< Chakruok 24 >

1 Ibrahim noseti kendo hike noniangʼ, kendo Jehova Nyasaye nosegwedhe e yore duto.
Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà,
2 Nowacho ne jatichne maduongʼ mane rito gige ode duto niya, “Ket lweti e kind ema.
Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi.
3 Adwaro mondo ikwongʼrina gi nying Jehova Nyasaye, Nyasach polo kod piny ni ok ibi yudone wuoda dhako koa kuom nyi Kanaan ma an jadak e kindgini,
Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé.
4 to ibiro dhi thurwa kendo ir wedena mondo iyudne wuoda Isaka dhako.”
Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”
5 Jatichne nopenje niya, “Datim angʼo ka nyakono ok oyie biro koda e pinyni? Dadwok wuodi thuru kumane iayeno?”
Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ń kọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”
6 Ibrahim nowachone niya, “Nyaka ine ni ok idwoko wuoda kuno.
Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
7 Jehova Nyasaye, ma Nyasach polo mane ogola thurwa e dala wuora kendo nowuoyo koda kotimo koda singruok ni, ‘To ne nyikwayi nami pinyni’ kendo en owuon ema obiro oro malaikane nyimi mondo mi iyudne wuoda dhako kuno.
“Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀.
8 To ka nyakono ok dwar biro kodi, eka inibed thuolo kuom singruok ma atimo kodini. Ne mana ni ok idwoko wuoda kuno.”
Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
9 Omiyo jatijeno noketo lwete e kind em ruodhe Ibrahim kendo notimo singruok kode e wachni.
Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.
10 Eka jatijeno nokawo ngamia apar mag ruodhe, kod chiwo duto mabeyo mochako wuoth kodhi Aram-Naharaim (tiende ni, Mesopotamia) koluwo yo madhi dala matin mar Nahor.
Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori,
11 Noketo ngamia onindo piny machiegni gi soko but dala; ne en kar angʼich welo, seche mamon dhi umbo.
ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.
12 Eka nolemo niya, “Yaye Jehova Nyasaye Nyasach ruodha Ibrahim, gwedha kawuono, kendo nyis ngʼwononi ne ruodha Ibrahim.
Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi.
13 Ne, koro eri achungo e bath sokoni, kama nyi dalani biro umboe pi.
Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi.
14 Mad timreni ka awachone nyako moro ni, ‘Asayi, yie dapigi piny mondo mi amodhie,’ kendo ka dowachna ni, ‘modhi kendo abiro chiwo pi ni ngamia-gi duto’ to en ema mondo obed nyako ma iseyierone Isaka jatichni. Kamano anangʼe ni isenyiso ngʼwononi ne ruodha.”
Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘Mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”
15 Kane pok otieko lemo, Rebeka notucho kotingʼo dapige e goke. Ne en nyar Bethuel wuod Milka, mane chi Nahor owadgi Ibrahim.
Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
16 Nyakoni ne en jaber man-gi chia, mapok ongʼeyo dichwo! Nolor e soko, motwomo pi eka odwogo.
Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.
17 Jatich Ibrahim noringo kadhi romone mi owachone niya, “Akwayi, yie imiyae pi mondo amodhi.”
Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”
18 Eka nowacho niya, “Modhi, ruodha” kendo mapiyo nono noloro dapi e lwete momiye pi omodho.
Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.
19 Bangʼ kane osemiye pi modho, nowachone niya, “Abiro dhi umbo pi ne ngamia magi bende, nyaka gitiek modho.”
Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.”
20 Omiyo noloko pi mapiyo nono e besen, moringo odok e soko omo pi kendo noomo moromo ngamiagego duto.
Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn.
21 Jatich Ibrahim nolingʼ thi ma ok owuoyo, karange lingʼ-lingʼ mondo one ane ka Jehova Nyasaye osegwedho wuodhe.
Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Olúwa ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
22 Kane ngamia-go osetieko modho, ngʼatno nogolo tere mar um mar dhahabu ma pekne romo achiel kuom apar mar kilo kod bangli ariyo mag dhahabu mapekgi oromo nus kilo.
Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá.
23 Eka nopenje niya, “In nyar ngʼa? Yie inyisa bende dwayudie kar nindo dalau?”
Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
24 Nodwoke niya, “An nyar Bethuel, ma wuod Nahor gi Milka.”
Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi.”
