< Jeremia 11 >

1 Ma e wach mane obirone Jeremia koa ir Jehova Nyasaye:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá:
2 “Chik iti ne chike mag singruokni kendo inyis jo-Juda kod mago modak Jerusalem.
“Fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí o sì sọ wọ́n fún àwọn ènìyàn Juda, àti gbogbo àwọn tó ń gbé ni Jerusalẹmu.
3 Nyisgi ni ma e gima Jehova Nyasaye, Nyasach Israel, wacho: ‘Okwongʼ ngʼatno ma ok oluoro gima singruokni dwaro,
Sọ fún wọn wí pé èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ègbé ni fún ẹni náà tí kò pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí mọ́.
4 chike mane amiyo kwereu kane agologi Misri, e kendo maliet makakni mach.’ Ne awacho ni, ‘Luora kendo itim gigo duto machikou to unubed joga, an bende nabed Nyasachu.
Àwọn májẹ̀mú tí mo pàṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, nígbà tí mo mú wọn jáde láti Ejibiti, láti inú iná alágbẹ̀dẹ wá.’ Mo wí pé, ‘Ẹ gbọ́ tèmi, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ènìyàn mi, Èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
5 Bangʼe anachop singo mane asingone kwereu, mar miyogi piny mopongʼ gi chak kod mor kich’ ma en piny mauntiere kawuono.” Ne adwoko Jehova Nyasaye niya, “Amin.”
Nígbà náà ni Èmi ó sì mú ìlérí tí mo búra fún àwọn baba ńlá yín ṣẹ; láti fún wọn ní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin,’ ilẹ̀ tí ẹ ní lónìí.” Mo sì dáhùn wí pé, “Àmín, Olúwa.”
6 Jehova Nyasaye nowachona niya, “Go milome mar wechegi duto e mier mag Juda kod jogo manie yore mag Jerusalem: ‘Chikuru itu ne chike mag singruokni kendo ulugi.
Olúwa wí fún mi pé, “Kéde gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ní àwọn ìlú Juda àti ní gbogbo òpópónà ìgboro Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí ẹ sì se wọn.
7 Kochakore kinde mane akelo kwereu koa Misri nyaka kawuono, ne asiemogi nyadingʼeny, ka awacho niya, “Luorauru.”
Láti ìgbà tí mo ti mú àwọn baba yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá títí di òní, mo kìlọ̀ fún wọn lọ́pọ̀ ìgbà wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi.”
8 To ne ok gichiko itgi kata winja; kuom mano, negiluwo mana timbegi mag jendeke mag chunjegi maricho. Omiyo nakelo kuomgi kwongʼ duto mag singruok mane achikogi mondo gilu to ne ok girito.’”
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kọbi ara sí i dípò èyí wọ́n tẹ̀síwájú ni agídí ọkàn wọn. Mo sì mú gbogbo ègún inú májẹ̀mú tí mo ti ṣèlérí, tí mo sì ti pàṣẹ fún wọn láti tẹ̀lé, tí wọn kò tẹ̀lé wa sórí wọn.’”
9 Eka Jehova Nyasaye nowachona, “Nitiere winjruok ma lingʼ-lingʼ e kind jo-Juda kod jogo modak Jerusalem.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ọ̀tẹ̀ kan wà láàrín àwọn ará Juda àti àwọn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
10 Gisedok e richo mag kweregi, mane otamore winjo wechega. Giseluwo bangʼ nyiseche manono mondo gitinegi. Od Israel gi od Juda giduto oseketho singruok mane atimo gi kweregi.
Wọ́n ti padà sí ìdí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn tí wọn kọ̀ láti tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n ti tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti sìn wọ́n. Ilé Israẹli àti ilé Juda ti ba májẹ̀mú tí mo dá pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn jẹ́.
11 Emomiyo ma e gima Jehova Nyasaye wacho: ‘Anakelnegi masira ma ok ginyal tonye. Kata bed ni giywakna, ok anawinjgi.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi yóò mu ibi tí wọn kò ní le è yẹ̀ wá sórí wọn, bí wọ́n tilẹ̀ ké pè mí èmi kì yóò fetí sí igbe wọn.
12 Mier mag Juda kod jo-Jerusalem nodhi kendo ywakne nyiseche manono ma giwangʼone ubani, to ok ginikonygi ngangʼ ka masira ochopo.
Àwọn ìlú Juda àti àwọn ará Jerusalẹmu yóò lọ kégbe sí àwọn òrìṣà tí wọ́n ń sun tùràrí sí; àwọn òrìṣà náà kò ní ràn wọ́n lọ́wọ́ ní ìgbà tí ìpọ́njú náà bá dé.
