< Chakruok 17 >
1 Kane Abram ne ja-higni piero ochiko gochiko, Jehova Nyasaye nofwenyorene mi nowachone niya, “An Nyasaye Maratego; bed ngʼama odimbore e nyima kendo maonge ketho.
Ní ìgbà tí Abramu di ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùn-ún ọdún, Olúwa farahàn án, ó sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, máa rìn níwájú mi, kí o sì jẹ́ aláìlábùkù.
2 Abiro guro singruokna e kinda kodi kendo anamed kothi obed mangʼeny.”
Èmi yóò sì fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò sì sọ ọ́ di púpọ̀ gidigidi.”
3 Abram nopodho auma e nyim Nyasaye kendo Nyasaye nowachone niya,
Abramu sì dojúbolẹ̀, Ọlọ́run sì wí fún un pé.
4 “Singruok matimo kodi ema: Inibed wuon ogendini mangʼeny.
“Ní ti èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ nìyí. Ìwọ yóò di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.
5 Ok nochak oluongi ni Abram; to enoluongi ni Ibrahim, nimar aseketi ibedo wuon ogendini mangʼeny.
A kì yóò pe orúkọ rẹ̀ ní Abramu mọ́, bí kò ṣe Abrahamu, nítorí, mo ti sọ ọ́ di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.
6 Anamiyi nyikwayo mathoth; ginidog ogendini madongo kendo ruodhi nowuog kuomgi.
Èmi yóò mú ọ bí si lọ́pọ̀lọ́pọ̀, ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè ni èmi yóò sì mú ti ara rẹ jáde wá, àwọn ọba pẹ̀lú yóò sì ti inú rẹ jáde.
7 Anagur singruokna manyaka chiengʼ e kinda kodi gi nyikwayi kod tienge mabiro, mi anabed Nyasachi kendo Nyasach nyikwayi nyaka chiengʼ.
Èmi yóò sì gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ láàrín tèmi tìrẹ, ní májẹ̀mú ayérayé àti láàrín irú-ọmọ rẹ ní ìran-ìran wọn, láti máa ṣe Ọlọ́run rẹ àti ti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ.
8 Piny Kanaan duto makoro udakieni anamiyi kaachiel gi nyikwayi mondo obed girkeni manyaka chiengʼ kendo anabed Nyasachgi.”
Gbogbo ilẹ̀ Kenaani níbi tí ìwọ ti ṣe àjèjì ni èmi yóò fi fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ láéláé. Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.”
9 Eka Nyasaye nowacho ne Ibrahim niya, “In kaachiel gi nyikwayi kod tienge mabiro nyaka rit singruokna.
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Abrahamu pé, “Ìwọ máa pa májẹ̀mú mi mọ́, ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ àti àwọn ìran tí ó ń bọ̀.
10 Singruokna manyaka iriti, in kaachiel gi nyikwayi ema: Ngʼato ka ngʼata madichwo e kindu nyaka ter nyangu.
Èyí ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ àti ìran rẹ lẹ́yìn rẹ, májẹ̀mú tí ẹ̀yin yóò máa pamọ́. Gbogbo ọkùnrin yín ni a gbọdọ̀ kọ ní ilà.
11 Nyaka teru nyangu kendo ma nobed ranyisi mar singruokna e kinda kodu.
Ẹ̀yin yóò kọ ara yín ní ilà, èyí ni yóò jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrín tèmi tiyín.
12 Kuom tienge mabiro ngʼato angʼata madichwo monywol e uteu kata ongʼiew gi pesa ma ok kothu nyaka ter nyangu, e odiechiengʼ mar aboro bangʼ nywolne.
Ní gbogbo ìran tí ń bọ̀ lẹ́yìn, gbogbo ọkùnrin ni a gbọdọ̀ kọ ni ilà ní ọjọ́ kẹjọ tí a bí wọn, àti àwọn tí a bí ní ilé rẹ, tàbí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àwọn àjèjì, àwọn tí kì í ṣe ọmọ rẹ̀. Èyí yóò sì jẹ́ májẹ̀mú láéláé tí yóò wà láàrín Èmi àti irú-ọmọ rẹ.
13 Nyaka tergi nyangu bedni onywolgi e uteu kata ongʼiewogi gi pesa. Singruokna man kuom ringreu nyaka bed mosiko.
Ìbá à ṣe ẹni tí a bí nínú ilé rẹ, tàbí ẹni tí o fi owó rà, a gbọdọ̀ kọ wọ́n ní ilà; májẹ̀mú mí lára yín yóò jẹ́ májẹ̀mú ayérayé.
14 Ngʼato angʼata madichwo, mane ok oter nyangu e ringruok, nogol oko kuom jogi; nikech oseketho singruokna.”
Gbogbo ọmọkùnrin tí kò bá kọ ilà, tí a kò kọ ní ilà abẹ́, ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀, nítorí pé ó da májẹ̀mú mi.”
