< Jeremia 29 >

1 Ma e baruwa mane janabi Jeremia ooro koa Jerusalem ne jodongo mane otony e dier jotwech kod ne jodolo, jonabi kod ji mamoko duto mane Nebukadneza notero e twech koa Jerusalem nyaka Babulon.
Èyí ni ọ̀rọ̀ inú lẹ́tà tí wòlíì Jeremiah rán láti Jerusalẹmu sí ìyókù nínú àwọn àgbàgbà tí ó wà ní ìgbèkùn àti sí àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo àwọn ènìyàn tí Nebukadnessari tí kó ní ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
2 (Ma ne en bangʼ ka Ruoth Jehoyakin kod min ruoth, jotelo mag agola kod jotend Juda gi Jerusalem, jopecho gi jogoro osedhi e twech koa Jerusalem.)
Lẹ́yìn ìgbà tí Jekoniah, ọba, àti ayaba, àti àwọn ìwẹ̀fà, àti àwọn ìjòyè Juda àti Jerusalẹmu, àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà àti àwọn olùyàwòrán tí wọ́n lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu.
3 Nomiyo Elasa wuod Shafan kod Gemaria wuod Hilkia baruwa, jogo mane Zedekia ruodh Juda nooro Babulon ir Ruoth Nebukadneza. Kawacho niya:
Ó fi lẹ́tà náà rán Eleasa ọmọ Ṣafani àti Gemariah ọmọ Hilkiah, ẹni tí Sedekiah ọba Juda rán sí Nebukadnessari ọba Babeli. Wí pé.
4 Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego, ma Nyasach Israel, wacho ne jogo duto mane atero e twech koa Jerusalem nyaka Babulon:
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn tí mo kó lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu ní Babeli:
5 “Geruru udi kendo udag kanyo; pidhuru puothe kendo ucham gik ma ginyago.
“Ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.
6 Nyomburu mondo onywol yawuowi kod nyiri; yuduru mon ne yawuotu kendo uchiw nyiu mondo onyuom, magin bende ginywol yawuotgi kod nyigi mondo kwanu omedre kendo kik udog chien.
Ẹ ṣe ìgbéyàwó, kí ẹ sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin, ẹ gbé ìyàwó fún àwọn ọmọkùnrin yín, kí ẹ sì fi àwọn ọmọbìnrin yín fún ọkọ. Kí àwọn náà lè ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin. Ẹ máa pọ̀ sí i ní iye, ẹ kò gbọdọ̀ dínkù ní iye níbẹ̀ rárá.
7 Bende, dwaruru kwe kod mwandu mar dala maduongʼ ma aseterou e twech. Lamuru Jehova Nyasaye, ndalono nikech kodhi maber to un bende unudhi maber.”
Bákan náà, ẹ máa wá àlàáfíà àti ìre ìlú, èyí tí mo kó yín lọ láti ṣe àtìpó. Ẹ gbàdúrà sí Olúwa fún ìre ilẹ̀ náà; nítorí pé bí ó bá dára fún ilẹ̀ náà, yóò dára fún ẹ̀yin pẹ̀lú.”
8 Ee, ma e gima Jehova Nyasaye Maratego, ma Nyasach Israel, wacho: “Kik iwe jonabi kod joma neno wach e lek manie dieru wuondu. Kik uchik itu ne lek ma gileko nikech mano miyo gimedo leko.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: “Ẹ má ṣe gbà kí àwọn wòlíì èké àti àwọn aláfọ̀ṣẹ àárín yín tàn yín jẹ. Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí àlá, èyí tí ẹ gbà wọ́n níyànjú láti lá.
9 Gikoro miriambo gi nyinga. Ok aorogi,” Jehova Nyasaye owacho.
Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún yín lórúkọ mi, Èmi kò rán wọn níṣẹ́,” ni Olúwa wí.
10 Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Bangʼ ka usetieko higni piero abiriyo e Babulon, to anabi iru kendo achop singo mara mar ngʼwono mondo aduogu ka.”
Báyìí ni Olúwa wí: “Nígbà tí ẹ bá lo àádọ́rin ọdún pé ní Babeli, èmi yóò tọ̀ yín wá láti ṣe àmúṣẹ ìlérí ńlá mi fún un yín, àní láti kó o yín padà sí Jerusalẹmu.
11 Nimar Jehova Nyasaye wacho niya, “Angʼeyo chenro ma an-go kodu. Chenro mar dhi maber to ok mar hinyou, chenro mar miyou geno kod ngima mabiro.
