< Nehemia 13 >

1 Chiengʼno kitabu mar Musa nosom ka ji winjo kendo noyud kondikie ni jo-Amon kata jo-Moab ok onego yienegi donjo e chokruok mar Nyasaye,
Ní ọjọ́ náà ni a ka ìwé Mose sókè sí etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn, nínú rẹ̀ ni a ti rí i tí a kọ ọ́ sílẹ̀ pé a kò gbọdọ̀ gba àwọn ará a Ammoni tàbí àwọn ará a Moabu sí àárín ìjọ ènìyàn Ọlọ́run láéláé.
2 nikech ne ok giromone jo-Israel gi chiemo kod pi, makmana to negichulo Balaam mondo okwongʼ-gi. (Kata kamano, Nyasachwa noloko kwongʼno obedo gweth.)
Nítorí wọn kò mú oúnjẹ àti omi wá pàdé àwọn ọmọ Israẹli lọ́nà, dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n bẹ Balaamu ní ọ̀wẹ̀ láti gégùn ún lé wọn lórí. (Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa yí ègún náà padà sí ìbùkún.)
3 Ka ji nowinjo chikni, negigolo oko jogo duto ma welo kuom jo-Israel.
Nígbà tí àwọn ènìyàn gbọ́ òfin yìí, wọ́n yọ gbogbo àwọn àjèjì ènìyàn tí ó darapọ̀ mọ́ wọn kúrò láàrín àwọn Israẹli.
4 Ka ma ne pok otimore, to Eliashib jodolo noseketi jarit kuonde keno mag od Nyasachwa. To ne en osiep Tobia machiegni ahinya,
Ṣáájú èyí a ti fi Eliaṣibu àlùfáà ṣe alákòóso yàrá ìkó nǹkan ilé Ọlọ́run wa sí. Ó súnmọ́ Tobiah pẹ́kípẹ́kí.
5 kendo ne osemiye ot malach kama yande ikanoe chiwo mar cham kod gik ubani kod gige hekalu, bende nikanoe achiel kuom apar mar cham, divai manyien gi mo kaka pok jo-Lawi, jower kod jorit dhorangeye, kaachiel gi chiwo mag jodolo.
Ó sì ti pèsè yàrá ńlá kan fún un, èyí tí a ń lò tẹ́lẹ̀ fún ìtọ́jú ọrẹ ọkà, tùràrí àti àwọn ohun èlò tẹmpili àti ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró ti a fi lélẹ̀ bí ìlànà fún àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà àti pẹ̀lú gbogbo ọrẹ fún àwọn àlùfáà.
6 To ka magi duto ne dhi nyime, ne aonge Jerusalem, nimar e higa mar piero adek gariyo mar loch Artaksases ruodh Babulon ne asedok ir ruoth. Bangʼe ne akwaye thuolo
Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo èyí ń lọ lọ́wọ́, èmi kò sí ní Jerusalẹmu, nítorí pé ní ọdún kejìlélọ́gbọ̀n Artasasta ọba Babeli ni mo padà tọ ọba lọ. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó ṣe díẹ̀, mo gba ààyè lọ́dọ̀ọ rẹ̀.
7 mi adok Jerusalem. To ma ne omiyo afwenyo gima rach mane Eliashib nosetimo kuom miyo Tobia kar dak e od Nyasaye.
Mo sì padà sí Jerusalẹmu. Níhìn-ín ni mo ti mọ̀ nípa onírúurú ohun búburú tí Eliaṣibu ti ṣe ní ti pípèsè yàrá fún Tobiah nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run.
8 Ne abedo gi chwanyruok kendo ne awito gige Tobia mag ot duto oko mar kama nodakie.
Kò tẹ́ mi lọ́rùn rárá, mo kó gbogbo ohun èlò ìdílé e Tobiah dà síta láti inú iyàrá náà.