15 Nyasaye nomedo wachone Ibrahim niya, “Koro ok inichak iluong Sarai chiegi ni Sarai, to iniluonge ni Sara.
Ọlọ́run wí fún Abrahamu pé, “Ní ti Sarai, aya rẹ̀, ìwọ kì yóò pè é ní Sarai mọ́, bí kò ṣe Sara.
16 Anagwedhe kendo anamiyi nyathi ma wuowi koa kuome. Anagwedhe mi nobed min ogendini; kendo ruodhi mag ogendini noa kuome.”
Èmi yóò bùkún fún un, èmi yóò sì fun ọ ní ọmọkùnrin kan nípasẹ̀ rẹ̀. Èmi yóò bùkún un, yóò sì di ìyá àwọn orílẹ̀-èdè, àwọn ọba àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì ti ara rẹ̀ jáde wá.”
17 Ibrahim nopodho auma; monyiero kowacho e chunye niya, “Bende ngʼama ja-higni mia achiel nyalo nywolo wuowi? Bende Sara ma ja-higni piero ochiko nyalo nywolo nyathi?”
Abrahamu sì dojúbolẹ̀, ó rẹ́rìn-ín, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “A ó ha bí ọmọ fún ẹni ọgọ́rùn-ún ọdún? Sara tí í ṣe ẹni àádọ́rùn-ún ọdún yóò ha bímọ bí?”
18 Kendo Ibrahim nowacho ne Nyasaye niya, “Mano nyalo mana timore kaponi Ishmael odak e bwo ngʼwono mari!”
Abrahamu sì wí fún Ọlọ́run pé, “Sá à jẹ́ kí Iṣmaeli kí ó wà láààyè lábẹ́ ìbùkún rẹ.”
19 Eka Nyasaye nodwoke niya, “Ooyo, en mana Sara chiegi ema nonywolni wuowi, kendo iniluong nyinge ni Isaka. Anaket singruokna kode kaka singruok manyaka chiengʼ ne nyikwaye.
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo gbọ́, ṣùgbọ́n Sara aya rẹ̀ yóò bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isaaki, èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀ ní májẹ̀mú ayérayé àti àwọn irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
20 To bende asewinjo kwayo mikwayo nikech Ishmael, omiyo anagwedhe, kendo anamiye nyithindo gi nyikwayo mangʼeny.
Ṣùgbọ́n ní ti Iṣmaeli, mo gbọ́ ohun tí ìwọ wí, èmi yóò bùkún fún un nítòótọ́, èmi ó sì mú un bí sí i, yóò sì pọ̀ sí i, òun yóò sì jẹ́ baba fún àwọn ọmọ ọba méjìlá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.
21 Makmana singruokna abiro chopo gi Isaka ma Sara biro nywolone e kinde maka ma e higa mabiro.”
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú Isaaki, ẹni tí Sara yóò bí fún ọ ni ìwòyí àmọ́dún.”
22 Kane Nyasaye osetieko wuoyo kod Ibrahim, noweye modhi.
Nígbà tí ó ti bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Ọlọ́run sì gòkè lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
23 E odiechiengno Ibrahim nokawo wuode Ishmael kod jogo duto machwo monywol e ode kata mane ongʼiewo gi pesa, kendo noterogi nyangu, mana kaka Nyasaye nonyise.
Ní ọjọ́ náà gan an ni Abrahamu mú Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ àti àwọn ẹrú tí a bí ní ilé rẹ̀ àti àwọn tí ó fi owó rà, ó sì kọ wọ́n ní ilà. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kọ gbogbo ọkùnrin tí ń bẹ ní ilé rẹ̀ ní ilà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Ọlọ́run.
24 Ibrahim ne ja-higni piero ochiko gochiko kane otere nyangu,
Abrahamu jẹ́ ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùn-ún ọdún nígbà tí a kọ ọ́ ní ilà.
25 to wuode Ishmael ne ja-higni apar gadek.
Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlá.
26 Ibrahim kod wuode Ishmael noter nyangu odiechiengno.
Ní ọjọ́ náà gan an ni a kọ Abrahamu ní ilà pẹ̀lú Iṣmaeli ọmọ rẹ̀ ọkùnrin.
27 Kendo chwo duto mane ni e od Ibrahim, kaachiel gi monywol e ode kata ma ongʼiewo, bende noter nyangu kode.
Àti gbogbo ọkùnrin tí ó wà ní ilé Abrahamu, ìbá à ṣe èyí tí a bí ní ilé rẹ̀ tàbí èyí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àlejò ni a kọ ní ilà pẹ̀lú rẹ̀.