< Jeremia 49 >

1 Wach kuom jo-Amon: Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Onge yawuowi e Israel? Oonge gi jarit girkeni mage? To kare angʼo momiyo Molek osekawo mwandu Gad? Angʼo momiyo joge odak e dalane?”
Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
2 Jehova Nyasaye wacho niya, “To ndalo biro, ma anagoye koko mar lweny mondo oked gi Raba mar jo-Amon; enobed pith mar kethruok, kendo gwenge molworogi nowangʼ. Eka Israel noriemb jogo mane oriembogi,” Jehova Nyasaye ema owacho.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
3 “Dengi, yaye Heshbon, nimar Ai okethi! Ywaguru, yaye joma odak Raba! Rwakuru lepu mag ywak kendo uywagi; ringuru koni gi koni, e alwora mar dala, nimar Molek noter e twech, kaachiel gi jodolo mage kod jotelo mage.
“Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
4 Angʼo momiyo usungoru kuom holo mau, sungruok kuom holo mau manyak? Yaye nyako ma ok ja-ratiro, igeno kuom mwandu magi kendo iwacho niya, Ngʼama biro monja?
Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
5 Anakel luoro kuomu koa kuom jogo duto man butu,” Ruoth, Jehova Nyasaye Maratego ema owacho. “Un duto noriembu, kendo onge ngʼama nochok joma noringo moke.
Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 “Kata kamano bangʼe, anaduog mwandu jo-Amon,” Jehova Nyasaye ema owacho.
“Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
7 Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego wacho kuom Edom: “Bende pod nitie rieko ei Teman? To puonj oselalne jorieko? To rieko mag-gi osetop?
Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
8 Lokreuru kendo uringi, ponduru e rogo mopandore, un joma odak Dedan, nimar anakel masira ne Esau e kinde ma anakume.
Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
9 Ka jopon olemb mzabibu obiro iru, donge digiwe olemb mzabibu matin? Ka jokwoge obiro gotieno, donge gibiro kwalo mwandu magu kaka ginyalo?
Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
10 To analony Esau duk; anael kuondege malingʼ-lingʼ, mondo omi kik opondi. Nyithinde, wedene gi jomodak bute nolal nono, kendo ok nochak obed chutho.
Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
11 Weuru kiye mau; anares ngimagi. Mondu duto ma chwogi otho, bende nyalo keto geno mag-gi kuoma.”
Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
12 Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Ka jogo ma ok owinjore omadh kikombe nyaka madhe, to angʼo momiyo ok anyal kumi? Ok initony ma ok okumi, to nyaka imadhe.”
Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
13 Jehova Nyasaye wacho niya, “Akwongʼora gi nyinga awuon, ni Bozra nokethi kendo nobed gir bwogo ji, gir jaro kendo nobed gir kwongʼ, kendo mieche duto nokethi chuth.”
Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
14 Asewinjo wach koa kuom Jehova Nyasaye kama: Jaote oseor mondo owach ne ogendini niya, “Chokreuru mondo umonje! Chungʼuru malo wadhi e kedo!”
Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
15 “Koro abiro miyo udok matin e kind ogendini, kendo joma ijaro e dier ji.
“Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
16 Luoro musemiyo ji kod sunga manie chunyu osewuondou, un jogo modak e kind lwendni, modak kuonde motingʼore gi malo mar got. Kata obedo ni ugero uteu mabor ka od otenga, koa kuno abiro dwokou piny,” Jehova Nyasaye owacho.
Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
17 “Edom nobed gima bwogo ji; jogo duto makalo bute nohum nono, kendo gininyiere ka gineno adhondene duto.”
“Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
18 Jehova Nyasaye wacho niya, “Mana kaka Sodom gi Gomora nokethi, kaachiel gi mier mokiewo kodgi, e kaka en bende nobedi maonge ngʼato angʼata modak kanyo kendo.