9 Ne achiwo chik motegno mondo opwodh odno, bangʼe to ne adwoko gik milemogo mag od Nyasaye gi chiwo mar cham kod ubani.
Mo pàṣẹ kí wọn ya àwọn iyàrá náà sí mímọ́, mo sì kó àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run padà síbẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ọkà àti tùràrí.
10 Bende ne afwenyo ni bath pok mane oket ne jo-Lawi ne pod ok omigi, to kendo ni jo-Lawi gi jower mane ochungʼ ne tich nosedok e puothegi giwegi.
Mo sì tún gbọ́ pé, kò fi àwọn ìpín tí a yà sọ́tọ̀ fún àwọn Lefi, àwọn akọrin tí ń ṣe àkóso ìsìn sì ti padà sí ẹnu onírúurú iṣẹ́ wọn.
11 Omiyo ne adhawone jotelogo kendo apenjogi niya, Angʼo momiyo od Nyasaye ojwangʼ? Bangʼe ne aluongogi kanyakla kendo aketogi kuondegi.
Nígbà náà ni mo bá àwọn ìjòyè wí, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí a fi kọ ilé Ọlọ́run sílẹ̀?” Nígbà náà ni mo pè wọ́n jọ pọ̀, mo sì fi olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
12 Jo-Juda duto nokelo achiel kuom apar mar cham, divai manyien kod mo e ute keno.
Gbogbo Juda mú ìdámẹ́wàá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró wá sínú yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí.
13 Ne aketo Shelemia jadolo, Zadok jandiko, kod ja-Lawi ma nyinge Pedaya kaka jachungʼ mar ute keno kendo ne aketo Hanan wuod Zakur, wuod Matania jalupgi, nikech jogi nokwan ka jo-ratiro. Nomigi tich mar pogo gigo mokel ne owetegi.
Mo sì fi àlùfáà Ṣelemiah, Sadoku akọ̀wé àti ọmọ Lefi kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Pedaiah ṣe alákòóso àwọn yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí. Mo sì yan Hanani ọmọ Sakkuri, ọmọ Mattaniah bí olùrànlọ́wọ́ ọ wọn. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ni a kà sí àwọn tó ṣé e gbẹ́kẹ̀lé. Àwọn ni a yàn láti máa pín ohun èlò fún àwọn arákùnrin wọn.
14 Yaye Nyasacha, para kuom ma kendo kik wiyi wil gi gik masetimone odi gadiera gi tijeni duto.
Rántí ì mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o má sì ṣe gbàgbé ohun tí mo fi òtítọ́ ṣe fún ilé Ọlọ́run mi yìí àti fún iṣẹ́ ẹ rẹ̀ gbogbo.
15 E ndalogo naneno jomoko e piny Juda kabiyo mzabibu milosogo divai chiengʼ Sabato kendo gikelo cham ka giketo e ngʼe punda, kaachiel gi divai, mzabibu, ngʼowu kod misike mopogore opogore. To negikelo gigi duto ei Jerusalem chiengʼ Sabato. Omiyo ne akwerogi ni kik gihon chiemo odiechiengʼno.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ènìyàn ní Juda tí wọ́n ń fúntí ní ọjọ́ ìsinmi, tí wọ́n sì ń gbé ọkà wọlé, tí wọn ń di ẹrù lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pẹ̀lú wáìnì, èso àjàrà, ọ̀pọ̀tọ́ àti onírúurú ẹrù. Wọ́n sì ń kó gbogbo èyí wá sí Jerusalẹmu ní ọjọ́ ìsinmi. Nítorí náà, mo kìlọ̀ fún wọn nípa títa oúnjẹ ní ọjọ́ náà.
16 Jo-Turo mane odak Jerusalem ne kelo rech kod gige ohala mopogore opogore bangʼe gihonogi ei Jerusalem ne jo-Juda chiengʼ Sabato.
