< Jeremia 37 >

1 Zedekia wuod Josia noket ruodh juda gi Nebukadneza ruodh Babulon; nobedo gi loch kar Jehoyakin wuod Jehoyakim.
Sedekiah ọmọ Josiah sì jẹ ọba ní ipò Jehoiakini ọmọ Jehoiakimu ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli fi jẹ ọba ní ilẹ̀ Juda.
2 En kata jorit mage kata jopinyno ne ok owinjo weche mane Jehova Nyasaye owacho kokalo kuom janabi Jeremia.
Ṣùgbọ́n àti òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kò fetísí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípa wòlíì Jeremiah.
3 Ruoth Zedekia, kata kamano, nooro Jehukal wuod Shelemia gi jadolo Zefania wuod Maseya ir janabi Jeremia gi wachni: “Kiyie to lamnwa Jehova Nyasaye ma Nyasachwa.”
Sedekiah ọba sì rán Jehukali ọmọ Ṣelemiah àti Sefaniah ọmọ Maaseiah sí Jeremiah wòlíì wí pé, “Jọ̀wọ́ gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
4 Koro Jeremia ne nigi thuolo mondo obi kendo odhi e dier ji, nimar ne pod ok okete e od twech.
Nígbà yìí Jeremiah sì ń wọlé, ó sì ń jáde láàrín àwọn ènìyàn nítorí wọ́n ti fi sínú túbú.
5 Jolwenj Farao ne osewuok oa Misri, kendo ka jo-Babulon mane gero pidhe kolworo Jerusalem nowinjo wach mar biro margi, ne gidar gia Jerusalem.
Àwọn ọmọ-ogun Farao ti jáde kúrò nílẹ̀ Ejibiti àti nígbà tí àwọn ará Babeli tó ń ṣàtìpó ní Jerusalẹmu gbọ́ ìròyìn nípa wọn, wọ́n kúrò ní Jerusalẹmu.
6 Eka wach Jehova Nyasaye nobiro ne janabi Jeremia niya:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì Ọlọ́run wá:
7 “Ma e gima Jehova Nyasaye, ma Nyasach Israel, wacho: Nyis ruodh Juda, mane oorou mondo unona ni, ‘Jolwenj Farao, mosewuok mondo okonyu, biro dok e pinygi giwegi, Misri.
“Èyí ni, ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ fún ọba àwọn Juda tó rán ọ láti wádìí nípa mi. ‘Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáde láti kún ọ lọ́wọ́ yóò padà sílẹ̀ wọn sí Ejibiti.
8 Eka jo-Babulon nodwogi kendo ginimonj dala maduongʼni; ginikawe kendo wangʼe pep.’
Nígbà náà ni àwọn ará Babeli yóò padà láti gbógun ti ìlú. Wọn yóò mú wọn nígbèkùn, wọn yóò sì fi iná jó ìlú náà kanlẹ̀.’
9 “Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: Kik uwuondru uwegi, kuparo ni, ‘Jo-Babulon gadiera biro weyowa.’ Ok giniweu ngangʼ!
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹ má ṣe tan ara yín jẹ ní èrò wí pé, ‘Àwọn ará Babeli yóò fi wá sílẹ̀ pẹ̀lú ìdánilójú.’ Wọn kò ní ṣe bẹ́ẹ̀.
10 Kata ka bed ni ne unyalo loyo jolwenj Babulon duto ma biro monjou kendo chwo mohiny kende ema odongʼ e hembegi, giniwuogi oko kendo giwangʼ dala maduongʼni.”
Kódà tó bá ṣe pé wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọmọ-ogun Babeli tí ń gbóguntì yín àti àwọn tí ìjàǹbá ṣe, tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ibùdó wọn; wọn yóò jáde láti jó ìlú náà kanlẹ̀.”
11 Bangʼ ka jolwenj Babulon nose aa Jerusalem nikech jolwenj Farao,
Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ-ogun Babeli ti kúrò ní Jerusalẹmu nítorí àwọn ọmọ-ogun Farao.
