,
Nígbà tí àwọn Israẹli dúró ní Ṣittimu, àwọn ènìyàn sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin Moabu,
2 mane ogwelogi e chiwo misengini ne nyisechegi. Ji nochiemo moyiengʼ kendo negipodho auma ka gilamo nyisechegi.
tí ó pè wọ́n sí ibi ẹbọ òrìṣà wọn. Àwọn ènìyàn náà jẹun wọ́n sì foríbalẹ̀ níwájú òrìṣà wọn.
3 Omiyo Israel noriwore kodgi e yor lamo Baal mar Peor. Kendo mirima nomako Jehova Nyasaye ahinya kodgi.
Báyìí ni Israẹli ṣe darapọ̀ mọ́ wọn tí wọ́n sì jọ ń sin Baali-Peori. Ìbínú Olúwa sì ru sí wọn.
4 Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya, “Kaw jotend jogi duto, neg-gi kendo dhurgi e lela e nyim Jehova Nyasaye, mondo omi mirimb Jehova Nyasaye owuog kuom Israel.”
Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú gbogbo àwọn olórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, pa wọ́n kí o sì fi wọ́n kọ́ sórí igi ní gbangba nínú oòrùn níwájú Olúwa, kí ìbínú Olúwa lè kúrò ní ọ̀dọ̀ Israẹli.”
5 Omiyo Musa nowacho ne jongʼad bura mag Israel niya, “Ngʼato ka ngʼato kuomu nyaka neg jou machwo ma oseriwore e lamo Baal mar Peor.”
Mose sọ fún àwọn onídàájọ́ Israẹli, “Ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ pa arákùnrin rẹ̀ èyí tí ó darapọ̀ ní fífi orí balẹ̀ fún Baali-Peori.”
6 Eka ja-Israel moro nobiro gi nyar jo-Midian e hembe ka Musa neno kaachiel gi oganda jo-Israel duto mane oyudo ywak e dho Hemb Romo.
Nítòótọ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin Israẹli sì mú obìnrin Midiani wá síwájú ojú Mose àti gbogbo ìjọ ti Israẹli wọ́n sì ń sọkún ní àbáwọlé àgọ́ ìpàdé.
7 Kane Finehas wuod Eliazar, ma wuod Harun jadolo, noneno ma, nowuok e chokruokno, mokawo tongʼ e lwete,
Nígbà tí Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni, àlùfáà, rí èyí, ó fi ìjọ sílẹ̀, pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ní ọwọ́ rẹ̀.
8 kendo noluwo bangʼ ja-Israelno nyaka e hema. Nochwowogi duto moriwogi gi tongʼ. Eka tho mane osenego jo-Israel norumo;
Ó sì tẹ̀lé arákùnrin Israẹli yìí lọ sínú àgọ́. Ó sì fi ọ̀kọ̀ gún àwọn méjèèjì ní àgúnyọ láti ara ọkùnrin Israẹli àti sí ara obìnrin náà. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn lórí àwọn ọmọ Israẹli sì dúró;
9 to ji mane tho ma kamano onego ne gin ji alufu piero ariyo gangʼwen.
ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí ó kú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn náà jẹ́ ẹgbàá méjìlá.
10 Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya,
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
11 “Finehas wuod Eliazar, ma wuod Harun jadolo, osetieko mirimba kuom jo-Israel; nimar en gi nyiego machal gi mara; mano emomiyo ne ok atiekogi kata obedo nine an kod mirima kodgi kamano.
“Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà, ti yí ìbínú mi padà kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí tí ó ní ìtara bí èmi náà ti ní ìtara fún iyì mi láàrín wọn, kí ó lè jẹ́ pé èmi ló pa wọ́n run nínú ìtara mi sí wọn.
12 Emomiyo nyise ni aloso singruok mar kwe kode.
Nítorí náà sọ fún un pé èmi ṣe májẹ̀mú àlàáfíà mi pẹ̀lú rẹ̀.
13 Asingorane ni en kod nyikwaye ginibed jodolo maga nyaka chiengʼ, nikech ne en jasinani kuom miyo Nyasache duongʼ kendo negichiwo misango mar pwodho jo-Israel e richo.”
Òun àti irú-ọmọ rẹ̀ yóò ní májẹ̀mú láéláé fún iṣẹ́ àlùfáà, nítorí pé ó ní ìtara fún Ọlọ́run rẹ̀ láti fi yẹ́ Ọlọ́run sí, ó sì ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Israẹli.”
14 Nying ja-Israel mane onegi gi nyar jo-Midian ne en Zimri wuod Salu, mane en jatend dhood Simeon.
Orúkọ ọmọ Israẹli tí a pa pẹ̀lú obìnrin Midiani náà ni Simri, ọmọ Salu, olórí ilé kan nínú àwọn ọmọ Simeoni.
15 To nying nyar jo-Midian mane onegi ne en Kozbi ma nyar Zur, ma wuon-gi ne en jatend dhood jo-Midian.
Orúkọ ọmọbìnrin Midiani náà tí a pa ní Kosbi ọmọbìnrin Suri, tí ṣe olóyè àwọn ẹ̀yà kan nínú ìdílé kan ní Midiani.
16 Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya,
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
17 “Sanduru jo-Midian kendo uneg-gi,
“Ka àwọn ará Midiani sí ọ̀tá, kí o sì pa wọ́n,
18 nikech ne githagou gi timbegi maricho mane gitimo Peor kendo kuom wach Kozbi ma nyar jatend Midian mane onegi ndalo mane yamb tho obiro nikech gima notimore Peor.”
nítorí pé wọ́n ṣe sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá nígbà tí wọ́n tàn yín nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Peori, àti arábìnrin wọn Kosbi ọmọbìnrin ìjòyè Midiani kan, obìnrin tí a pa nígbà tí àjàkálẹ̀-ààrùn ṣẹlẹ̀ nítorí Peori.”

< Kwan 25 >