Àwọn ará Tire ti ń gbé nínú Jerusalẹmu ń gbé ẹja àti onírúurú ọjà wá fún títà ní ọjọ́ ìsinmi fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti fún àwọn ọmọ Juda.
17 Ne adhawone jodong Juda mi apenjogi niya, “Ma en gima rach manade mutimo chiengʼ Sabato?
Mo bá àwọn ọlọ́lá Juda wí, mo wí fún wọn pé, “Èwo ni ohun búburú tí ẹ ń ṣe yìí ti ẹ ń ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.
18 Donge kwereu notimo mana gik machalre gi gigi, ma nomiyo Nyasachwa okelo masiragi duto kuomwa kendo kuom dala maduongʼ? Omiyo koro umedo kelo kwongʼ kuom jo-Israel kuom njawo chiengʼ Sabato.”
Ṣé àwọn baba ńlá yín kò ha ti ṣe nǹkan kan náà tí Ọlọ́run wa fi mú gbogbo àjálù yìí wá orí wa, àti sórí ìlú yìí? Báyìí, ẹ̀yin tún ń ru ìbínú sókè sí i sórí Israẹli nípa bíba ọjọ́ ìsinmi jẹ́.”
19 Ka chiengʼ ne pok opodho e dhorangeye Jerusalem kendo ka Sabato pok ochopo, ne achiwo chik mondo dhoudi olor kendo mondo kik yawgi nyaka Sabato rum. Ne oketo joge owuon e rangeye mondo kik misigo moro amora kel chiengʼ Sabato.
Nígbà tí ojú ọjọ́ ń bora ní ẹnu ibodè Jerusalẹmu, ṣáájú ọjọ́ ìsinmi, mo pàṣẹ pé kí a ti àwọn ìlẹ̀kùn, kí wọn má sì ṣí i títí tí ọjọ́ ìsinmi yóò fi kọjá. Mo yan àwọn ìránṣẹ́ mi láti ṣọ́ ẹnu ibodè, kí a má ba à lè gbé ẹrù kankan wọlé ní ọjọ́ ìsinmi.
20 Johala kod joma hono gik mopogore opogore nobiro dichiel kata diriyo mobuoro but Jerusalem.
Síbẹ̀, àwọn tí ń tà àti àwọn tí ń rà sùn ẹ̀yìn odi Jerusalẹmu ní ẹ̀ẹ̀kan tàbí ẹ̀ẹ̀mejì.
21 To ne asiemogi kawacho niya, “Angʼo momiyo unindo oko machiegni gi ohinga?” Ka uchako utimo ma, to abiro makou. Chakre godiechiengno ne ok gichako gidwogo chiengʼ Sabato.
Ṣùgbọ́n mo kìlọ̀ fún wọn pé, “Èétijẹ́ ti ẹ̀yin fi ń sùn ní ẹ̀yin odi ní òru? Bí ẹ̀yìn bá tún dánwò mọ́, èmi yóò fi ọwọ́ líle mú yín.” Láti ọjọ́ náà lọ, wọn kò sì wá ní ọjọ́ ìsinmi mọ́.
22 Bangʼe ne achiwo chik ne jo-Lawi mondo opwodhre kendo gidhi girit rangeye mondo gimi chiengʼ Sabato obed maler. Yaye Nyasacha, para ema bende, kendo itimna ngʼwono kaluwore gi herani maduongʼ.
Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi pé kí wọn ya ara wọn sí mímọ́, kí wọn sì ṣọ́ ẹnu ibodè kí a lè pa ọjọ́ ìsinmi mọ́. Tún rántí mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o sì fi àánú un rẹ hàn fún mi gẹ́gẹ́ bí i títóbi ìfẹ́ ẹ̀ rẹ.
23 Kata kamano, e ndalogo ne aneno joma chwo moa Juda mane okendo nyi Ashdod, Amon kod Moab.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, mo rí àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin láti Aṣdodu, Ammoni àti Moabu.
