< Chakruok 13 >

1 Omiyo Abram nowuok Misri gi chiege kod Lut kod gik moko duto mane en-go kochomo Negev.
Abramu sì gòkè láti Ejibiti lọ sí ìhà gúúsù, pẹ̀lú aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní àti Lọti pẹ̀lú.
2 Abram koro nosebedo ja-mwandu ahinya mar jamni gi fedha kod dhahabu.
Abramu sì ti di ọlọ́rọ̀ gidigidi; ní ẹran ọ̀sìn, ó ní fàdákà àti wúrà.
3 Nodhi nyime kod wuoth koa Negev kobuoro e yo nyaka nochopo Bethel, kumane okwongo geroe hembe e kind Bethel kod Ai,
Láti gúúsù, ó ń lọ láti ibìkan sí ibòmíràn títí ó fi dé ilẹ̀ Beteli, ní ibi tí àgọ́ rẹ̀ ti wà ní ìṣáájú rí, lágbedeméjì Beteli àti Ai.
4 kendo kama nokwongo geroe kendo mar misango. Kanyo Abram nolamoe Jehova Nyasaye.
Ní ibi pẹpẹ tí ó ti tẹ́ síbẹ̀ ní ìṣáájú, níbẹ̀ ni Abramu sì ń ké pe orúkọ Olúwa.
5 To Lut ma bende ne wuotho kod Abram neni kod jamni matindo mathoth, gi kweth mag dhok kod hembe.
Àti Lọti pẹ̀lú, tí ó ń bá Abramu rìn kiri, ní agbo ẹran, ọ̀wọ́ ẹran àti àgọ́.
6 Kuonde mag kwath ne tin mane ok nyal romogi ka gidak kanyakla, nimar mwandu mane gin-go nomedore mane ok ginyal dak kaachiel.
Ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà kò le gbà wọ́n tí wọ́n bá ń gbé pọ̀, nítorí, ohun ìní wọn pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, dé bi wí pé wọn kò le è gbé pọ̀.
7 Kendo dhawo nowuok e kind jakwadh Abram kod jokwadh Lut. E kindeno jo-Kanaan kod jo-Perizi ne pod odak e pinyno.
Èdè-àìyedè sì bẹ̀rẹ̀ láàrín àwọn darandaran Abramu àti ti Lọti. Àwọn ará Kenaani àti àwọn ará Peresi sì ń gbé ní ilẹ̀ náà nígbà náà.
8 Omiyo Abram nowacho ne Lut niya, “Kik dhawo bed e kindwa kata e kind jokwadhi kod jokwadha nikech wan wede.
Abramu sì wí fún Lọti pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí èdè-àìyedè kí ó wà láàrín èmi àti ìrẹ, àti láàrín àwọn darandaran wa, nítorí pé ẹbí kan ni àwa ṣe.
9 Donge piny duto ni e lweti? Ber wapogre, kidhi koracham to adhi korachwich; to kidhi korachwich to adhi koracham.”
Gbogbo ilẹ̀ ha kọ́ nìyí níwájú rẹ? Jẹ́ kí a pínyà. Bí ìwọ bá lọ sí apá ọ̀tún, èmi yóò lọ sí apá òsì, bí ó sì ṣe òsì ni ìwọ lọ, èmi yóò lọ sí apá ọ̀tún.”
10 Lut notingʼo wangʼe moneno paw Jordan duto ka nitie gi pi maber mana ka puoth Jehova Nyasaye, machalo gi piny Misri kochiko Zoar. (Mano notimore kane pok Jehova Nyasaye oketho Sodom kod Gomora.)
Lọti sì gbójú sókè, ó sì ri wí pé gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jordani ni omi rin dáradára bí ọgbà Olúwa, bí ilẹ̀ Ejibiti, ní ọ̀nà Soari. (Èyí ní ìṣáájú kí Olúwa tó pa Sodomu àti Gomorra run.)
11 Omiyo Lut noyiero pewe duto mag Jordan kendo nowuok kochomo yo wuok chiengʼ. Mano e kaka ji ariyogi nopogore.
Nítorí náà Lọti yan gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jordani yìí fún ara rẹ̀, ó sì ń lọ sí ọ̀nà ìlà-oòrùn. Òun àti Abramu sì pínyà.
12 Abram nodak e piny Kanaan, to Lut nodak e kind mier madongo manie paw Jordan kendo nogero hembene machiegni gi Sodom.
Abramu ń gbé ni ilẹ̀ Kenaani, Lọti sì jókòó ní ìlú agbègbè àfonífojì náà, ó sì pàgọ́ rẹ̀ títí dé Sodomu.
13 Koro jo-Sodom ne gin joma okethore kendo matimo richo mag wangʼ teko e nyim Jehova Nyasaye.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Sodomu jẹ́ ènìyàn búburú, wọn sì ń dẹ́ṣẹ̀ gidigidi ni iwájú Olúwa.
14 Jehova Nyasaye nowacho ne Abram kane Lut osepogore kode niya, “Tingʼ wangʼi gi kuma in tiere kendo ingʼi yo nyandwat gi yo milambo, yo wuok chiengʼ kod yo podho chiengʼ.
Olúwa sì wí fún Abramu lẹ́yìn ìpinyà òun àti Lọti pé, “Gbé ojú rẹ sókè nísinsin yìí, kí o sì wò láti ibi tí o gbé wà a nì lọ sí ìhà àríwá àti sí ìhà gúúsù, sí ìlà-oòrùn àti sí ìwọ̀ rẹ̀.
15 Piny duto ma inenono abiro miyi gi nyikwayi nyaka chiengʼ.
Gbogbo ilẹ̀ tí ìwọ ń wò o nì ni èmi ó fi fún ọ àti irú-ọmọ rẹ láéláé.
16 Anami nyikwayi bed mangʼeny mana ka buru mae lowo; ma ka ngʼato nyalo kwano buru, to nyikwayi bende inyalo kwan.
Èmi yóò mú kí irú-ọmọ rẹ kí ó pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí ó bá ṣe pé ẹnikẹ́ni bá le è ka erùpẹ̀ ilẹ̀, nígbà náà ni yóò tó lè ka irú-ọmọ rẹ.
17 Aa malo kendo iwuothi e tungʼ piny koni gi koni, nikech amiyigo.”
Dìde, rìn òró àti ìbú ilẹ̀ náà já, nítorí ìwọ ni Èmi yóò fi fún.”
18 Omiyo Abram nopudho hembene mi odhi odak but yiende madongo mag Mamre ei Hebron, kamane ogeroe kendo mar misango ne Jehova Nyasaye.
Nígbà náà ni Abramu kó àgọ́ rẹ̀, ó sì wá, ó sì jókòó ní ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre, tí ó wà ní Hebroni. Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan sí fún Olúwa.

< Chakruok 13 >