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
19 “Ka sibuor mabiro koa e bungu moyugno mar Jordan nyaka kar kwath man-gi lum, anariemb Edom oa e pinye kadiemo wangʼ. En ngʼa mowal manyalo yiero ne ma? En ngʼa machalo koda kendo manyalo chungʼ koda? Koso jakwath mane manyalo chungʼ koda?”
“Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
20 Emomiyo, winj gima Jehova Nyasaye osechano timo ne Edom, gima oseramo ni nyaka otimne joma odak Teman: Nyithi rombe bende nokaw; enoketh chuth kuondegi mag kwath nikech gin.
Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
21 Piny noyiengni kowinjo ni ologi; ywakgi nowinjre nyaka e Nam Makwar.
Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
22 Ne! Otenga nofu kochomo malo kendo piny koyaro bwombene ewi Bozra. E odiechiengno chunje jolweny mag Edom nochal gi chuny dhako mamuoch kayo.
Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
23 Kuom Damaski: “Hamath gi Arpad luoro omako, nimar giwinjo wach marach, chunygi omoko, kendo nigi chandruok ka nam mogingore.
Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
24 Damaski osebedo maonge teko, osea gi ngʼwech, kendo achiedh-nade osemake; lit gi rem osemake, kaka rem mar dhako mamuoch kayo.
Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
25 Angʼo momiyo ok osejwangʼ dala maduongʼ mongʼere; dala mamor godo?
Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
26 Adiera, joge matindo nopodh e yore; jolweny mage duto nolingʼ thi odiechiengno,” Jehova Nyasaye Maratego owacho.
Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
27 “Anawangʼ ohingini mag Damaski; notiek kuonde mochiel motegno mag Ben-Hadad.”
“Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
28 Kuom Kedar gi pinyruodhi mag Hazor, mane Nebukadneza ruodh Babulon omonjo: Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Chungʼuru malo, kendo umonj Keda, mi utiek joma aa yo wuok chiengʼ.
Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
29 Hembegi gi jambgi nokaw; kar dak margi nowal oko, kaachiel gi mwandugi duto kod ngamia. Ji nogonegi koko ni, ‘Masira maduongʼ koni gi koni!’”
Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
30 Jehova Nyasaye wacho niya, “Ringuru piyo uayi! Daguru e rogo matut, un joma odak Hazor. Nebukadneza ruodh Babulon nigi paro marach kuomu; osechano timonu marach.
“Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
31 “Chunguru kendo umonj pinyni momewo, modak kodhil,” Jehova Nyasaye owacho, “piny maonge dhorangeye kata lodi; joge odak kendgi.
“Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
32 Ngamia mag-gi noyaki kendo kweth mag dhogi nope. Anake joge mantie kuma bor e tunge piny kendo anakelnegi masira koa koni gi koni,” Jehova Nyasaye owacho.
Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
33 “Hazor nobed thim mar ondiegi, kama ojwangʼ nyaka chiengʼ. Onge ngʼama nodag kanyo; onge ngʼama nodag e iye.”
“Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
34 Ma e wach Jehova Nyasaye mane obirone janabi Jeremia kuom Elam, e ndalo chakruok mar loch Zedekia ruodh Juda:
Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
35 Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego, wacho: “Ne, anatur atung Elam, girgi maduongʼ mar tekogi.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
36 Anamonj Elam gi yembe angʼwen moa e tunge angʼwen mar polo; anakegi e yembe angʼwen-go kendo onge piny ma jo-Elam momaki ok nodhiye.
Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
37 Anami Elam ongʼengʼ e nyim wasike, e nyim jogo madwaro tieko ngimagi; anakel masiche kuomgi, ma en mirimba mager,” Jehova Nyasaye ema owacho. “Analawgi gi ligangla manyaka atiekgi.”
Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
38 Jehova Nyasaye wacho niya, “Anaket koma mar duongʼ ei Elam, kendo atiek ruodhe kod jotende.”
Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
39 “Kata kamano anaduog mwandu Elam e ndalo ma biro,” Jehova Nyasaye ema owacho.
“Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.

< Jeremia 49 >