< Jeremia 42 >

1 Eka jotend lweny duto, kaachiel gi Johanan wuod Karea kod Jezania wuod Hoshaya, kod ji duto chakre matin nyaka maduongʼ nodhi ir
Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá.
2 janabi Jeremia kendo owachone niya, “Kiyie to iwinj kwayowa kendo ilamnwa Jehova Nyasaye ma Nyasachi ne joma otonygi duto. Nimar kaka ineno sani, kata obedoni chon ne wangʼeny, to koro sani ji matin ema odongʼ.
Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù.
3 Lem mondo Jehova Nyasaye ma Nyasachi onyiswa kuma wanyalo dhiyoe kendo gima wanyalo timo.”
Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”
4 Janabi Jeremia nodwoko niya, “Asewinjou. Adier nyaka analamnu Jehova Nyasaye ma Nyasacha kaka usekwayo; ananyisu gimoro amora ma Jehova Nyasaye owacho kendo onge gima anapandnu.”
Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”
5 Eka negiwachone Jeremia, “Mad Jehova Nyasaye bed ja-adiera kendo janeno makare kuomwa ka dipo ni timbewa ok oluwore gi gimoro ma Jehova Nyasaye ma Nyasachi ooroi godo irwa.
Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa.
6 Kowinjore kata ka ok owinjore, wanaluor Jehova Nyasaye ma Nyasachwa, ma waori ire, mondo omi obed maber kodwa, nimar wanaluor Jehova Nyasaye ma Nyasachwa.”
Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
7 Bangʼ ndalo apar wach Jehova Nyasaye nobiro ne Jeremia.
Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá,
8 Omiyo noluongo Johanan wuod Karea kod jotend lweny mane ni kode kod ji duto chakre matin nyaka maduongʼ.
O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
9 Nowachonegi niya, “Ma e gima Jehova Nyasaye, Nyasach Israel, mane uora ire mondo aterne kwayou, wacho:
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi.
10 ‘Ka idak e pinyni, anageru kendo ok anatieku; anapidhu to ok pudhou oko, nimar asebedo gi lit kuom masiche masekelo kuomu.
Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.
11 Kik uluor ruodh Babulon, makoro uluoro. Kik uluore, Jehova Nyasaye wacho, nimar an kodu kendo anaresu ua e lwetene.
Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀.
12 Anatimnu ngʼwono mondo omi en bende ongʼwonnu kendo odwoku e pinyu.’
Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’
13 “To ka uwacho, ‘Ok wanadagie pinyni,’ mamano mi ubed ma ok uluoro Jehova Nyasaye ma Nyasachu,
“Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín.
14 kendo ka uwacho ni, ‘Ooyo, wanadhi kendo wadag Misri, kama ok wana neye lweny kata winjo turumbete kata bedo gi kech mar makati,’
Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’
15 to uwinj wach Jehova Nyasaye, yaye joma otony modongʼ mag Juda. Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego, ma Nyasach Israel, wacho: ‘Ka uramo ni nyaka udhi Misri kendo udhi udak kanyo,
nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀.
16 to ngʼeuru ni ligangla ma uluoro nomaku, kendo kech mabwogou noluu nyaka Misri, kendo kanyo ema unuthoe.
Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí.
17 Adiera, jogo duto moramo mondo odhi odag Misri noneg gi ligangla, kech kod masira maonge ngʼato angʼata ma notony e chandruok mabiro kelo kuomgi.’
Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’
18 Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego, ma Nyasach Israel, wacho: ‘Kaka ich wangʼ mara kod mirimba aseolo kuom jogo modak Jerusalem, e kaka mirimba ibiro olo kuomu ka udhi Misri. Inibed gir kwongʼ kendo mabwogo ji, gima ingʼadogo bura kendo gir ajara; ok unuchak une kaeni kendo.’
Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’
19 “Yaye jo-Juda modongʼ, Jehova Nyasaye osenyisou ni, ‘Kik udhi Misri.’ Beduru gadiera kuom ma: Asiemou kawuono
“Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí,
20 ni ne uketho ketho malich kane uora ir Jehova Nyasaye ma Nyasachu kendo uwacho ni, ‘Lamnwa Jehova Nyasaye ma Nyasachwa; nyiswa gik moko duto mowacho kendo wanatim kamano.’
pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’
21 Asewachonu kawuono, to pod ok uluoro Jehova Nyasaye ma Nyasachu kuom gigo duto mane oora mondo anyisu.
Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín.
22 Omiyo koro, beduru gadieri kuom ma: Nonegu gi ligangla, kech kod masira kuma udwaro dhiye mondo udagie.”
Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”

< Jeremia 42 >