< Jeremia 39 >

1 E higa mar ochiko mar Zedekia ruodh Juda, e dwe mar apar, Nebukadneza ruodh Babulon nodhi gi jolweny mage duto momonjo Jerusalem kendo ne gigoyone agengʼa.
Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í.
2 To odiechiengʼ mar ochiko e dwe mar angʼwen e higa mar apar gachiel mar loch Zedekia, ohinga mar dala maduongʼno nomuki.
Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà.
3 Eka jotelo duto mag ruodh Babulon nobiro kendo obet e Dhorangach Madiere: Negal-Shareza ma ja-Samgar, Nebo-Sasekim jatelo maduongʼ, Negal-Shareza jatelo mamalo maduongʼ kod jotelo mamoko duto mag ruodh Babulon.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú.
4 Ka Zedekia ruodh Juda kod jolweny duto nonenogi, negiringo giwuok e dala maduongʼno gotieno ka gikalo e rangach man e kind ohinga ariyo man but puoth ruoth, kendo ka gichomo Araba.
Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.
5 To jolwenj Babulon nolawogi kendo ojuko Zedekia e pewe mag Jeriko. Negimake mi gitere Ribla e piny Hamath ir Nebukadneza ruodh Babulon, kama nongʼadone bura.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
6 E Ribla ruodh Babulon nonego yawuot Zedekia koneno bende nonego jo-Juda duto ma joka ruoth.
Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda.
7 Eka nogolo wenge Zedekia oko kendo notweye gi rateke mag mula mondo notere Babulon.
Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.
8 Jo-Babulon nowangʼo kar dak ruoth kod ute ji kendo negimuko ohinga mag Jerusalem.
Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu.
9 Nebuzaradan ma jatend lweny mar piny nomako joma nodongʼ e dala maduongʼ moterogi e twech Babulon, kanyakla gi jogo mane osedhi ire, kod joma moko.
Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.
10 To Nebuzaradan ma jatend lweny noweyo e piny Juda joma odhier, mane onge gi gimoro; kendo e ndalogo nomiyogi puothe mzabibu kod puothe mamoko.
Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.
11 Koro Nebukadneza ruodh Babulon nosechiwo chike kuom Jeremia kokalo kuom Nebuzaradan ma jatend lweny mar piny kowacho ni:
Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé:
12 “Kawe kendo irite; kik ihinye to timne gimoro amora mokwayo.”
“Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”
13 Omiyo Nebuzaradan ma jatend lweny, Nebushazban ma jatelo maduongʼ, Negal-Shareza ma jatelo mamalo kod jotelo duto mag ruodh Babulon
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli,
14 nooro wach mondo ogol Jeremia oa e laru mar jarito. Ne gitere ir Gedalia wuod Ahikam, ma wuod Shafan, mondo odwoke dalane. Omiyo nodongʼ e dier jogi owuon.
ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Sa mane Jeremia nokan e laru mar jolweny, wach Jehova Nyasaye nobirone niya:
Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé:
16 “Dhiyo kendo inyis Ebed-Melek ja-Kush, ‘Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego, ma Nyasach Israel, wacho: Achiegni timo gik mane awacho ni natim ne dala maduongʼni, ka akelo ne masiche to ok kwe. E kindeno notimgi ka ineno.
“Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.
17 Jehova Nyasaye wacho ni enoresi odiechiengʼno, ok nochiwi ne jogo miluoro.
Ṣùgbọ́n, Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.
18 Enoresi; ok nonegi gi ligangla to initony gi ngimani, nikech igeno kuoma,’” Jehova Nyasaye owacho.
Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’”

< Jeremia 39 >