< Jeremia 6 >

1 “Un jo-Benjamin, ringuru utony! Ringuru ua Jerusalem! Gouru turumbete Tekoa! Keturu ranyisi ewi Beth Hakerem! Nimar masira aa yo nyandwat, kod kethruok malich.
“Ẹ̀yin ènìyàn Benjamini, sá sí ibi ààbò! Ẹ sá kúrò ní Jerusalẹmu. Ẹ fọn fèrè ní Tekoa! Kí ẹ gbé àmì sókè lórí Beti-Hakeremu! Nítorí àjálù farahàn láti àríwá, àní ìparun tí ó lágbára.
2 Anatiek nyar Sayun, ma ber neno kendo ma dende yom.
Èmi yóò pa ọmọbìnrin Sioni run, tí ó jẹ́ arẹwà àti ẹlẹgẹ́.
3 Jokwath kod jambgi noked kode; ginigur hembegi molwore, ka moro ka moro rito kare owuon.”
Olùṣọ́-àgùntàn pẹ̀lú agbo wọn yóò gbóguntì wọ́n. Wọn yóò pa àgọ́ yí wọn ká, olúkúlùkù yóò máa jẹ ní ilé rẹ̀.”
4 “Ikri mar kedo kode! Wuoguru, wadhi wamonjgi e dier odiechiengʼ! To mano kaka ler mar odiechiengʼ bedo ma dimdim, kendo tipo mag odhiambo yware.
“Ẹ ya ará yín sí mímọ́ láti bá a jagun! Dìde, kí a kọlù ú ní ìgbà ọ̀sán! Ṣùgbọ́n ó ṣe, nítorí ọjọ́ lọ tán, ọjọ́ alẹ́ náà sì gùn sí i.
5 Omiyo aa malo, wamonjgi gotieno kendo waketh ohingane motegno!”
Nítorí náà, ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú ní àṣálẹ́ kí a sì ba odi alágbára rẹ̀ jẹ́.”
6 Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego wacho: “Ngʼad yiende kendo iger pidhe mondo wamonj Jerusalem. Dala maduongʼni nyaka kum; nikech opongʼ gi joma hinyo jowadgi.
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ ké àwọn igi náà lulẹ̀ kí ẹ sì mọ odi ààbò yí Jerusalẹmu ká. Èyí ni ìlú títóbi tí a ó bẹ̀wò, nítorí pé ó kún fún ìninilára.
7 Kaka soko olo pige oko, e kaka en bende oolo timbene mamono. Lweny kod kethruok mor e iye; tuone kod adhondene osiko e nyima.
Gẹ́gẹ́ bí kànga ṣe ń da omi inú rẹ̀ sílẹ̀, náà ni ó ń tú ìwà búburú rẹ̀ jáde. Ìwà ipá àti ìparun ń tún pariwo nínú rẹ̀; nígbà gbogbo ni àìsàn àti ọgbẹ́ rẹ̀ ń wà níwájú mi.
8 Winj siem, yaye Jerusalem, ka ok kamano to abiro weyi, mi awe pinyi nono, ma ngʼato angʼata ok nyal dak e iye.”
Ìwọ Jerusalẹmu, gba ìkìlọ̀, kí Èmi kí ó má ba à lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, kí n sì sọ ilẹ̀ rẹ di ahoro, tí kò ní ní olùgbé.”
9 Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego wacho: “Mad gidwog jo-Israel modongʼ kaka jochok olemb mzabibu; ngʼauru bedeu e bede yath, mana kaka ngʼama pono olemo.”
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Jẹ́ kí wọn pèsè ìyókù Israẹli ní tónítóní bí àjàrà; na ọwọ́ rẹ sí àwọn ẹ̀ka nì lẹ́ẹ̀kan sí i gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ti í kó èso àjàrà jọ.”
10 En ngʼa ma anyalo wuoyogo kendo miyo siemni? En ngʼa manyalo winja? Itgi odino omiyo ok ginyal winjo wach. Wach Jehova Nyasaye chwanyogi; ok gine gima ber kuome.
Ta ni ẹni tí mo lè bá sọ̀rọ̀ àti tí mo lè fún ní ìmọ̀ràn? Ta ni yóò tẹ́tí sílẹ̀ sí mi? Etí wọn ti di, nítorí náà wọn kò lè gbọ́. Ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ ohun búburú sí wọn, wọn kò sì ní inú dídùn nínú rẹ̀.