Nítorí mo mọ èrò tí mo rò sí yín,” ni Olúwa wí, “àní èrò àlàáfíà, kì í sì ṣe fún ibi, èrò láti fún un yín ní ìgbà ìkẹyìn àti ìrètí ọjọ́ iwájú.
12 Eka unuluonga mi anabi kendo ulama, to anawinju.
Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò ké pè mí, tí ẹ̀yin yóò sì gbàdúrà sí mi, tí èmi yóò sì gbọ́ àdúrà yín.
13 Unudwara kendo unuyuda ka udwara gi chunyu duto.
Ẹ̀yin yóò wá mi, bí ẹ̀yin bá sì fi gbogbo ọkàn yín wá mi: ẹ̀yin yóò rí mi ni Olúwa Ọlọ́run wí.
14 Ununwangʼa kendo anaduogu ka ua e twech. Anachoku ka ua e pinje duto kod kuonde ma asekeyoue kendo anaduogu kama ne uae ka aterou e twech,” Jehova Nyasaye owacho.
Èmi yóò di rí rí fún yín ni Olúwa wí, Èmi yóò sì mú yín padà kúrò ní ìgbèkùn. Èmi yóò ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè àti ibi gbogbo tí Èmi ti lé yín jáde, ni Olúwa wí. Èmi yóò sì kó yín padà sí ibi tí mo ti mú kí a kó yín ní ìgbèkùn lọ.”
15 Unyalo wacho niya, “Jehova Nyasaye osemiyowa jonabi ei Babulon,”
Ẹ̀yin lè wí pé, “Olúwa ti gbé àwọn wòlíì dìde fún wa ní Babeli.”
16 to ma e gima Jehova Nyasaye wacho kuom ruoth mobet e kom duongʼ mar Daudi kod jogo duto modongʼ e dala maduongʼni, jopinyu mane ok odhi kodu e twech;
Ṣùgbọ́n èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ti ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi àti ní ti gbogbo ènìyàn tó ṣẹ́kù ní ìlú yìí; àní ní ti àwọn ènìyàn yín tí kò bá yín lọ sí ìgbèkùn,
17 adiera, ma e gima Jehova Nyasaye Maratego wacho: “Anaor ligangla, kech kod masira kuomgi kendo analokgi ka ngʼope maricho ma ok nyal cham.
bẹ́ẹ̀ ni, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín wọn; Èmi yóò ṣe wọ́n bí èso ọ̀pọ̀tọ́ búburú tí kò ṣe é jẹ.
18 Analawgi gi ligangla, kech kod masira kendo anami gibed joma bwogo gwenge duto manie piny kendo gir kwongʼ kod bwok, gima ok onego mi luor kendo ma jaricho, e dier ogendini duto mane aseriembogie.”
Èmi yóò fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn lépa wọn, Èmi yóò sì sọ wọ́n di ìríra lójú gbogbo ìjọba ayé, fún ègún, àti ìyanu, àti ẹ̀sín, àti ẹ̀gàn láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, ní ibi tí Èmi yóò lé wọn sí.
19 Jehova Nyasaye wacho niya, “Nimar pok giwinjo wechena, ma gin weche mane aoronegi kuom jotichna ma jonabi. To kata mana un joma ne oter e twech pok uwinja,” Jehova Nyasaye owacho.
Nítorí wọ́n kọ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,” ni Olúwa Ọlọ́run wí. Ọ̀rọ̀ tí mo tún ti ẹnu àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sọ ní ẹ̀yin tí ń ṣe àtìpó kò gbọ́ ni Olúwa Ọlọ́run wí.
20 Emomiyo, winjuru wach Jehova Nyasaye, un joma ni e twech duto ma aseriembo koa Jerusalem nyaka Babulon.
Nítorí náà, gbogbo ẹ̀yin ìgbèkùn, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí mo rán lọ kúrò ní Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
21 Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego, ma Nyasach Israel, wacho kuom Ahab wuod Kolaya kod Zedekia wuod Maseya, ma koronu miriambo e nyinga: “Anachiwgi ne Nebukadneza ruodh Babulon, kendo enoneg-gi e nyimu ka uneno.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli sọ nípa Ahabu ọmọ Kolaiah àti nípa Sedekiah ọmọ Maaseiah tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún un yín lórúkọ mi: “Èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́. Òun yóò sì gba ẹ̀mí wọn ní ìṣẹ́jú yìí gan an.
22 Nikech gin, joma ni e twech duto moa Juda man Babulon noti gi kwongʼni kawacho ni: ‘Mad Jehova Nyasaye timnu mana kaka notimone Zedekia kod Ahab, mane ruodh Babulon owangʼo e mach.’