25 Kendo nomedo wacho niya, “Wan kod lum kod chiemb ngamia mangʼeny kaachiel gi ot ma unyalo nindoe.”
Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”
26 Ngʼatno nopodho auma molamo Jehova Nyasaye,
Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa,
27 kowacho niya, “Duongʼ odogne Jehova Nyasaye, ma Nyasach ruodha Ibrahim, ma ok oseweyo nyiso adierane gi ngʼwonone ne ruodha. To an, Jehova Nyasaye osetelona e wuoth nyaka e od wede ruodha.”
wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”
28 Nyakono noringo modhi onyiso joodgi duto gik mane osetimorene.
Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.
29 Rebeka ne nigi owadgi miluongo ni Laban, kendo Laban noringo matek ka dhi ir ngʼatno mane ni e sokono.
Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò.
30 Kane Laban oseneno tere e um nyamin kod bangli ka ni e lwet nyamin kendo kane owinjo gima Rebeka wacho ni ngʼatno onyise, Laban nodhi ir ngʼatno moyude ka ochungʼ e bath ngamia-go machiegni gi soko.
Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi.
31 Laban nowachone niya, “Bi, in ngʼama Jehova Nyasaye ogwedho. Angʼo ma omiyo ichungʼ oko ka? Aseikoni ot kendo nitie kar ngamia bende.”
Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”
32 Kuom mano ngʼatno nodonjo e ot kendo misike mane ngamia otingʼo nogol kuomgi. Nomigi lum kod chiembgi mi nokelo pi ne jatich Ibrahim kod joge mondo olwokgo tiendegi.
Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn.
33 Eka nokel chiemo ne jatich Ibrahim to nowachonegi niya, “Ok abi chiemo kapok anyisou gima onego awachnu.” Laban nowachone niya, “Kara nyiswa.”
Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.” Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”
34 Kuom mano nowacho niya, “An jatich Ibrahim.
Nítorí náà, ó wí pé, “Ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi.
35 Jehova Nyasaye osegwedho ruodha ahinya kendo osebedo jamoko. Osemiye rombe kod dhok, fedha kod dhahabu, jotich machwo kod mamon gi ngamia kod punde.
Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
36 Sara, jaod ruodha osenywolone wuowi ka hike oniangʼ kendo ruodha osemiyo wuodeno mwandune duto.
Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní.
37 Ruodha nomiyo akwongʼora kowacho ni, ‘Kik iyudne wuoda nyako kuom nyi Kanaan ma adakie lopgini,
Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé,
38 to dhi e dala wuora kendo ir anywolana kendo iyudne nyako ne wuoda.’
ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’
39 “Eka ne apenjo ruodha ni, ‘Datim nangʼo ka nyakono ok oyie biro koda?’
“Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ń kọ́?’
40 “Nodwoke ni, ‘Jehova Nyasaye, ma asebedo ka awuotho e nyime biro ori gi malaikane kendo obiro gwedho wuodhi, mondo mi iyudne wuoda nyako moa kuom anywolana kendo e od wuora.
“Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi.
41 Ka idhi michopo ir jowa to singruogni ok nomaki, to bende ka gitamore miyi nyakono mondo ibigo, to kwongʼruokni ok nobed e wiyi.’
Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’
42 “Kane abiro e soko kawuono, nawacho ni, ‘Yaye Jehova Nyasaye, Nyasach ruodha Ibrahim, kalongʼoni, to gwedh wuodhani.
“Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí.
43 Ne, koro eri achungo e bath sokoni, ka jatich ma nyako obiro omo pi kendo awachone niya, “Yaye miyae pi amodhi,”
Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,”
44 kendo ka owachona niya, “Modhi, kendo abiro omo pi nyaka ne ngamia-gi bende,” to en ema mondo obed nyako ma Jehova Nyasaye oseyiero ne wuod ruodha.’
tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’
45 “Kane pok atieko lemo e chunya, Rebeka nochopo ka otingʼo dapi e goke. Nolor e soko mondo otuom pi kendo nawachone ni, ‘Yaye miyae pi amodhi.’
“Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’
46 “Piyo piyo nono noyieyo pi piny mi owacho ni, ‘Modhi kendo abiro miyo ngamia magi bende pi.’ Kuom mano namodho, kendo ngamia bende nomodho.
“Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.
47 “Napenje ni, ‘In nyar ngʼa?’ “En to nodwoka ni, ‘An nyar Bethuel, wuod Nahor gi Milka.’ “Eka ne aketo tere e ume gi bangli e lwete,
“Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’ “Ó sì wí fún mi pé, ‘Ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’ “Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́.
48 kendo napodho auma kalamo Jehova Nyasaye. Namiyo Jehova Nyasaye ma Nyasach ruodha Ibrahim duongʼ, mane telona e yo maber mayudo nyako ma nyakwar owad gi ruodha ne wuode.
Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀.
49 Koro nyisauru kuyie timo ngʼwono kod adieri ne ruodha; to ka ok kamano to nyisa mondo mi angʼe kuma achomo.”
Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”
50 Laban kod Bethuel nodwoke niya, “Ma-oa kuom Jehova Nyasaye ok wanyal wachoni gimoro amora.
Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ.
51 Rebeka eri; kawe mondo udhi, kendo obed chi wuod ruodhi, mana kaka Jehova Nyasaye osechiko.”
Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”
52 Kane jatich Ibrahim owinjo gima negiwacho, nopodho auma e nyim Jehova Nyasaye.
Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa.
53 Eka jatich Ibrahim nogolo gik moko mag dhahabu kod mag fedha kod lewni mi nomiyogi Rebeka; kendo nochiwo mich ma nengogi tek ne owadgi kod min-gi.
Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú.
54 Eka jatich Ibrahim kod jogo mane ni kode nochiemo kendo ometho kendo ne ginindo kanyo. Kane gichiewo kinyne gokinyi nowacho niya, “Weuru adog ir ruodha.”
Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà. Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”
55 To owad gi Rebeka kod min-gi nodwoke niya, “We nyakoni odongʼ kodwa kuom ndalo apar kata moloyo kanyo; eka udhi.”
Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”
56 To jatich Ibrahim nowachonegi niya, “Kik ugengʼna, to weyauru adog ir ruodha, nikech Jehova Nyasaye osegwedho wuodha.”
Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”
57 Eka negiwacho niya, “We waluong nyako mondo wapenje kuom wachni.”
Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í.”
58 Kuom mano negiluongo Rebeka kendo gipenje niya, “Inyalo dhi gi ngʼatni?” Rebeka nodwokogi niya, “Abiro dhi.”
Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”
59 Kuom mano ne giweyo Rebeka odhi kaachiel gi nyako mane opire kod jatich Ibrahim gi joge.
Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ.
60 Kendo negigwedho Rebeka kagiwachone niya, “Nyathiwa, bed min ji gana gi gana; mad nyikwayi medre ma kaw mier madongo mag wasikgi.”
Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé, “Ìwọ ni arábìnrin wa ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”
61 Eka Rebeka kod jotije ma nyiri noikore moidho ngamia-gi mi gidhi gi jatich Ibrahim. Kuom mano jatich Ibrahim nokawo Rebeka kendo gidhi.
Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
62 Noyudo ka koro Isaka oa Beer-Lahai-Roi, nikech noyudo odak Negev.
Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé.
63 Ka noyudo owuotho e pap godhiambo chiengʼ moro ka owuoyo gi Nyasaye, kendo kane orango malo, noneno ngamia kabiro.
Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá.
64 Rebeka bende norango malo moneno Isaka. Nolor piny koa ewi ngamia
Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ,
65 kendo nopenjo jatich Ibrahim niya, “Macha en ngʼa manie pap mabiro romonwa cha?” Jatich nodwoke niya, “En ruodha.” Eka nokawo nanga ma oumogo wangʼe.
ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?” Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.
66 Eka jatich nonyiso Isaka gik moko duto mane osetimo.
Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe.
67 Isaka notero Rebeka e hemb Sara min-gi, kendo Isaka nokendo Rebeka. Kuom mano Rebeka nobedo chi Isaka, kendo Isaka nohero Rebeka gihera mamalo; kendo Isaka ne ok obedo gi parruok bangʼ tho min mare.
Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.

< Chakruok 24 >