< Jongʼad Bura 8 >

1 Jo-Efraim nopenjo Gideon niya, “Angʼo ma omiyo isetimonwa kama? Angʼo ma notami luongowa kane idhi kedo gi jo-Midian?” Omiyo negidhawo kode matek.
Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
2 To nodwokogi niya, “Angʼo ma asetimo kipimo gi gima usetimo? Donge mzabibu mag Efraim modongʼ ber moloyo keyo maduongʼ mar mzabibu mar Abiezer?
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
3 Nyasaye nochiwo Oreb kod Zeb, jotend jo-Midian, e lwetgi. En angʼo mane anyalo timo kipimo gi gima usetimo?” Kuom mano, ich wangʼ margi norumo.
Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
4 Kata obedo ni Gideon gi joge mia adek nool kamano, negimedo lawo ruodhi mag Midian mi gingʼado aora Jordan.
Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
5 Nowachone jo-Sukoth niya, “Miuru joga ma jolweny makati nikech giol, kendo pod alawo Zeba kod Zalmuna, ma gin ruodhi jo-Midian.”
Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
6 To jotelo mag Sukoth nowacho niya, “Bende usemako Zeba kod Zalmuna? Ere kaka dwami jolweny magi moolgi makati?”
Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
7 Eka Gideon nodwoko niya, “Nikech gima uwacho, ka Jehova Nyasaye osechiwo Zeba gi Zalmuna e lweta, to abiro yuyo ringreu gi pedo kod matata.”
Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
8 Noa kanyo kodhi Peniel kendo ochiwonegi kwayo makamano, to negidwoko mana kaka jo-Sukoth nowacho.
Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
9 Omiyo nowachone jo-Peniel niya, “Ka aduogo gi loch, to abiro muko bath ohinga moger motingʼore gi malo.”
Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
10 Noyudo ka Zeba gi Zalmuna neni Karkor kaachiel gi jolweny mage manyalo romo ji alufu apar gabich, ne gin jolweny mane odongʼ kuom jolweny mag wuok chiengʼ, to jolweny alufu mia achiel gi piero ariyo nonegi e lweny.
Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
11 Gideon nodhi koluwo yo jokwath mantiere yo wuok chiengʼ mar Noba kod Jogbeha mi nodonjo kuom jolweny mamoko apoya.
Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
12 Zeba gi Zalmuna, ma ruodhi ariyo mag Midian, noringo, to nolawogi mi omakogi, kendo makogino nokelo luoro maduongʼ ne jolwenjgi.
Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
13 Bangʼ mano Gideon wuod Joash noduogo koa e lweny koluwo yor Heres.
Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
14 Nomako wuod Sukoth mi openje penjo, kendo wuowino nondikone nying ruodhi piero abiro gabiriyo mag Sukoth.
Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
15 Eka Gideon nobiro mi owachone jo-Sukoth niya, “Eri Zeba gi Zalmuna, mane osemiyo uchaya kuwacho ni, ‘Bende usemako Zeba gi Zalmuna? Ere kaka dwami jolweny magi moolgi makati?’”
Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
16 Nokawo jodong dalano mi okawo pedo kod matata mokumogo jo-Sukoth.
Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
17 Bende nomuko kama oger motingʼore gi malo mar Peniel mi onego jo-dalano.
Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
18 Eka nopenjo Zeba kod Zalmuna niya, “Ne inego ji machalo nade Tabor?” Negidwoke niya, “Ji machalo kodi, ma ngʼato ka ngʼato ne nigi kido machalo mar ruoth.”
Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
19 Gideon nodwoko niya, “Mago ne owetena, yawuot minwa owuon. Akwongʼora gi nying Jehova Nyasaye mangima ni ka dine ingʼwononegi, to dine ok anegou.”
Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
20 Eka nonyiso wuode maduongʼ miluongo ni Jetha niya, “Neg-gi!” To Jetha ne ok owuodho liganglane, nikech ne pod en rawera kendo noluor.
Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
21 Zeba gi Zalmuna nowacho niya, “Bi inegwa mana in iwuon nimar in e ngʼat maduongʼ maratego.” Omiyo Gideon nosudo machiegni kodgi monegogi, bangʼe nokawo pien mane ni e ngʼut ngamia mag-gi.
Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
22 Jo-Israel nowachone Gideon niya, “Bed jatendwa, in kaachiel gi wuodi kod nyakwari ma wuowi, nikech iseresowa e lwet jo-Midian.”
Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
23 To Gideon nokonegi niya, “Ok anabed jatendu, kata wuoda bende ok nobed jatendu. Jehova Nyasaye ema biro bedo jatendu.”
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
24 Kendo nowacho niya, “An-gi kwayo achiel, ni ngʼato ka ngʼato kuomu omiya stadi kuom pok mag gik mane uyako.” Ne en kit jo-Ishmael mondo gilier stadi mar dhahabu e itgi.
Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
25 Negidwoko niya, “En morwa mondo wachiwgi.” Omiyo ne gipedho nanga, kendo ngʼato ka ngʼato nodiro stadi koa kuom gik mane giyako e nangano.
Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
26 Pek mar stadi mag dhahabu mane okwayo ne oromo shekel alufu achiel gi mia abiriyo, ka ok okwano bangli, odeyo kod nengni maralik mirwako gi ruodhi mag Midian kata nyoroche mane ni e ngʼut ngamia margi.
Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
27 Gideon noloso kido mar nyasaye manono mar efod gi dhahabu, ma noketo e dalane miluongo ni Ofra. Jo-Israel duto notimo timbe mag dwanyruok e kindgi giwegi ka gilamo kidono kanyo kendo nobedo obadho ni Gideon kod dalane.
Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
28 Kamano e kaka jo-Midian noloo gi jo-Israel kendo ne ok gichako gitugo lweny moro kendo. E kinde ma Gideon ne pod ngima, pinyno nobedo gi kwe kuom higni piero angʼwen.
Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
29 Jerub-Baal wuod Joash nodok dala.
Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
30 Ne en-gi yawuowi piero abiriyo ma mage owuon, nimar ne en-gi mon mangʼeny.
Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
31 Bende ne en gi jatich madhako mane odak Shekem, mane onywolone wuowi miluongo ni Abimelek.
Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
32 Gideon wuod Joash notho ka en-gi higni mathoth kendo noyike e liend wuon mare Joash man Ofra dala jo-Abiezer.
Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
33 Bangʼ ka Gideon nosetho jo-Israel nochako timo timbe dwanyruok kalamo Baal. Negiketo Baal-Berith kaka nyasachgi,
Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
34 kendo ne ok giparo Jehova Nyasaye ma Nyasachgi, mane oseresogi e lwet jowasikgi duto koni gi koni.
Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
35 Bende negitamore timo ngʼwono ni joka Jerub-Baal (mano en Gideon) kuom gigo mabeyo duto mane osetimonigi.
Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.

< Jongʼad Bura 8 >