< Jeremia 22 >

1 Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Dhiyo e kar dak mar ruodh Juda kendo iland wachni kanyo:
Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀:
2 ‘Winj wach Jehova Nyasaye, yaye ruodh Juda, un joma bet e kom duongʼ Daudi, in, jotendi kod jogi madonjo gie dhorangeyegi.
‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí.
3 Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: Tim gima nikare kendo mowinjore. Res ngʼatno e lwet ngʼama thire, ngʼatno mosemaye. Kik itim marach kata tugo lweny gi jadak, kiye kata mon ma chwogi otho, kendo kik ichwer remo maonge gi wach ka eri.
Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí.
4 Nimar ka urito chikegi maber, eka ruodhi mabet e kom duongʼ mar Daudi nondonji gi e dhorangeye mag kar dak ruoth, ka giriembo geche kendo giidho farese, ka gin gi jotendgi kod jogegi.
Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
5 To ka ok urito chikegi, Jehova Nyasaye wacho, akwongʼora an owuon ni kar dak ruodhni nolal nono.’”
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’”
6 Nimar ma e gima Jehova Nyasaye wacho kuom kar dak mar ruodh Juda: “Kata obedo ni in kaka Gilead ne an, kaka wi got Lebanon, adiera analoku kaka kama otwo, ka mier maonge joma odakie.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi, gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni, dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀, àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
7 Anaor joma tiekou, ngʼato ka ngʼato gi gige lweny, kendo ginitongʼ sirniu mabeyo mag sida mi giwitgi ei mach.
Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀, wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀, wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.
8 “Ji moa e pinje mangʼeny nokal e dala maduongʼni kendo ginipenjre kendgi giwegi ni, ‘Angʼo momiyo Jehova Nyasaye timo gima chalo kama ne dala maduongʼni?’
“Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’
9 To dwoko nobed: ‘Nikech gisejwangʼo singruok mar Jehova Nyasaye ma Nyasachgi kendo giselamo kendo tiyone nyiseche mamoko.’”
Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’”
10 Kik uywag ruoth motho kata goyo nduru ne lal mare; to onego, uywag malit ne ngʼatno moter e twech, nikech ok enoduogi kata neno piny mane onywole kendo.
Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú nítorí kì yóò padà wá mọ́ tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.
11 Nimar ma e gima Jehova Nyasaye osewacho kawuoyo kuom Shalum wuod Josia, mane okawo loch bangʼ wuon-gi kaka ruodh Juda, “Osea ka kendo ok nodwogi.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.
12 Enotho kama gisetere e twech; ok enone pinyni kendo.”
Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”
13 “Mano kaka none malit ngʼatno magero kare mar dak maonge ratiro, utene mamalo e yor mecho koketo jothurgi tiyo maonge chudo.
“Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo, àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́ tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
14 Owacho, ‘Anagerne an owuon kar dak mara maduongʼ ka en-gi ute mamalo malach.’ Omiyo oloso dirisni malach kuome, olwore gi fito mar yiend sida, kendo obuke gi range marakwaro.
Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀, ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’ A ó sì fi igi kedari bò ó, a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
15 “Bedo gi yiende mag sida mangʼeny nyalo miyo ibed ruoth? Donge wuonu ne nigi chiemo kod math? Notimo gima ratiro kendo nikare, omiyo duto nobedo maber kode.
“Ìwọ ó ha jẹ ọba kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari? Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu? Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo, nítorí náà ó dára fún un.
16 Ne ochungʼ motegno ne joma odhier kendo ni gidwaro, kendo duto nobedo maber kode. Donge mano e tiend ngʼeya?” Jehova Nyasaye owacho.
Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní, ohun gbogbo sì dára fún un. Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?” ni Olúwa wí.
17 “To wengeu kod chunyu ochikore mana e yor yudo ohala gi mecho, e chwero remo maonge gi wach kuom thiro ji kod lweny.”
“Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ wà lára èrè àìṣòótọ́ láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”
18 Emomiyo ma e gima Jehova Nyasaye wacho kuom Jehoyakim wuod Josia ruodh Juda: “Ok giniywage ni: ‘Yaye, owadwa! Yaye, nyamera!’ Ok giniywage ni: ‘Yaye, jatenda! Yaye, duongʼ mari!’
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda: “Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’ Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
19 Enoyike ka punda, moywa kendo owit oko mar dhorangeye Jerusalem.”
A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.”
20 “Dhiyo Lebanon kendo iywag matek, mad dwondi winjre Bashan, ywagi ka ia Abarim, nimar joma osiepenigo oseduny matindo tindo.
“Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta, kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani, kí o kígbe sókè láti Abarimu, nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
21 Ne amiyou siem e kinde mane uparo ni uritoru maber, to ne iwacho ni, ‘Ok anachik ita!’ Ma osebedo yori chakre ibed rawera; ok iseluora.
Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu, ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’ Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ, ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
22 Yamo noriemb jokwadhu duto, kendo joma osiepeni noter e twech. Eka wiyi nokuodi kendo nogengʼni nikech timbegi maricho.
Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ, gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn, nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́ nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
23 Un jogo modak Lebanon, modak e ute bao mag sida moger gi malo, mano kaka unuywag malit ka rem ochopo kuomu, rem machalo gi mar dhako mamuoch kayo!”
Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’ tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari, ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ, ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!
24 Jehova Nyasaye owacho niya, “An Jehova Nyasaye mangima akwongʼora ni kata ne bed ni in Jehoyakin wuod Jehoyakim ruodh Juda, ni in e tere manie lweta ma korachwich, to pod dawuodhi oko.
“Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀.
25 Anachiwi ne jogo madwaro ngimani kendo miluoro. Abiro chiwou ne Nebukadneza ruodh Babulon kod jo-Babulon.
Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli.
26 Anadiri oko kod miyo mane onywoli e piny machielo, kama onge ngʼama nonywole kuomu, kendo kanyo ema uduto unuthoe.
Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí.
27 Ok unuduogie piny ma ugombo duogoeni.”
Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”
28 Bende ngʼatni Jehoyakin en ngʼama ojar, agulu motore, gino maonge ngʼama dwaro? En angʼo momiyo en kod nyithinde nyaka witgi oko e piny ma ok gingʼeyo?
Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo, ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́? Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
29 Yaye piny, piny, piny, winj wach Jehova Nyasaye!
Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
30 Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Kwan ngʼatni ka ngʼama onge nyathi, ngʼatno ma ok nyal dhi nyime maber, e kinde mar ngimane, nimar onge gunde mane dhi maber, onge manobed e kom duongʼ Daudi, kata bed gi loch kendo ei Juda.”
Báyìí ni Olúwa wí: “Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere, èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”

< Jeremia 22 >