< Chakruok 12 >

1 Jehova Nyasaye nowacho ne Abram niya, “Dar iwe pinyu gi jou kod joodu mondo idhi e piny ma abiro nyisi.
Olúwa sì wí fún Abramu, “Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.
2 “Anaketi oganda maduongʼ kendo anagwedhi; anami nyingi bed gi huma, kendo anami ibed gweth ne ji.
“Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì bùkún fún ọ; èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá, ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.
3 Anagwedh jogo ma gwedhi kendo anakwongʼ jogo makwongʼi, kendo ogendini duto manie piny nogwedhi nikech in.”
Èmi yóò bùkún fún àwọn tí ó súre fún ọ, ẹni tí ó fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré; nínú rẹ ni a ó bùkún gbogbo ìdílé ayé.”
4 Omiyo Abram nowuok kaka Jehova Nyasaye nosenyise kendo Lut nodhi kode. Abram ne ja-higni piero abiriyo gabich kane owuok Haran.
Bẹ́ẹ̀ ni Abramu lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọti náà sì bá a lọ. Abramu jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Harani.
5 Nokawo chiege Sarai, gi Lut wuod owadgi, gi mwandu duto mane gisechoko kod wasumbini duto mane gin-go Haran, kendo negichako wuoth mar dhi Kanaan mi negichopo kuno.
Abramu sì mú Sarai aya rẹ̀, àti Lọti ọmọ arákùnrin rẹ̀: gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti kójọ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n ní ní Harani. Wọ́n sì jáde lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Wọ́n sì gúnlẹ̀ síbẹ̀.
6 Abram nowuotho e piny mochopo Shekem e tiend yath maduongʼ mar More. E kindego jo-Kanaan nodak e pinyno.
Abramu sì rìn la ilẹ̀ náà já títí dé ibi igi ńlá kan tí à ń pè ni More ní Ṣekemu. Àwọn ará Kenaani sì wà ní ilẹ̀ náà.
7 Jehova Nyasaye nofwenyore ne Abram mi owachone niya, “Anami kothi pinyni.” Omiyo Abram nogero kendo mar misango kanyo ne Jehova Nyasaye mane osefwenyorene.
Olúwa sì farahan Abramu, ó sì wí fún un pé, “Irú-ọmọ rẹ ni Èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún.” Abramu tẹ́ pẹpẹ kan síbẹ̀ fún Olúwa tí ó fi ara hàn án.
8 Noa kanyo modhi e piny gode ma yo wuok chiengʼ mar Bethel kendo nogero hembe e kind Bethel man yo podho chiengʼ to gi Ai man yo wuok chiengʼ. Kanyo nogeroe kendo mar misango ne Jehova Nyasaye kendo nolamo Jehova Nyasaye kanyo.
Ó sì kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè àwọn òkè kan ní ìhà ìlà-oòrùn Beteli, ó sì pàgọ́ rẹ̀ síbẹ̀. Beteli wà ní ìwọ̀-oòrùn, Ai wà ní ìlà-oòrùn. Ó tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ó sì ké pe orúkọ Olúwa.
9 Eka Abram nochako wuoth kendo odhi nyime giwuoth kochomo Negev.
Nígbà náà ni Abramu tẹ̀síwájú sí ìhà gúúsù.
10 Koro kech nomako pinyno kendo Abram nodhi Misri mondo odhi odag kuno kuom kinde matin nikech kech ne duongʼ.
Ìyàn kan sì mú ní ilẹ̀ náà, Abramu sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ṣe àtìpó níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, nítorí ìyàn náà mú gidigidi.
11 Kane ochiegni donjo Misri, nowacho ne Sarai chiege niya, “Angʼeyo kaka in dhako ma jaber.
Bí ó ti ku díẹ̀ kí ó wọ Ejibiti, ó wí fún Sarai, aya rẹ̀ pé, “Mo mọ̀ pé arẹwà obìnrin ni ìwọ,
12 Ka jo-Misri oneni, gibiro wacho, ‘Ma en chiege.’ Mi gininega to inires ngimani.
nígbà tí àwọn ará Ejibiti bá rí ọ, wọn yóò wí pé, ‘Aya rẹ̀ nìyí.’ Wọn yóò si pa mí, ṣùgbọ́n wọn yóò dá ọ sí.
13 Wach ni in nyamera, mondo mi gitimna maber kendo ngimana obedie nikech in.”
Nítorí náà, sọ pé, arábìnrin mi ni ìwọ, wọn yóò sì ṣe mí dáradára, a ó sì dá ẹ̀mí mi sí nítorí tìrẹ.”
14 Kane Abram ochopo Misri, jo-Misri noneno Sarai kaka ne en dhako ma jaber miwuoro.
Nígbà tí Abramu dé Ejibiti, àwọn ará Ejibiti ri i pé aya rẹ̀ rẹwà gidigidi.
15 Kendo kane jodong Farao oneno Sarai, negiwuoro berne ne Farao kendo nokawe motere kar dak ruoth.
Nígbà tí àwọn ìjòyè Farao sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú Farao, wọ́n sì mú un lọ sí ààfin.
16 Farao nomiyo Abram rit maber nikech Sarai, kendo nomiyo Abram rombe, dhok, pundane machwo gi mamon, wasumbini machwo gi mamon kod ngamia.
Ó sì kẹ́ Abramu dáradára nítorí Sarai, Abramu sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú ìbákasẹ.
17 To Jehova Nyasaye nosando Farao gi joode gi tuoche madongo nikech Sarai chi Abram.
Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn búburú sí Farao àti ilé rẹ̀, nítorí Sarai aya Abramu.
18 Omiyo Farao noluongo Abram kendo nopenje niya, “Angʼo ma isetimonani? Ere gima omiyo ne ok inyisa ni Sarai en chiegi?
Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Abramu, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe?
19 Mara angʼo ne iwuonda ni Sarai en nyameru momiyo akawe mondo obed chiega? Chiegi eri, kawe mondo udhi.”
Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí o sì máa lọ.”
20 Eka Farao nogolo chik ne joge mondo ogol Abram, chiege gi gige duto kendo gikowogi oko mar pinyno.
Nígbà náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Abramu, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.

< Chakruok 12 >