24 Nus mar nyithindgi ne wacho dho Ashdod kata dho achiel kuom joma moko, to ne ok gi ngʼeyo dho Juda.
Ìdajì àwọn ọmọ wọn ń sọ èdè Aṣdodu tàbí èdè ọ̀kan lára àwọn ènìyàn mìíràn tókù, wọn kò sì mọ bí a ṣe ń sọ èdè Juda.
25 Ne adhawonegi mi akwongʼogi. Ne agoyo chwo moko mi apudho yie wigi. Ne aketogi gikwongʼore e nying Nyasaye mi giwacho niya, “Kik uwe nyiu kend gi yawuotgi, kata nyigi bende kik kend gi yawuotu, to un bende kik ukend nyigi.
Mo bá wọn wí mo sì gégùn ún lé wọn lórí. Mo lu àwọn ènìyàn díẹ̀ nínú wọn mo sì fa irun orí wọn tu. Mo mú kí wọn búra ní orúkọ Ọlọ́run, kí wọn wí pé, “Ẹ̀yin kì yóò fi àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó tàbí fún ẹ̀yin tìkára yín.
26 Donge ne en nikech kend ma kamagi mane omiyo Solomon ruodh Israel otimo richo? E dier ogendini duto ne onge ruoth machal kode. Nohere gi Nyasache, kendo Nyasaye nokete ruoth ewi jo-Israel duto, to kata kamano mon ma ok jo-Yahudi nomiyo otimo richo.
Kì í ha á ṣe àwọn ìgbéyàwó bí irú èyí ni ọba Solomoni fi dá ẹ̀ṣẹ̀? Láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí ọba kan bí i tirẹ̀. Ọlọ́run rẹ̀ fẹ́ràn rẹ̀, Ọlọ́run sì fi jẹ ọba lórí i gbogbo Israẹli, ṣùgbọ́n àwọn obìnrin àjèjì ti sọ ọ́ sínú òfin ẹ̀ṣẹ̀.
27 To koro dwawinj ni un bende utimo timbe dwanyruok malich kama kendo ubedo joma ok jo-ratiro ne Nyasachwa kuom nyuomo mon ma welogi?”
Ǹjẹ́ ó ha yẹ kí àwa tún gbọ́ báyìí pé ẹ̀yin náà tún ń ṣe àwọn nǹkan tí ó burú jọjọ wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣe aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì?”
28 Achiel kuom yawuot Joyada wuod Eliashib ma jadolo maduongʼ ne en or Sanbalat ma ja-Horon. Emomiyo ne ariembe oa buta.
Ọ̀kan lára àwọn ọmọ Joiada, ọmọ Eliaṣibu olórí àlùfáà jẹ́ àna Sanballati ará a Horoni. Mo sì lé e jáde kúrò lọ́dọ̀ mi.
29 Yaye Nyasacha, parie kaka gisedwanyo tij dolo gi singruok mar bedo jadolo kod mano mar jo-Lawi.
Rántí wọn, Ọlọ́run mi, nítorí wọ́n ti ba iṣẹ́ àlùfáà jẹ́ pẹ̀lú májẹ̀mú iṣẹ́ àlùfáà àti ti àwọn Lefi.
30 Omiyo ne apwodho jodolo kod jo-Lawi kuom gimoro amora ma wendo, mi amiyogi tije, moro ka moro gi kare owuon.
Nítorí náà, mo ya àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi sí mímọ́ kúrò nínú gbogbo ohun àjèjì, mo sì yan iṣẹ́ fún wọn, olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ rẹ̀.
31 Bende ne achiwo thuolo mar chiwo mar yien e seche mowal, kendo bende ne olembe mokwongo. Yaye Nyasacha, para gi ngʼwono.
Mo sì tún pèsè fún ọrẹ, igi—pákó ní àkókò tí a yàn àti fún àwọn èso àkọ́so. Rántí mi fún rere, Ọlọ́run mi.

< Nehemia 13 >