< Jongʼad Bura 6 >

1 Jo-Israel nochako otimo timbe mamono e nyim Jehova Nyasaye, kendo kuom higni abiriyo nochiwogi e lwet jo-Midian.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
2 Nikech jo-Midian ne keto ji gi tich matek mar achuna, jo-Israel nogero kuonde pondo e tiend got, rogo kod kuonde moko ma ginyalo dakie.
Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
3 Kinde ka kinde mane jo-Israel opidho cham mag-gi, jo-Midian, jo-Amalek kod jogo moa yo wuok chiengʼ ne monjo piny.
Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
4 Negichokore e pinyno kendo negiketho cham duto nyaka Gaza kendo onge gima ngima kaka rombe kata dhok kata punde mane giweyo e piny Israel.
Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 Negibiro gi jambgi kod hembegi machal gi kweth mar dede. Kar kwan jogo kaachiel gi ngamia mag-gi ne tek ngʼeyo, kendo negimonjo pinyno mi gikethe.
Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
6 Jo-Midian nokelone jo-Israel dhier maduongʼ mane giywakne Jehova Nyasaye mondo okonygi.
Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 Ka jo-Israel noywak ne Jehova Nyasaye nikech jo-Midian,
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 nooronegi janabi, mane owachonegi niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye ma Nyasach Israel, wacho: Nagolou e piny Misri, kuma ne unie wasumbini.
Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
9 Ne agolou e loch jo-Misri kendo aresou e lwet joma ne sandou. Ne ariembogi gia e nyimu kendo amiyou pinygi.
Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 Ne awachonu niya, ‘An Jehova Nyasaye ma Nyasachu; kik ulam nyiseche jo-Amor, makoro udak e pinygi.’ To pod ok udewo winja.”
Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
11 Malaika mar Jehova Nyasaye nobiro mobet e tiend yiend ober moro mantiere Ofra mane mar Joash ma ja-Abiezer, kama wuod Gideon ne dinoe ngano mondo kik jo-Midian yude.
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
12 Ka malaika nofwenyore ne Gideon, nowacho niya, “Jehova Nyasaye ni kodi, in jalweny maratego.”
Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
13 To Gideon nodwoke niya, “Ruodha, ka Jehova Nyasaye nikodwa, to angʼo momiyo magi duto osetimorenwa? Ere honni duto mane kwerewa onyisowa kagiwacho ni, ‘Donge Jehova Nyasaye ema nogolowa e piny Misri?’ To koro Jehova Nyasaye osejwangʼowa mi oketowa e lwet jo-Midian.”
Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
14 Jehova Nyasaye nodwoke niya, “Gi teko ma in-go, dhiyo kendo ires jo-Israel e lwet jo-Midian. Donge an ema aori?”
Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
15 Gideon nopenje niya, “To Ruoth, ere kaka anyalo reso jo-Israel? Anywolana ema nyape mogik ei Manase, kendo an ema atin e odwa.”
Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
16 Jehova Nyasaye nodwoko niya, “Anabed kodi, kendo ibiro nego jo-Midian duto.”
Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
17 Gideon nodwoko niya, “Ka koro ayudo ngʼwono e nyim wangʼi, to miya ranyisi ni in ema iwuoyo koda.
Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
18 Kiyie to kik iwuog ka nyaka abi kendo akel misango mara mi achiwe e nyimi.” To Jehova Nyasaye nowacho niya, “Abiro rito nyaka iduogi.”
Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
19 Gideon nodhi, moyangʼo nyadiel kendo otedo, bangʼe nokawo mogo madirom kilo piero ariyo gariyo mi olosogo makati ma ok oketie thowi koketo ringʼo e adita kod kate e tawo, nokelogi oko kendo ochiwogi ne Jehova Nyasaye e tiend yiend ober.
Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
20 Malaika mar Nyasaye nowachone niya, “Kaw ringʼono kod makati ma ok oketie thowi, ketgi e lwandani, kendo iol kado piny.” Kendo Gideon notimo kamano.
Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
21 Malaika mar Jehova Nyasaye nomulo ringʼo kod makati ma ok oketie thowi gi wi luth mane otingʼo e lwete. Mach nowuok e lwanda, mowangʼo ringʼo kod makati pep. Kendo malaika mar Jehova Nyasaye nolal nono e wangʼe.
Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
22 Kane Gideon ofwenyo ni ne en malaika mar Jehova Nyasaye, nowacho niya, “Yaye, Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto! Aseneno malaika mar Jehova Nyasaye wangʼ gi wangʼ!”
Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
23 To Jehova Nyasaye nowachone niya, “Bed gi kwe! Kik iluor. Ok nitho.”
Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
24 Omiyo Gideon nogero ne Jehova Nyasaye kendo mar misango mi oluongo kanyo ni Jehova Nyasaye en Kwe. Kendono pod ni Ofra kuno e piny jo-Abiezer nyaka chil kawuono.
Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
25 Otienono Jehova Nyasaye nowachone niya, “Kaw rwath mar ariyo koa e kweth wuonu, ma hike abiriyo. Muk kendo wuonu mar misango ne Baal kendo ingʼad siro mar Ashera man bute.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
26 Eka iger kendo mar misango malongʼo ne Jehova Nyasaye ma Nyasachu ewi kama otingʼore maloni mondo ichiw rwath mar ariyo kaka misango miwangʼo pep, kitiyo gi yiend Ashera mane ingʼado.”
Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
27 Omiyo Gideon nokawo jotijene apar kendo notimo kaka Jehova Nyasaye nowachone. Notimo tijno gotieno ma ok odiechiengʼ nikech noluoro jo-dalagi kod joodgi.
Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
28 Gokinyi ka joma ni e dalano nochiewo, negiyudo ka kar wangʼo misango mar Baal omuki, ka yiend Ashera mane ni bute bende ongʼadi kendo ka rwath mar ariyo ochiw ka misango e kendo mar misango mane oger manyien!
Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
29 Negipenjore kendgi niya, “En ngʼa motimo ma?” Kane ginono matut, nowachnegi niya, “Gideon wuod Joash ema osetimo ma.”
Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
30 Jo-dalano nowachone Joash niya, “Gol wuodi oko. Nyaka otho nikech oseketho kendo mar misango mar Baal kendo ongʼado yiend Ashera man bute.”
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
31 To Joash nodwoko oganda mager mane ni bute niya, “Un ema uwuoyo e lo Baal? Utemo rese? Ngʼato angʼata mokedone enonege gokinyi! Ka Baal en nyasaye, to onyalo resore kende owuon kuom ngʼama muko kendone mar misango.”
Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
32 Omiyo odiechiengno negichako Gideon ni Jerub-Baal, kagiwacho niya, “We Baal otiek kode,” nikech nomuko kendo mar misango mar Baal.
Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
33 Koro jo-Midian duto gi jo-Amalek kod jogo moa yo wuok chiengʼ noriwore e lweny ma gingʼado aora Jordan kendo gigo kambi e Holo mar Jezreel.
Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
34 Eka Roho mar Jehova Nyasaye nobiro kuom Gideon, kendo nogoyo turumbete, kowachoni jo-Abiezer mondo oluw bangʼe.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
35 Nooro joote odhi Manase duto, koluongogi mondo gitingʼ gige lweny, kendo gidhi ir Asher, Zebulun kod Naftali, mondo gin bende gidhi girom kode.
Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
36 Gideon nowachone Nyasaye niya, “Ka inires jo-Israel kokalo kuoma kaka ne isingo,
Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
37 to abiro keto pien rombo kar dino cham. Kapo ni pien rombono thoo omokoe, to lowo molwore odongʼ kotwo, eka anangʼe ni ibiro reso jo-Israel gi lweta kaka ne iwacho.”
kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
38 Kendo mano e gima notimore. Gideon nochiewo gokinyi mangʼich; nobiyo pien-no ma thoo owuok madirom bakul achiel.
Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
39 Eka Gideon nowachone Nyasaye niya, “Kik iyi wangʼ koda. We mondo akwayi kwayo achiel makende. Yiena mana tem achiel kende gi pien. E kindeno, pien mondo obed kotwo, to lowo molwore obed gi thoo.”
Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
40 Otienono Nyasaye notimo kamano. Pien kende ema ne otwo; to lowo duto molwore ne thoo omoke.
Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.

< Jongʼad Bura 6 >