< Joshua 2 >

1 Bangʼe Joshua wuod Nun nooro jonon piny ariyo lingʼ-lingʼ moa Shitim. Nowachonegi niya, “Dhiuru, ungʼi pinyni, to moloyo Jeriko.” Omiyo negidhi ma gidonjo e od dhako moro mandhaga ma nyinge Rahab, mi gidak kanyo.
Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
2 Ruodh Jeriko nonyisi niya, “Ngʼe ni jo-Israel moko osebiro ka gotienoni mondo onon pinywa.”
A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
3 Omiyo ruodh Jeriko nooro wach ni Rahab niya, “Gol oko jogo mane obiro iri kendo odonjo e odi, nikech gisebiro mondo gitim nonro ma lingʼ-lingʼ e pinyni duto.”
Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
4 Kata kamano, Rahab nosekawo ji ariyogi kendo opandogi. Nowacho niya, “En adier, ni jogi nobiro ira, to ne ok angʼeyo ni gia kanye.
Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
5 E seche mag angʼich welo, e sa michiegoe dhoranga dala maduongʼ, jogi nowuok. Ok angʼeyo yo mane gidhiyoe. Ringuru bangʼ-gi piyo. Unyalo makogi.”
Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
6 To chutho, noyudo ka osepando jogi ewi tado e bwo othith mane opedhi ewi tado kanyo.
(Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
7 Omiyo oganda mar ruodh pinyno nowuok piyo ka gilawogi e yo mochiko aora Jordan, kendo mana gisano ka jogo mane lawogi nosewuok oko, dhorangajno nolor.
Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
8 Kane jonon pinygo ne pok odhi nindo, dhakoni noidho modhi ewi tado,
Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
9 kendo mowachonegi niya, “Angʼeyo ni Jehova Nyasaye osemiyou pinyni kendo mano osemiyo luoro omako ngʼato ka ngʼato kuomwa, omiyo joma odak e pinyni kihondko osemako nikech un.
Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
10 Wasewinjo kaka Jehova Nyasaye nomiyo pi Nam Makwar oduono kane uwuok e piny Misri, kendo gima ne utimone Sihon kod Og, ruodhi ariyo mag jo-Amor modak yo wuok chiengʼ mar aora Jordan, mane uketho chuth.
Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
11 Kane wawinjo wachno, to kihondko nomakowa kendo chir duto mane ngʼato angʼata nigo norumo nikech un, kendo nikech Jehova Nyasaye ma Nyasachu en Nyasaye manie polo malo kendo e piny mwalo.
Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
12 “Kuom mano, kwongʼrenauru gi Jehova Nyasaye ni ubiro ngʼwonone jooda, nikech an bende asetimonu ngʼwono. Singrenauru
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
13 ni ubiro ngʼwonone wuonwa kod minwa, owetena kod nyiminena, kod jogegi duto, kendo ni ubiro resowa mondo kik watho.”
pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
14 Jogi nowachone adier niya, “Ngimau en ngimawa! Ka ok uwacho gino ma watimo, to wabiro bedo kodu gi ngʼwono kod ratiro e ndalo ma Jehova Nyasaye nomiwa pinyni.”
“Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
15 Omiyo nolorogi piny gi tol ka giluwo dirisa, nikech ot mane odakie ne ochwogi e kor ohinga mar dala maduongʼ.
Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
16 E sa onogo nowachonegi niya, “Dhiuru e got mondo joma lawou kik yudu. Ponduru kuno kuom ndalo adek nyaka giduogi; eka udhi nyime giwuodhu.”
Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
17 Jogi nowachone niya, “Kwongʼ ma isemiyo wakwongʼore godo ok otweyowa,
Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
18 makmana, chiengʼ mwadonjo e pinyni, to nyaka itwe tol makwarni e dirisa kama ilorowanie, kendo nyaka ikel wuonu gi minu, oweteni gi joodi duto ei odi.
Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
19 Ka dipo ni ngʼato owuok e odi modhi e yore mag mier, rembe enobed e wiye owuon; ok enobed wachwa. To ne ngʼatno manobed kodi ei ot, rembe nobedi e wiwa ka dipo ni lwedo moro nomule.
Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
20 Makmana, ka dipo ni iwacho gino ma watimo, to inigonywa kuom kwongʼruok mane iketowa wakwongʼore godo.”
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
21 Nowachonegi niya, “Wawinjore! Kendo mondo obed kaka uwachono.” Omiyo ne ogologi mi gidhi. Bangʼe notweyo tol makwar e dirisa.
Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
22 Kane gisea, negidhi nyaka e gode mi gidak kuno kuom ndalo adek, manyaka joma ne lawogi otieko manyo kuonde duto ka giluwo yo mi gidwogo ma ok giyudogi.
Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
23 Eka jonon piny ariyogi nolor oa e gode. Negingʼado aora, mi gidhi ir Joshua wuod Nun, kendo giwachone gigo duto mane otimorenigi.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
24 Negiwachone Joshua niya, “Adiera, Jehova Nyasaye osechiwo pinyni duto e lwetwa, bende jogo modak e pinyno kihondko osemako nikech wan.”
Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”

< Joshua 2 >