< Joshua 24 >

1 Bangʼe Joshua nochoko dhout Israel duto kama iluongo ni Shekem. Noluongo jodongo, jotelo, jongʼad bura kod jotelo mamoko mag Israel mi gidhi e nyim Nyasaye.
Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
2 Joshua nowachone ji duto niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye, ma Nyasach Israel wacho, Chon gi lala kwereu, motingʼo nyaka Tera ma wuon Ibrahim kod Nahor, nodak but Aora Yufrate kendo negilamo nyiseche manono.
Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
3 Makmana nagolo wuonu Ibrahim oa e pinyno machiegni gi Aora Yufrate mi atelone e piny Kanaan duto kendo amiye nyikwayo mathoth. Ne amiye Isaka,
Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
4 to Isaka namiyo Jakobo kod Esau. Ne awalo piny Seir manie got ne Esau, to Jakobo gi nyithinde nodhi Misri.
àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
5 “‘Bangʼe ne aoro Musa gi Harun, kendo ne agoyo jo-Misri gi tuoche kanyo, bangʼe agolou oko.
“‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
6 Kane agolo wuoneu Misri, ne uchopo e nam, kendo jo-Misri nolawou gi geche kod jogo mariambo farese nyaka e Nam Makwar.
Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
7 To ne giywakne Jehova Nyasaye mondo okonygi, omiyo ne oketo mudho e kindu gi jo-Misri; mi nam oimogi. Ne uneno gima ne atimone jo-Misri. Bangʼ mano nudak e thim kuom ndalo marabora.
Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
8 “‘Ne akelou nyaka e piny jo-Amor manodak yo wuok chiengʼ mar aora Jordan. Negikedo kodu, to naketogi e lwetu. Ne atiekogi chuth e nyimu, mi ukawo pinygi.
“‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
9 Kane Balak wuod Zipor, ma ruodh Moab, ne ikore mondo oked gi Israel, nooro Balaam wuod Beor mondo okwongʼu.
Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
10 To ne ok anyal chiko ita ne Balaam, omiyo nogwedhou mogundho, mi nagolou oko e lwete.
Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
11 “‘Bangʼe ne ungʼado aora Jordan mi ubiro Jeriko. Joma odak Jeriko, kaka jo-Amor, jo-Perizi, jo-Kanaan, jo-Hiti, jo-Girgash, jo-Hivi, gi jo-Jebus nokedo kodu, to ne achiwogi duto e lwetu.
“‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
12 Ne amiyo kibaji omakogi ma giringo e nyimu, kaachiel gi ruodhi jo-Amor ariyo. Ne ok utimo ma gi liganglau uwegi kod atungʼ.
Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
13 Omiyo ne amiyou piny mane ok utiyone kod mier madongo mane ok ugero; mi udak kanyo kendo uchamo olemb mzabibu kod zeituni ma bende ne ok upidho.’
Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
14 “Omiyo koro luoruru Jehova Nyasaye kendo beduru joratiro kinde duto kutiyone. Wituru oko nyiseche manono mag kwereu mane gilamo yo Aora Yufrate kod e piny Misri, mondo uti ne Jehova Nyasaye.
“Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
15 To ka dipo ni tiyone Jehova Nyasaye ok miu mor, to kawuononi yier aneuru ngʼama ubiro tiyone, kata ka en nyiseche manono mane kwereu tiyone e Aora Yufrate, kata en nyiseche manono mag jo-Amor, modak e pinygi. Makmana an gi jooda duto, wabiro tiyone Jehova Nyasaye.”
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
16 Eka ji nodwoko niya, “Mad gima chal kamano kik timrenwa ka wajwangʼo Jehova Nyasaye, mondo watine nyiseche manono!
Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
17 En Jehova Nyasaye ma Nyasachwa owuon mane ogolowa gi kwerewa e piny Misri, e piny mane wan wasumbini, kendo motimo ranyisi madongo-go ka waneno. Ne oritowa e wuodhwa duto kendo e kind ogendini duto mane wakalo eigi.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
18 Kendo Jehova Nyasaye ne oriembo ogendini duto e nyimwa, kaachiel gi jo-Amor, mane odak e pinyno. Wan bende wabiro tiyone Jehova Nyasaye, nikech en e Nyasachwa.”
Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
19 Joshua nowachone ji niya, “Ok unyal tiyone Jehova Nyasaye. En Nyasaye maler, en Nyasaye ma janyiego. Ok obi wenu kuom wich teko maru kod richo mutimo.
Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
20 Ka ungʼanyo uweyo Jehova Nyasaye mi utiyo ne nyiseche manono, to obiro lokore mi okelnu thagruok kendo enotieku duto, kata obedo ni ne osedoko jakoru kamano.”
Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
21 To jo-Israel nodwoko Joshua niya, “Ooyo! Wabiro tiyone Jehova Nyasaye.”
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
22 Bangʼe Joshua nowacho niya, “Un uwegi usebedo joneno magu kuom yiero mondo uti ne Jehova Nyasaye.” Negidwoko niya, “Ee, wan joneno.”
Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
23 Joshua nowacho niya, “Koro wituru nyiseche manono manie dieru mondo uchiw chunyu ni tiyo ne Jehova Nyasaye, ma Nyasach Israel.”
Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
24 To jogo nowachone Joshua niya, “Wabiro tiyone Jehova Nyasaye ma Nyasachwa kendo wanamiye luor.”
Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
25 E odiechiengno Joshua noketo singruok ne jogo, kendo kane gin Shekem nomiyogi chike monego gilu.
Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
26 Joshua nondiko gigo duto piny e Kitabu mar Chik mar Nyasaye. Bangʼe nokawo kidi maduongʼ mi okete maber e tiend yiend ober but kama ler mar Jehova Nyasaye.
Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
27 Nowachone jogo niya, “Neuru! Kidini biro bedo janeno kuomu. Osewinjo weche duto ma Jehova Nyasaye osewachonwa. Obiro bedo janeno kuomu ka ubedo jo-miriambo ne Nyasachu.”
“E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
28 Bangʼe Joshua nogolo ji duto mondo odhi kuondegi mane opognigi.
Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
29 Bangʼ mago duto, Joshua wuod Nun, jatich Jehova Nyasaye, notho ka en gi higni mia achiel gapar.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
30 Kendo ne giike e lope mane opogne, mantiere Timnath Sera e piny gode mag Efraim, mantiere yo nyandwat mar Gash.
Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
31 Jo-Israel notiyone Jehova Nyasaye e ndalo duto mag ngima Joshua kod jodongo mane osedak higni moloye, kendo mane nigi lony kuom gik moko duto mane Jehova Nyasaye osetimo ni jo-Israel.
Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
32 To choke Josef, mane jo-Israel nobiro godo koa Misri, noiki Shekem e pinyno mane Jakobo ongʼiewo fedha mia achiel koa kuom yawuot Hamor, ma wuon Shekem. Ma nobedo kaka pok mar nyikwa Josef.
Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
33 Eliazar wuod Harun bende notho kendo noyike Gibea, kama nopogne wuode Finehas e piny gode mag Efraim.
Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.

< Joshua 24 >