< Tim Jo-Lawi 2 >
1 Ka ngʼato okelone Jehova Nyasaye chiwo mar cham, to nyaka obed mogo mayom. Onego ool mo kuom mogono kendo ochwo ubani kuome,
“‘Bí ẹnìkan bá mú ọrẹ ẹbọ ohun jíjẹ wá fún Olúwa ọrẹ rẹ̀ gbọdọ̀ jẹ́ ìyẹ̀fun dáradára, kí ó da òróró sí i, kí o sì fi tùràrí sí i,
2 eka otere ne yawuot Harun ma jodolo. Jadolo nokaw mogo mayom moru gi sanja achiel kaachiel gi ubani duto kendo nowangʼe kaka pok mar rapar ewi kendo mar misango, ma en misango miwangʼo pep, madum tik mangʼwe ngʼar ne ma Jehova Nyasaye.
kí ó sì gbé lọ fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà. Àlùfáà yóò bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú ìyẹ̀fun àti òróró náà, pẹ̀lú gbogbo tùràrí kí ó sì sun ún gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí lórí pẹpẹ, ọrẹ tí a fi iná ṣe, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
3 Cham mar misango mane odongʼ koro nobedi mar Harun gi yawuote, ma en gima ler moloyo kuom misengini mag Jehova Nyasaye miwangʼo gi mach.
Ìyókù nínú ọrẹ ohun jíjẹ náà jẹ́ ti Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó jẹ́ ìpín tí ó mọ́ jùlọ nínú ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa.
4 Ka ikelo chiwo mar cham motedie kendo, nyaka obed kek molosi gi mogo mayom ma ok oketie thowi modwal gi mo kata chapat mowir gi mo.
“‘Bí ẹ bá mú ọrẹ ohun jíjẹ, èyí tí a yan lórí ààrò iná, kí ó jẹ́ ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára, àkàrà tí a ṣe láìní ìwúkàrà, tí a sì fi òróró pò àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a ṣe láìní ìwúkàrà èyí tí a fi òróró pò.
5 To ka chiwo mari mar cham en gima otedi e tawo, to enobedi mogo mayom ma ok oketie thowi, kendo moru gi mo.
Bí ọrẹ ẹbọ rẹ bá jẹ́ inú àwo pẹẹrẹ ni o ti ṣe ohun jíjẹ rẹ, kí ó jẹ́ ìyẹ̀fun dáradára tí a fi òróró pò, kò sì gbọdọ̀ ní ìwúkàrà.
6 Poge matindo tindo, ol mo kuome, nikech en misango mar cham.
Rún un kí o sì da òróró sí i lórí, ọrẹ ohun jíjẹ ni.
7 To ka chiwo mari mar cham en gima otedi e tawo, inilose gi mogo mayom kod mo.
Bí ọrẹ ẹbọ rẹ bá jẹ́ ẹbọ ohun jíjẹ, tí a yan nínú apẹ, ìyẹ̀fun dáradára ni kí o fi ṣè é pẹ̀lú òróró.
8 Kel misango mar cham molos gi gigi ne Jehova Nyasaye, kele ne jadolo, mabiro chiwe e kendo mar misango.
Mú ọrẹ ohun jíjẹ tí a fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe wá fún Olúwa gbé e fún àlùfáà, ẹni tí yóò gbe e lọ sí ibi pẹpẹ.
9 Enopog moko kaka pok mar rapar kendo chiw moko e kendo mar misango kaka misango miwangʼo pep madum tik mangʼwe ngʼar ne Jehova Nyasaye.
Àlùfáà yóò sì mú ẹbọ ìrántí nínú ọrẹ ohun jíjẹ yìí, yóò sì sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ tí a fi iná sun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
10 To gima nodongʼ kuom chiwo mari mar cham nobed mar Harun gi yawuote, en gima ler moloyo nikech ogole kuom misango miwangʼo gi mach ne Jehova Nyasaye.
Ìyókù nínú ọrẹ ohun jíjẹ yìí jẹ́ ti Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó jẹ́ èyí tí ó mọ́ jùlọ nínú ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa.
11 Misengini duto mag cham ma uchiwo ni Jehova Nyasaye nyaka bed ma ok oketie thowi, nimar misango ma uwangʼo gi mach ni Jehova Nyasaye kik ketie mor kich kata thowi.
“‘Gbogbo ọrẹ ohun jíjẹ tí ẹ bá mú wá fún Olúwa kò gbọdọ̀ ní ìwúkàrà nínú, nítorí pé ẹ kò gbọdọ̀ sun ohun wíwú tàbí oyin nínú ọrẹ tí ẹ fi iná sun sí Olúwa.
12 To gigo unyalo chiwo ni Jehova Nyasaye kaka misango mar cham mokwongo, makmana kik uwangʼ-gi e kendo mar misango kaka iwangʼo misango madum tik mangʼwe ngʼar.
Ẹ lè mú wọn wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọrẹ àkọ́so ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ mú wọn wá sórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn.
13 To chiwo duto mag cham mondo ituonie chumbi. Kik iwe mak ituone chumbi e misengini magi duto mag mogo kaka nisingori ni Nyasachi; mano emomiyo chumbi nyaka tuonie misengini duto mutimo.
Ẹ fi iyọ̀ dun gbogbo ọrẹ ohun jíjẹ yín. Ẹ má ṣe aláìfi iyọ̀ májẹ̀mú Ọlọ́run yín sínú àwọn ọrẹ ohun jíjẹ yín, ẹ fi iyọ̀ sí gbogbo ọrẹ yín.
14 Ka ukelone Jehova Nyasaye misango mar cham kod cham mokwongo nyak, to nyaka uchiw wiye cham manyien mobul e mach kendo moyoki.
“‘Bí ẹ bá mú ọrẹ ohun jíjẹ ti àkọ́so oko yín wá fún Olúwa kí ẹ mú ọkà tuntun tí a fi iná yan.
15 Keturu mo gi ubani nikech en misango mar cham.
Kí ẹ da òróró lé e lórí, kí ẹ sì fi tùràrí sí i, ó jẹ́ ọrẹ ohun jíjẹ.
16 Jadolo nokaw cham moko mondo oru gi mo kendo enowangʼ-gi kaachiel gi ubani kaka rapar, nikech en misango miwangʼo ni Jehova Nyasaye gi mach.
Àlùfáà yóò sun ẹbọ ìrántí lára ọkà àti òróró náà, pẹ̀lú gbogbo tùràrí gẹ́gẹ́ bí ọrẹ tí a fi iná sun sí Olúwa.