Nítorí tiwọn, ègún yìí yóò ran gbogbo àwọn àtìpó tó wà ní ilẹ̀ Babeli láti Juda: ‘Olúwa yóò ṣe yín bí i Sedekiah àti Ahabu tí ọba Babeli dáná sun.’
23 Nimar gisetimo gik mamono ei Israel; giseterore gi monde jobathgi kendo e nyinga gisewacho miriambo, mane ok anyisogi mondo giwachi. Angʼeye kendo an janeno kuom wachno,” Jehova Nyasaye owacho.
Nítorí wọ́n ti ṣe ibi ní ilé Israẹli, wọ́n ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ìyàwó aládùúgbò wọn, àti ní orúkọ mi ni wọ́n ti ṣe èké, èyí tí Èmi kò rán wọn láti ṣe. Ṣùgbọ́n, Èmi mọ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo sì jẹ́ ẹlẹ́rìí sí i,” ni Olúwa wí.
24 Nyis Shemaya ja-Nehelam,
Wí fún Ṣemaiah tí í ṣe Nehalami pé,
25 “Ma e gima Jehova Nyasaye Maratego ma Nyasach Israel, wacho: Ne ioro barupe e nyingi iwuon ne ji duto man Jerusalem, ne Zefania wuod Maseya jadolo, kendo ne jodolo mamoko duto. Ne iwachone Zefania ni,
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí: Ìwọ fi lẹ́tà ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu sí Sefaniah ọmọ Maaseiah tí í ṣe àlùfáà ní orúkọ mi; ó sì sọ fún Sefaniah wí pé,
26 ‘Jehova Nyasaye oseyieri jadolo kar Jehoyada mondo ibed jarit od Jehova Nyasaye; omiyo koro ngʼato ma janeko mawuondore ni janabi onego itwe gi nyororo kod chuma molworo ngʼute.
‘Olúwa ti yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà rọ́pò Jehoiada láti máa jẹ́ alákòóso ilé Olúwa, kí o máa fi èyíkéyìí nínú àwọn aṣiwèrè tó bá ṣe bí i wòlíì si inú àgò irin.
27 Marangʼo pod ok imako Jeremia moa Anathoth, ma ketore ni janabi e dieru?
Nítorí náà, èéṣe tí o kò fi bá Jeremiah ará Anatoti wí. Ẹni tí ó ń dúró bí i wòlíì láàrín yín?
28 Oseoranwa wachni Babulon: Enobed kinde marabora. Emomiyo geruru udi kendo udagie eigi; pidhuru puothe kendo ucham gigo ma ginyago.’”
Ó ti rán iṣẹ́ yìí sí wa ni Babeli wí pé, àtìpó náà yóò pẹ́ kí ó tó parí, nítorí náà, ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.’”
29 Zefania jadolo, kata kamano, nosomo baruwani ne Jeremia janabi.
Sefaniah àlùfáà ka lẹ́tà náà sí etí ìgbọ́ Jeremiah tí í ṣe wòlíì.
30 Eka wach Jehova Nyasaye nobiro ne Jeremia ni,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé,
31 “Or wachni ne joma ni e twech duto: ‘Ma e gima Jehova Nyasaye wacho kuom Shemaya ja-Nehelam: Nikech Shemaya osekoronu, kata obedo ni ne ok aore, kendo osemiyo uyie gi miriambo,
“Rán iṣẹ́ yìí sí gbogbo àwọn ìgbèkùn wí pé: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí ní ti Ṣemaiah, ará Nehalami: Nítorí pé Ṣemaiah ti sọtẹ́lẹ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n èmi kò ran an, tí òun sì ń mú u yín gbẹ́kẹ̀lé èké.
32 ma e gima Jehova Nyasaye wacho: Adier, anakum Shemaya ja-Nehelam kod gunde. Onge ngʼama nodongʼ kuom joge, kata neno gik mabeyo mabiro timo ne joga, nikech oselando mondo ji ongʼanyna. An Jehova Nyasaye ema awacho kamano.’”
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Wò ó, èmi yóò bẹ Ṣemaiah, ará Nehalami wò, àti irú-ọmọ rẹ̀; òun kì yóò ní ọkùnrin kan láti máa gbé àárín ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò rí rere náà tí èmi yóò ṣe fún àwọn ènìyàn mi ni Olúwa wí, nítorí ó ti ti kéde ìṣọ̀tẹ̀ sí mi.’”

< Jeremia 29 >