< Hosea 10 >

1 Israel ne en mzabibu malandore; ne onyago olembene owuon. Ka olembene ne medore, nomedo gero kende mag misango; kendo ka pinye ne medo mewo, to nomedo loso kido milamo.
Israẹli jẹ́ igi àjàrà tó gbilẹ̀ ó ń so èso fún ara rẹ̀. Bí èso rẹ̀ ṣe ń pọ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó ń kọ́ pẹpẹ sí i bí ilẹ̀ rẹ̀ ṣe ń ṣe rere o bu ọlá fún òkúta ìyàsọ́tọ̀ ère rẹ̀.
2 Chunygi opongʼ gi miriambo kendo koro nyaka gitingʼ mana kum marom kodgi. Jehova Nyasaye nomuk kendegi mag misango kendo kitegi ma gilamo bende nokethi.
Ọkàn wọn kún fún ìtànjẹ báyìí wọ́n gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn. Olúwa yóò wó pẹpẹ wọn palẹ̀ yóò sì pa gbogbo òkúta ìyàsọ́tọ̀ wọn run.
3 Eka giniwachi, “Waonge ruoth nikech watamore miyo Jehova Nyasaye luor. To kata kane wan gi ruoth, to dotimonwa angʼo?”
Nígbà náà ni wọn yóò wí pé, “A kò ní ọba nítorí tí a kò bọ̀wọ̀ fún Olúwa ṣùgbọ́n bí a tilẹ̀ ní ọba, kí ni yóò ṣe fún wa?”
4 Githoro wacho weche manono ka gikwongʼore gi miriambo, kendo giloso winjruok ma ok nyal konyogi; emomiyo buche mag larruok medore mana ka buya malandore e puothe mosepur.
Wọ́n ṣe ìlérí púpọ̀, wọ́n ṣe ìbúra èké, wọ́n da májẹ̀mú; báyìí ni ìdájọ́ hù sókè bí igi ìwọ̀ ni aporo oko, bi i koríko májèlé láàrín oko tí a ro.
5 Ji modak Samaria luoro osemako nikech nyaroya molos gi dhahabu mar Beth Aven. Joge noywage, kamano bende e kaka jodologe malamo nyiseche manono noywage, mago mosebedo gi mor kuom berne nikech osegole kuomgi kitere e twech.
Àwọn ènìyàn tí ń gbé Samaria bẹ̀rù nítorí ère abo màlúù tó wà ní Beti-Afeni. Àwọn ènìyàn rẹ̀ yóò ṣọ̀fọ̀ le e lórí bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà rẹ̀. Gbogbo àwọn tó láyọ̀ sì dídán rẹ̀, nítorí tí a ti mú lọ sí ìgbèkùn.
6 Enotingʼe kitere Asuria kaka mich ne ruoth maduongʼ. Efraim noma duongʼne to Israel nokuod wiye nikech nyisechene molos gi bao.
A ó gbé lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn fún ọba ńlá a ó dójútì Efraimu; ojú yóò ti Israẹli nítorí ìgbìmọ̀ rẹ̀.
7 Samaria kod ruodhige nolew gi malo mana ka bad yien malewo gi malo ewi pi.
Bí igi tó léfòó lórí omi ni Samaria àti àwọn ọba rẹ yóò sàn lọ.
8 Kuonde motingʼore malo mag anjawo nokethi, en emomiyo jo-Israel timo richo. Kuthe kod buya ema biro dongo maim kendegi mag misango. Eka giniwach ne gode madongo niya, “Umwauru!” Kendo ne gode matindo niya, “Rwombreuru kuomwa!”
Àwọn ibi gíga tí ẹ tí ń hùwà búburú ni a o parun, èyí ni ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli. Ẹ̀gún ọ̀gàn àti ẹ̀gún òṣùṣú yóò hù jáde, yóò sì bo àwọn pẹpẹ wọn. Wọn yóò sọ fún àwọn òkè gíga pé, “Bò wá mọ́lẹ̀!” àti fún àwọn òkè kéékèèké pé, “Ṣubú lù wá!”
9 “Nyaka aa ndalo mar Gibea, isebedo ka itimo richo, yaye Israel, to kanyo ema isesike. Donge lweny notieko jotim richo man Gibea?
“Láti ìgbà Gibeah, ni ó ti ṣẹ̀, ìwọ Israẹli, ìwọ sì tún wà níbẹ̀. Ǹjẹ́ ogun kò lé ẹ̀yin aṣebi ni Gibeah bá bí?
10 Ka ahero to abiro kumogi; ogendini nonywaknegi, maketgi e twech kuom richogi duto.
Nígbà tó bá tẹ́ mi lọ́rùn, èmi yóò fi ìyà jẹ wọ́n; Orílẹ̀-èdè yóò kó ra wọn jọ, wọ́n ó sì dojúkọ wọn, láti fi wọn sínú ìdè nítorí ìlọ́po ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
11 Efraim en nyaroya mobo mohero dino cham; omiyo anatwe jok e ngʼute maberno. Anariemb Efraim, to Juda nyaka pur, kendo Jakobo biro baro lowo.
Efraimu jẹ́ ọmọ abo màlúù tí a tí kọ́, to si fẹ́ràn láti máa pa ọkà; lórí ọrun rẹ̀ tó lẹ́wà ni èmi ó dí ẹrù wúwo lé. Èmi yóò mú kí a gun Efraimu bí ẹṣin Juda yóò tú ilẹ̀, Jakọbu yóò sì fọ́ ògúlùtu rẹ̀.
12 Chwouru adiera ne un uwegi, kaa-uru olemo mar hera ma ok rum, kendo baruru lopu mapok opur, nimar en kinde mar manyo Jehova Nyasaye, nyaka chop ool tim makare kuomu.
Ẹ gbin òdòdó fún ara yín, kí ẹ sì ká èso ìfẹ́ àìlópin. Ẹ tu ilẹ̀ yín tí a kò ro, nítorí pé ó ti tó àsìkò láti wá Olúwa, títí tí yóò fi dé, tí yóò sì rọ òjò òdodo lé yín lórí.
13 To nikech usechwoyo anjawo, usekayo timbe maricho, kendo usechamo olemb miriambo. Nikech usegeno kuom tekou uwegi kendo kuom jolwenju mangʼeny,
Ṣùgbọ́n ẹ tí gbin búburú ẹ si ka ibi, ẹ ti jẹ èso èké nítorí ẹ tí gbẹ́kẹ̀lé agbára yín àti àwọn ọ̀pọ̀ jagunjagun yín,
14 kuom mano koko mar lweny biro monjo jou, ma mi kuondeu mochiel motegno nomuki, mana kaka Shalman nomuko Beth Arbel e odiechieng lweny, kama mine kod nyithindgi nodhir mopodho.
ariwo ogun yóò bo àwọn ènìyàn yín kí gbogbo odi agbára yín ba le parun. Gẹ́gẹ́ bí Ṣalmani ṣe pa Beti-Arbeli run lọ́jọ́ ogun, nígbà tí a gbé àwọn ìyá ṣánlẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn.
15 Ma e kaka notimre ne un bende, yaye Bethel, nikech anjawo maru duongʼ. Ka odiechiengno ochopo, ruodh Israel notiek chuth.”
Báyìí ni a o sì ṣe sí ọ, ìwọ Beteli, nítorí pé ìwà búburú yín ti pọ̀jù. Ní àfẹ̀mọ́júmọ́ ọjọ́ náà, a o pa ọba Israẹli run pátápátá.

< Hosea 10 >