< Jeremia 3 >

1 Jehova Nyasaye wacho niya, “Ka dichwo oriembo chiege kendo chiege odhi moweye mi okende gi dichwo machielo, bende dodog ir dhakoni kendo? Donge pinyni dibed mochido chuth? To isedak kaka ochot man-gi johera mangʼeny bende koro diduog ira?
“Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn, ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá? Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí? Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́, ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?” ni Olúwa wí.
2 Tingʼ wangʼi malo mondo ingʼiane kuonde motimo ongoro motingʼore mondo ine. Bende nitiere kamoro amora modongʼ e piny mapok iterorigo? E dir yo ne ibet piny ka irito johera magi, ibet piny ka jakwath mamanyo pi ne dhoge e piny motwo. Isedwanyo piny gi chode mari, kod timbegi mamono.
“Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́? Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́, bí i ará Arabia kan nínú aginjù, ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́ pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
3 Emomiyo osetuonu koth, kendo kodh chwiri pod ok ochwe. Kata kamano in gi neno machalo gi mar ochot; wiyi bende ok kuodi nikech ionge gi wichkuot.
Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn, kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò. Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà, ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
4 Donge koro eka iwachona kama: Wuonwa, osiepna chakre tin-na,
Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé, ‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
5 inisik ka iyi owangʼ? Bende mirimbi biro bedo manyaka chiengʼ? Ma e kaka iwuoyo, to itimo timbe mamono duto minyalo.”
Ìwọ yóò ha máa bínú títí? Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’ Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀ ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”
6 E kinde mar loch Ruoth Josia, Jehova Nyasaye nowachona niya, “Bende iseneno gima Israel ma ok ja-ratiro otimo? Osedhi ewi gode duto matindo maboyo kendo e bwo yiende duto motimo otiep mi osechodo kanyo.
Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀.
7 Ne aparo ni kane osetimo magi duto to ne odhi duogo ira makmana ne ok odwogo, kendo kata mana nyamin mare ma Juda ma ok ja-ratiro noneno mano.
Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i.
8 Ne amiyo Israel maonge gi yie baruwa mar weruok kendo mi ariembe nikech timbene duto mag chode. Kata kamano ne aneno ka nyamin-gi ma Juda maonge ratiro ne ok oluor; en bende nodhi kendo ochodo.
Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè.
9 Nikech anjawo mar Israel nonenore gima tin, ne gidwanyo piny ka gilamo kite kod bepe.
Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi.
10 To kuom magi duto, nyamin mare ma Juda ma ok ja-adiera ka en ne ok odwogo ira gi chunye duto, to mana kuom wuondruok,” Jehova Nyasaye ema owacho.
Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.
11 Jehova Nyasaye nowachona niya, “Israel maonge gi yie ler moloyo Juda ma ok ja-adiera.
Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ.
12 Dhi mondo iland wachni yo nyandwat ni: “Jehova Nyasaye wacho niya, ‘Duogi in Israel maonge gi yie, ok anabed gi mirima kodi kendo, nimar an jangʼwono, iya ok bi wangʼ kodi nyaka chiengʼ.
Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá: “‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́, nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí. Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé.
13 Yie kethoni kende nikech isengʼanyone Jehova Nyasaye ma Nyasachi, isekayo timbegi mag ngʼwono mana ne nyiseche manono e bwo yiende motimo otiep, kendo pod ok iluora,’” Jehova Nyasaye ema owacho.
Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ, ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀, ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’” ni Olúwa wí.
14 Jehova Nyasaye wacho niya, “Dwoguru ira, un joga maonge yie, nimar an e chworu. Abiro yierou ka ngʼato achiel oa e dala to ji ariyo koa e anywola mi akelu Sayun.
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni.
15 Eka anamiu jokwath ma chunygi chal koda, mabiro telonu gi rieko kod winjo.”
Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀.
16 Jehova Nyasaye wacho niya, “E ndalogo, kakwanu osemedore mangʼeny e piny, ji ok nochak owuo kawacho ni, ‘Sandug Muma mar singruok mar Jehova Nyasaye.’ Ok enodonji e parogi bende ok ginipare; ok nodware, kata moro ok nolosi kendo.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa.’ Kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́.
17 E kindeno gibiro luongo Jerusalem ni Kom Loch mar Jehova Nyasaye, kendo ogendini duto nochokre ei Jerusalem mondo omi nying Jehova Nyasaye duongʼ. Ok ginichak gitim tim wich teko, bende ok ginibed gi chuny mar timo richo.
Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́.
18 E ndalogo od Juda biro riwore gi od Israel, kendo giduto ginibi ka gia e piny ma yo nyandwat nyaka e piny mane amiyo kwereu kaka girkeni.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.
19 “An awuon ne awacho niya, “‘Mano kaka dabed mamor ka akawou kaka yawuota kendo amiu piny mowinjore, girkeni maber mogik mar piny moro amora.’ Ne aparo ni unyalo luonga ni ‘Wuonwa,’ kendo ni ok unuwe luwa.
“Èmi fúnra mi sọ wí pé, “‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’ Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’ o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
20 To mana ka dhako ma ok ja-ratiro ne chwore, omiyo usebedo maonge gadieri kuoma, yaye od Israel,” Jehova Nyasaye ema owacho.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi. Ìwọ ilé Israẹli,” ni Olúwa wí.
21 Ywak iwinjo e kuonde motingʼore motimo ongoro, en kuyo gi secho mar jo-Israel, nikech gisejwangʼo yoregi, kendo wigi osewil gi Jehova Nyasaye ma Nyasachgi.
A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga, ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po, wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.
22 “Dwoguru, un joma onge yie; abiro thiedhou kuom baro weyo yo.” “Ee, wabiro biro iri, nimar in Jehova Nyasaye ma Nyasachwa.
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́, Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.” “Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
23 Adiera lamo nyiseche mopa ewi gode matindo, kod gode madongo en wuond; adier kuom Jehova Nyasaye, ma Nyasachwa, ema warruok mar Israel yudore.
Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè kéékèèké àti àwọn òkè gíga, nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
24 Chakre tinwa nyiseche manono mag wichkuot osechamo olemb tije wuonewa, ma gin kweth mar jamni, kod kweth mag dhok, yawuotgi kod nyigi.
Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run, ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn, ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
25 We wanind piny e wichkuot marwa, kendo we timbewa maricho oumwa. Wasetimo richo ne Jehova Nyasaye ma Nyasachwa, wan kaachiel gi wuonewa; chakre ndalo mane wan rowere nyaka odiechiengni pod ok waluoro Jehova Nyasaye ma Nyasachwa.”
Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa, kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀. A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, àwa àti àwọn baba wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”

< Jeremia 3 >