11 To apongʼ gi mirima mar Jehova Nyasaye, kendo ok anyal lingʼ kode. “Ole oko kuom nyithindo manie yore, kendo kuom yawuowi mochokore kanyakla; dichwo kaachiel gi dhako gini nomaki, kod joma oti, jogo mahikgi oniangʼ.
Èmi kún fún ìbínú Olúwa, èmi kò sì le è pa á mọ́ra. “Tú u sí orí àwọn ọmọ ńigboro, àti sórí àwọn ọmọkùnrin tí wọn kó ra wọn jọ pọ̀, àti ọkọ àti aya ni a ò mú sínú rẹ̀, àti àwọn arúgbó tí ó ní ọjọ́ kíkún lórí.
12 Utegi ibiro miyo joma moko, kaachiel gi puothegi kod mondegi, ka arieyo lweta kuom jogo modak e piny,” Jehova Nyasaye owacho.
Ilé wọn o sì di ti ẹlòmíràn, oko wọn àti àwọn aya wọn, nígbà tí èmi bá na ọwọ́ mi sí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí.
13 “Chakre ngʼama tin nyaka ngʼama duongʼ, giduto girikni ka gidwaro mwandu e yor miganga; jonabi kod jodolo chalre, giduto gin jo-miriambo.
“Láti orí ẹni tí ó kéré sí orí ẹni tí ó tóbi ju, gbogbo wọn ni ó sì ní ojúkòkòrò fún èrè, àwọn wòlíì àti àlùfáà lápapọ̀ sì kún fún ẹ̀tàn.
14 Githiedho adhonde mag joga mana ka gima ok en gima lich. Giwacho niya, ‘Kwe, kwe,’ kata mana ka kwe onge.
Wọ́n sì ń wo ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi bí ẹni pé kò tó nǹkan. Wọ́n ń wí pé, ‘Àlàáfíà, Àlàáfíà,’ nígbà tí kò sì sí àlàáfíà.
15 Bende gin-gi wichkuot kuom timbegi makwero? Ooyo, gionge wichkuot kata mana matin; ok gingʼeyo kata kaka ginyalo wuondore. Omiyo gibiro podho mana kaka joma moko mopodho; kendo ibiro dwokgi piny kakumogi,” Jehova Nyasaye owacho.
Ojú ha a tì wọ́n nítorí ìwà ìríra wọn bí? Rárá, wọn kò ní ìtìjú mọ́, wọn kò tilẹ̀ ní oorun ìtìjú. Nítorí náà, wọn ó ṣubú láàrín àwọn tó ṣubú, a ó sì ké wọn lulẹ̀ nígbà tí mo bá bẹ̀ wọ́n wò,” ni Olúwa wí.
16 Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Chunguru e akek yore kendo urang wangʼ yore machon; penjuru kuma yo maber nitie, mondo uwuothie, kendo unuyud yweyo e chunyu. To ne uwacho ni, ‘Ok wanaluwe.’
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ẹ dúró sí ìkóríta, kí ẹ sì wò, ẹ béèrè fún ọ̀nà àtijọ́, ẹ béèrè ọ̀nà dáradára nì, kí ẹ rìn nínú rẹ, ẹ̀yin yóò sì rí ìsinmi fún ọkàn yín. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa kì yóò rìn nínú rẹ̀.’
17 Ne aketonu jorito kendo awacho, ‘Chikuru itu ne turumbete!’ To ne uwacho, ‘Ok wanachik itwa.’
Èmi yan olùṣọ́ fún un yín, mo sì wí pé: ‘Tẹ́tí sí dídún fèrè náà,’ ẹ̀yìn wí pé, ‘Àwa kì yóò tẹ́tí sílẹ̀.’
18 Omiyo winjuru, yaye un ogendini; ranguru malongʼo, yaye un joneno, gima biro timore negi.
Nítorí náà, gbọ́ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè; kíyèsi, kí ẹ sì jẹ́ ẹlẹ́rìí, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí wọn.
19 Winji, yaye piny: Akelo masira ne jogi, ma en olemo mar pachgi maricho, nikech gitamore winjo wechena, kendo gisedagi chikna.
Gbọ́, ìwọ ayé! Mò ń mú ìparun bọ̀ sórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, èso ìrò inú wọn, nítorí wọn kò fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n sì ti kọ òfin mi sílẹ̀.
20 Ere tiend ubani mangʼwe ngʼar moa kuom Sheba kata niangʼ ma milimili moa e piny mabor? Chiwo magu mag misengini miwangʼo pep ok ayiego; misango magu ok mora.”
