< Jeremia 17 >

1 Jehova Nyasaye wacho niya, “Richo mar Juda ondik gi kalamb chuma; ogor gi gima bith e chunygi, kendo e tunge kende mag misango miwangʼoe liswa.
“Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
2 Kata mana nyithindgi paro kendegi mag misango miwangʼoe liswa, kod sirni mag Ashera mantie bath yiende motimo otiep, kendo e gode matindo motingʼore gi malo.
Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
3 Goda maduongʼ manie piny kod mwanduni gi nyak magi duto anami wasiki, kaachiel gi kuonde magi motingʼore gi malo, nikech richo manie pinyu duto.
Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
4 Kethou uwegi nomi nomau girkeni mane amiyou. Anami ubed wasumb wasiku e piny ma ok ungʼeyo, nimar usemedo mirimba, kendo enowangʼ nyaka chiengʼ.”
Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
5 Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “Okwongʼ ngʼatno ma genone ni kuom dhano, ngʼatno mogeno kuom ringruok mondo omiye teko, kendo ma chunye aa kuom Jehova Nyasaye.
Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
6 Enochal ka bungu manie thim; ok enowinj maber ka ber obiro. Enodag kuonde motwo motimo ongoro, kama otimo chumbi maonge ngʼama odakie.
Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
7 “To ogwedh ngʼatno moketo geno mare kuom Jehova Nyasaye, kendo oyie kuome.
“Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
8 Enochal gi yien mopidh but pi ma tiende nyaa e tiend aora. Ok obed gi luoro ka liet obiro; ite osiko mana ka ngʼich. Oonge gi parruok e higa mar oro kendo ok owe ma ok onyago olemo.”
Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
9 Chuny en jawuond moloyo gik moko duto kendo ok nyal thiedhe. En ngʼa manyalo ngʼeye?
Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
10 “An Jehova Nyasaye ema anono chuny kendo apimo paro, mondo achiwne ngʼato kaluwore gi timne, kendo kaluwore gi kaka kite chalo.”
“Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
11 Kaka winyo ma butno e tongʼ mane ok onywolo, e kaka ngʼatno mayudo mwandu gi yore ma ok kare. Ka nus ngimane oserumo, mwandune noweye, kendo gikone nonere malongʼo ni en ngʼama ofuwo.
Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
12 Kom duongʼ, motingʼ malo aa chakruok, e kama ler mar lemo marwa.
Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
13 Yaye Jehova Nyasaye, geno mar Israel, jogo duto mojwangʼi noyud wichkuot. Jogo molokoni ngʼegi nondik nying-gi e buru nikech gisejwangʼo Jehova Nyasaye, soko mar pi ngima.
Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
14 Changa, yaye Jehova Nyasaye, kendo anachangi; resa kendo anaresra, nimar in kendi ema apaki.
Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
15 Gisiko ka giwachona ni, “Ere wach Jehova Nyasaye? Dak otimre sani!”
Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
16 Pok aweyo bedo jakwath mari; ingʼeyo ni pok agombo odiechiengʼ mar thagruok. Gima wuok e dhoga ingʼeyo.
Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
17 Kik ilokrina masira; in e kar pondana e kinde mar thagruok.
Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
18 Mad jogo masanda ne wichkuot, to an kik wiya kuodi; mad gibed gi bwok maduongʼ to an kik ibwoga. Kel gigi kuomgi e kinde mar masira; kethgi gi kethruok manyadiriyo.
Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
19 Ma e gima Jehova Nyasaye nowachona: “Dhi kendo ichungʼ e dhorangach miluongo ni dhoranga ji, kama ruodhi mag Juda donjogo kendo wuok godo oko; chungʼ bende e rangeye duto mag Jerusalem.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
20 Wachnegi, ‘Winj wach Jehova Nyasaye, yaye ruodhi mag Juda kod jo-Juda duto gi ngʼato angʼata modak e Jerusalem madonjo gie rangeyegi.
Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
21 Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: Bed motangʼ ma kik itingʼ misigo chiengʼ Sabato kata ikele kokalo e rangeye mag Jerusalem.
Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
22 Kik ukel misike koa ei uteu kata timo tich moro chiengʼ Sabato, to rit chiengʼ Sabato maler, mana kaka ne achiko kwereu.
Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
23 Kata kamano ne ok gichiko itgi kata winja; tokgi ne tek ta ma ok ginyal winjo wach kata winjo puonj.
Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
24 To ka inyalo bedo motangʼ kiluora, Jehova Nyasaye owacho, kendo onge misigo mikadhogo dhoranga dala maduongʼni chiengʼ Sabato, to irito chiengʼ Sabato maler ma ok itimo tich moro chiengʼno,
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
25 eka ruodhi mabet e kom duongʼ Daudi nobi kakalo e rangeye mag dala maduongʼni gi jotendgi. Gin kod jotelo mag-gi ginibi ka giriembo geche kod farese, ka gin kaachiel gi jo-Juda kod jogo modak e Jerusalem, kendo dala maduongʼni enodage nyaka chiengʼ.
Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
26 Ji nobi koa e dala mag Juda kod mier molworo Jerusalem, koae gwengʼ Benjamin gi tiend gode matindo ma yo podho chiengʼ, koa e piny manie gode matindo kod Negev, ka gikelo misango miwangʼo pep kod misengini mamoko, chiwo mag cham, ubani gi chiwo mag goyo erokamano e od Jehova Nyasaye.
Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
27 To ka ok umiya luor mondo urit Sabato maler ma ok utingʼo misigo ka udonjo e rangeye Jerusalem chiengʼ Sabato, to anamok mach ma ok tho e rangeye mag Jerusalem manowangʼ kuondegi mochiel motegno.’”
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”

< Jeremia 17 >