12 Jeremia nochako wuok e dala maduongʼ mondo odhi e gwengʼ Benjamin mondo oyud pokne e dier joma ni kanyo.
Jeremiah múra láti fi ìlú náà sílẹ̀, láti lọ sí olú ìlú Benjamini láti gba ẹ̀tọ́ rẹ̀ nínú ohun ìní láàrín àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀.
13 To kane ochopo e Dhoranga Benjamin, jatend jorito, ma nyinge en Irija wuod Shelemia, ma wuod Hanania, nomake kendo owacho niya, “Nenore ni iweyowa idokne jo-Babulon!”
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ẹnu ibodè Benjamini, olórí àwọn olùṣọ́ tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Irijah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Hananiah mú un, ó wí pé, “Ìwọ ń fi ara mọ́ àwọn ará Babeli.”
14 “Mano ok adiera!” Jeremia nowachone. “Ok aringi adogne jo-Babulon.” To Irija ne ok nyal winje; kuom mano, nomako Jeremia kendo okele ir jotelo.
Jeremiah sọ wí pé, “Èyí kì í ṣe òtítọ́! Èmi kò yapa sí àwọn ará Babeli.” Ṣùgbọ́n Irijah ko gbọ́ tirẹ̀, dípò èyí a mú Jeremiah, ó sì mú un lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ìjòyè.
15 Igi nowangʼ gi Jeremia kendo negikete ogoye kendo otweye e od Jonathan ma jagoro, mane giloso obedo od twech.
Nítorí náà ni àwọn ìjòyè ṣe bínú sí Jeremiah, wọ́n jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n tún fi sí túbú nílé Jonatani akọ̀wé nítorí wọ́n ti fi èyí ṣe ilé túbú.
16 Jeremia noketi e od twech manie bwo ot, kama ne obetie kuom kinde marabora.
Wọ́n fi Jeremiah sínú túbú tí ó ṣókùnkùn biribiri; níbi tí ó wà fún ìgbà pípẹ́.
17 Eka Ruoth Zedekia nooro mondo okele e kar dak ruoth, kama ne openje akwala niya, “Bende nitiere wach moa kuom Jehova Nyasaye?” Jeremia nodwoko ni, “Nitiere, nikech nochiwi ni ruodh Babulon.”
Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ sí i, tí ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n mú wá sí ààfin níbi tí ó ti bi í ní ìkọ̀kọ̀ pé, “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ kan wà láti ọ̀dọ̀ Olúwa?” Jeremiah fèsì pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, wọn ó fi ọ́ lé ọwọ́ ọba Babeli.”
18 Eka Jeremia nowachone Ruoth Zedekia niya, “En ketho mane ma asetimoni kata ne jotendi kata ne jogi, momiyo iketa e od twech?
Nígbà náà, Jeremiah sọ fún ọba Sedekiah pé, “Irú ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ yín, àwọn ìjòyè yín pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ẹ fi sọ mí sínú túbú?
19 To koro ere jonabi mane okoroni ni, ‘Ruodh jo-Babulon ok nomonj pinyu kata in?’
Níbo ni àwọn wòlíì yín tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín wí pé ọba Babeli kò ní gbóguntì yín wá?
20 To koro, ruodha, yie iwinja. We akel kwayona e nyimi: Kik idwoka e od Jonathan ma jagoro, ka ok kamano to abiro tho kanyo.”
Ṣùgbọ́n ní báyìí, olúwa mi ọba, èmí bẹ̀ ọ. Jẹ́ kí n mú ẹ̀dùn ọkàn mi tọ̀ ọ́ wá; má ṣe rán mi padà sí ilé Jonatani akọ̀wé, àfi kí n kú síbẹ̀.”
21 Eka Ruoth Zedekia nochiwo chik mondo Jeremia oket e laru jarito kendo miye makati koa e yore mag jolos makati odiechiengʼ ka odiechiengʼ, nyaka makati duto man e dala maduongʼno norumo.
Ọba Sedekiah wá pàṣẹ pé kí wọ́n fi Jeremiah sínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́, àti kí wọn sì fún ní àkàrà ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan títí tí àkàrà tó wà ní ìlú yóò fi tán; bẹ́ẹ̀ ni Jeremiah wà nínú àgbàlá náà.

< Jeremia 37 >