Èrè wo ni ó wà fún mi nínú tùràrí láti Ṣeba wá, tàbí èso dáradára láti ilẹ̀ jíjìn réré? Ẹbọ sísun yín kò ṣe ìtẹ́wọ́gbà, ọrẹ yín kò sì wù mí.”
21 Emomiyo ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Anaket rachwany e nyim jogi. Wuone kod yawuowi nochwanyre kuomgi; jogo modak mokiewo kodgi kod osiepe nolal nono.”
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Èmi yóò gbé ohun ìdènà síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Àwọn baba àti ọmọ yóò jùmọ̀ ṣubú lù wọ́n, àwọn aládùúgbò àti ọ̀rẹ́ yóò ṣègbé.”
22 Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Neuru, jolweny biro koa e piny man yo nyandwat; oganda maduongʼ itugo koa e tunge piny.
Báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, àwọn ọmọ-ogun ń bọ̀ wá láti ilẹ̀ àríwá, a ó sì gbé orílẹ̀-èdè ńlá dìde láti òpin ayé wá.
23 Gimanore gi atungʼ kod tongʼ; giger kendo gionge ngʼwono. Gimor ka nam mogingore ka giriembo faresegi; gibiro ka ji mochanore komanore gi gige lweny mondo gimonju, yaye Nyar Sayun.”
Wọ́n sì dìmọ́ra pẹ̀lú ọrun àti ọ̀kọ̀, wọ́n jẹ́ ẹni ibi, wọn kò sì ní àánú. Wọ́n ń hó bí omi Òkun, bí wọ́n ti ṣe ń gun àwọn ẹṣin wọn lọ; wọ́n sì wá bí ọkùnrin tí yóò jà ọ́ lógun, ìwọ ọmọbìnrin Sioni.”
24 Wasewinjo humbgi, kendo bedewa onge gi teko. Rem malich osemakowa, ka rem mar dhako mamuoch kayo.
Àwa ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wa sì di rírọ, ìrora sì mú wa bí obìnrin tí ń rọbí.
25 Kik udhi e puothe kata uwuothie yore, nimar jasigu nigi ligangla, kendo nitie luoro kamoro amora.
Má ṣe jáde lọ sí orí pápá tàbí kí o máa rìn ní àwọn ojú ọ̀nà, nítorí ọ̀tá náà ní idà, ìpayà sì wà níbi gbogbo.
26 Yaye joga, rwakuru lepu mag ywak kendo ngʼielreuru e buru; gouru nduru ka udengo malit mana ka ngʼama ywago wuode achiel kende, nimar apoya nono jaketh gik moko biro podho kuomwa.
Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀, kí ẹ sì sùn nínú eérú, ẹ ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ìpohùnréré ẹkún gẹ́gẹ́ bí i lórí ọmọkùnrin yín kan ṣoṣo nítorí pé lójijì ni àwọn apanirun yóò kọlù wá.
27 “Aseketi rapim mipimogo chumbe to joga kama ikunye chumbe, mondo mi ingʼi kendo ipim yoregi.
“Èmi ti fi ẹ́ ṣe ẹni tí yóò máa yọ́ irú àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bi irin tútù, kí wọn kí ó lè ṣe àkíyèsí, kí ó sì dán ọ̀nà wọn wò.
28 Giduto gin jongʼanyo ma tokgi tek ta, ka gidhi ka gi kacha mar kuotho. Gin nyinyo kod chuma; giduto gin jomecho.
Ọlọ́tẹ̀ tí ọkàn rẹ̀ le ní gbogbo wọn. Wọ́n ń lọ káàkiri láti sọ̀rọ̀-òdì. Wọ́n jẹ́ idẹ àti irin, wọ́n sì kún fún ìwà ìbàjẹ́.
29 Kata obedo ni jotheth moko mach matek mondo oleny fedha, kendo opwodhi, to mano en mana kayiem nono; kamano bende joma richo ok nyal pwodhore.
Ewìrì a fẹ́ná kíkankíkan, kí ó lè yọ́ òjé, ẹni tí ń yọ́ ọ ń yọ́ ọ lásán; a kò si ya ènìyàn búburú kúrò.
30 Iluongogi ni fedha mojwangʼ, nikech Jehova Nyasaye osejwangʼogi.”
A pè wọ́n ní fàdákà tí a kọ̀sílẹ̀, nítorí Olúwa ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀.”

< Jeremia 6 >