13 Un gi nyiseche manono mangʼeny mana kaka dalau, yaye Juda; bende kendo mar misango museiko mudwaro wangʼone nyasaye manono mar wichkuot miluongo ni Baal ngʼeny mana ka yore mag Jerusalem.’
Ìwọ Juda, bí iye àwọn ìlú rẹ, bẹ́ẹ̀ iye àwọn òrìṣà rẹ; bẹ́ẹ̀ ni iye pẹpẹ tí ẹ̀yin ti tẹ́ fún sísun tùràrí Baali ohun ìtìjú n nì ṣe pọ̀ bí iye òpópónà tí ó wà ní Jerusalẹmu.’
14 “Kik ilam ne jogi kata chiwonegi kwayo moro amora kata sayonegi, nikech ok anawinji ka gibiro ira e seche mag masira.
“Má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí pé, Èmi kì yóò dẹtí sí wọn nígbà tí wọ́n bá ké pè mí ní ìgbà ìpọ́njú.
15 “Angʼo ma jaherana timo e hekalu mara kochano timbe mamono gi ji mathoth? Bende ringʼo mowal tenge nyalo loko kum mari? Seche mitimo timbe marichogo, ema inie gi mor.”
“Kí ni olùfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹmpili mi, bí òun àti àwọn mìíràn ṣe ń hu oríṣìíríṣìí ìwà àrékérekè? Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀? Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ búburú rẹ̀, nígbà náà jẹ́ kí inú rẹ̀ kí ó dùn.”
16 Jehova Nyasaye noluongi ni yadh zeituni madongo maber man-gi olemo moolo maber. To mor matek mar yamb auka enowangʼe ka mach, kendo bedene notur.
Olúwa pè ọ́ ní igi olifi pẹ̀lú èso rẹ tí ó dára ní ojú. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líle ọ̀wọ́-iná ni yóò sun ún tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì di gígé kúrò.
17 Jehova Nyasaye Maratego mane opidhou kaka yath osegolo chik mondo unwangʼ masira, nikech od Israel kod od Juda osetimo maricho kendo gisechwanya ma iya owangʼ kuom wangʼo ubani ne Baal.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Israẹli àti Juda ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí si Baali.
18 Nikech Jehova Nyasaye nohulona marach mane gichano timo, ne angʼeyo wachno, nimar e kindeno nosefwenyona gima negitimo.
Nítorí Olúwa fi ọ̀tẹ̀ wọn hàn mí mo mọ̀ ọ́n; nítorí ní àsìkò náà ó fi ohun tí wọ́n ń ṣe hàn mí.
19 Asebedo kaka nyarombo mamuol mitero kar yengʼo; ne ok afwenyo nine gisechano timona marach, kagiwacho niya, “Watiek yath kaachiel gi olembene; wagole oko oaye piny joma ngima, mondo nyinge kik par kendo.”
Mo ti dàbí ọ̀dọ́-àgùntàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí a mú lọ fún pípa; n kò mọ̀ pé wọ́n ti gbìmọ̀ búburú sí mi wí pé: “Jẹ́ kí a run igi àti èso rẹ̀; jẹ́ kí a gé e kúrò ní orí ilẹ̀ alààyè, kí a má lè rántí orúkọ rẹ̀ mọ́.”
20 To, yaye Jehova Nyasaye Maratego, in ma ingʼado bura gi ratiro kendo pimo chuny kod paro, yie ane mirimbi kuom jogi, nimar in ema aseketoni kwayona.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo, tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn, jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn; nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.
21 “Emomiyo ma e gima Jehova Nyasaye wacho kuom jo-Anathoth madwaro ngimani, ‘Kik ikor e nying Jehova Nyasaye ka ok kamano to ibiro tho e lwetwa.’
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn arákùnrin Anatoti tí wọ́n ń lépa ẹ̀mí rẹ̀, tí wọ́n ń wí pé, ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìwọ ó kú láti ọwọ́ wa.’
22 Kuom mano Jehova Nyasaye Maratego wacho ni, ‘Anakumgi. Rowere mag-gi noneg gi ligangla, yawuotgi kod nyigi kech nonegi.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ pé, ‘Èmi yóò fì ìyà jẹ wọ́n, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn yóò tipasẹ̀ idà kú, ìyàn yóò pa àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
23 Onge ngʼato kuomgi manodongʼ, nikech anakel masira ne jo-Anathoth e higa manokumgie.’”
Kò ní ṣẹ́kù ohunkóhun sílẹ̀ fún wọn nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí àwọn ènìyàn Anatoti ní ọdún ìbẹ̀wò wọn.’”

< Jeremia 11 >