< Nahum 2 >

1 Ngʼat mabiro monji ochomi, yaye Nineve, omiyo rit dala mochiel motegno, rit yoreni, bed gi ikruok maber, kuom tekoni duto!
Àwọn apanirun ti dìde sí ọ, ìwọ Ninefe. Pa ilé ìṣọ́ mọ́, ṣọ́ ọ̀nà náà, di àmùrè, ẹ̀gbẹ́ rẹ kí ó le múra gírí.
2 Jehova Nyasaye biro dwoko duongʼ mar Jakobo, mana ka duongʼ mar Israel, kata obedo ni joma omonje osekethe kendo oseketho puothegi mag mzabibu.
Olúwa yóò mú ọláńlá Jakọbu padà sípò gẹ́gẹ́ bí ọláńlá Israẹli bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn apanirun ti pa ibẹ̀ run, tí wọ́n sì ba ẹ̀ka àjàrà wọn jẹ́.
3 Okumba mag jolweny osebedo makwar ka remo; kendo lewni ma girwakorego bende kwar. Chuma manie ewi gechegi mil ka giikore ne chiengʼ lweny; tongegi opiag mabith kendo milni ka gikedogo.
Asà àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì di pupa; àwọn ológun wọn sì wọ aṣọ òdòdó. Idẹ tí ó wà lórí kẹ̀kẹ́ ogun ń kọ mọ̀nàmọ́ná ní ọjọ́ tí a bá pèsè wọn sílẹ̀ tán; igi firi ni a ó sì mì tìtì.
4 Geche powore e yore mag dala, ka giringo koni gi koni e tunge mag dala. Gichalo gi rameny maliel mager, ka gipiachore ka mil polo.
Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun yóò ya bo àwọn pópónà, wọn yóò sì máa sáré síwá àti sẹ́yìn ní àárín ìgboro. Wọn sì dàbí ètùfù iná; tí ó sì kọ bí i mọ̀nàmọ́ná.
5 Oluongo jolweny mage moyiero, to gichwanyore ka gidhi. Giringo ka gidhi e ohinga mar dala; ka gigengʼore gi okumba.
Ninefe yóò ṣe àṣàrò àwọn ọlọ́lá rẹ̀; síbẹ̀ wọ́n ń kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà wọn; wọn sáré lọ sí ibi odi rẹ̀, a ó sì pèsè ààbò rẹ̀.
6 Ohinga mane gigengʼogo pi madonjo e dala ruoth omukore, bende od ruoth ogore piny.
A ó ṣí ìlẹ̀kùn àwọn odò wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀, a ó sì mú ààfin náà di wíwó palẹ̀.
7 Osegol Chik ni dala maduongʼ nyaka maki ma ter e piny ma wendo. Wasumbinigi ma nyiri ywagore ka akuche kendo ka gidwongʼo korgi.
A pa á láṣẹ pé ìlú náà, èyí tí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ ni a ó sì kó ní ìgbèkùn lọ. A ó sì mú un gòkè wá àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ yóò kérora bí ti ẹyẹ àdàbà, wọn a sì máa lu àyà wọn.
8 Nineve chalo dago, kendo pige mol kadhi. Giywak kagiwacho niya, “Chungʼ! Chungʼ!” to onge ngʼama lokore duogo.
Ninefe dàbí adágún omi, tí omi rẹ̀ sì ń gbẹ́ ẹ lọ. “Dúró! Dúró!” ni wọ́n ó máa kígbe, ṣùgbọ́n ẹnìkankan kì yóò wo ẹ̀yìn.
9 Yakuru fedha! Yakuru dhahabu! Mwandugi ngʼeny mokadho, gin mwandu mogol kuonde kenogi duto.
“Ẹ kó ìkógun fàdákà! Ẹ kó ìkógun wúrà! Ìṣúra wọn ti kò lópin náà, àti ọrọ̀ kúrò nínú gbogbo ohun èlò ti a fẹ́!”
10 Odongʼ nono, omaye gik moko duto, bende olonye modongʼ duk. Kibaji ogoyo chunygi, bende chongegi onyosere, kendo dendgi tetni ka ngʼato ka ngʼato wangʼe ojowore.
Òun ti ṣòfò, ó si di asán, ó sì di ahoro: ọkàn pami, eékún ń lu ara wọn, ìrora púpọ̀ sì wà nínú gbogbo ẹgbẹ́ àti ojú gbogbo wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì.
11 Koro to ere bur sibuor kama ne gipidhoe nyithindgi, kama sibuor madichwo gi sibuor madhako nodhiye, ka nyithind sibuochego onge gi gima ginyalo luoro?
Níbo ni ihò àwọn kìnnìún wà àti ibi ìjẹun àwọn ọmọ kìnnìún, níbi tí kìnnìún, àní abo kìnnìún tí ń rìn, àti ọmọ kìnnìún, láìsí ohun ìbẹ̀rù.
12 Sibuor ne yangʼo le moromo nyithinde kendo ne gideyo le ma gichamo gi nyawadgi, ka opongʼo kar kano chiembe kod kuonde dakne gi gik monegi.
Kìnnìún tipa ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì fún un ẹran ọdẹ ní ọrùn pa fún àwọn abo kìnnìún rẹ̀, ó sì fi ohun pípa kún ibùgbé rẹ̀ àti ihò rẹ̀ fún ohun ọdẹ.
13 Jehova Nyasaye Maratego wacho niya, “An gi sigu kodu. Abiro wangʼo gecheu mag lweny gi mach mawuog iro kendo ligangla biro tieko sibuoche matindo maroteke. Kata ringregi motho ok anawenu e piny. Dwond jooteu ok nowinj kendo.”
“Kíyèsi i èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò sì fi kẹ̀kẹ́ rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jóná nínú èéfín, idà yóò sì jẹ ọmọ kìnnìún rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì run. Èmi yóò sì ké ohun ọdẹ rẹ kúrò lórí ilẹ̀ ayé. Ohùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni a kì yóò sì tún gbọ́ mọ́.”

< Nahum 2 >