< Ezekiel 37 >

1 Teko Jehova Nyasaye ne ni kuoma, kendo ne ogola oko kuom teko mar Roho mare mi otera e dier holo moro; kama choke opongʼo.
Ọwọ́ Olúwa wà lára mi, ó sì mú mi jáde pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, ó mú kí ń wà ní àárín àfonífojì; ti o kún fún àwọn egungun.
2 Nowuotho koda e dier chokego koni gi koni, komako lweta, kendo naneno choke madongo mangʼeny motamore akwana, kanie dier holono; ne gin choke motwo kururu.
Ó mú mi lọ síwájú àti sẹ́yìn láàrín wọn, èmi sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn egungun ní orí ilẹ̀ àfonífojì, àwọn egungun tí ó gbẹ gan.
3 Ne openja niya, “Wuod dhano, chokegi bende nyalo bet mangima adier?” Ne awacho niya, “Yaye Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto, in kendi ema inyalo ngʼeyo.”
Olúwa sì bi mí léèrè, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ àwọn egungun wọ̀nyí lè yípadà di àwọn ènìyàn bí?” Èmi sì wí pé, “Ìwọ Olúwa Olódùmarè, ìwọ nìkan ni o lè dáhùn sí ìbéèrè yìí.”
4 Eka nowachona niya, “Kor wach ni chokegi kiwachonegi niya, Choke motwo, winjuru wach Jehova Nyasaye!
Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn egungun kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin egungun gbígbẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
5 Ma e gima Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho ni chokegi: Abiro kudho much ngima kuomu, mi unudok mangima.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn egungun wọ̀nyí. Èmi yóò mú kí èémí wọ inú yín ẹ̀yin yóò sì wá di ààyè.
6 Abiro keto leche kuomu kendo abiro miyo ringʼo gi pien um dendu kendo abiro kudho much ngima kuomu mi unudok mangima. Eka unungʼe ni An e Jehova Nyasaye.”
Èmi yóò so iṣan ara mọ́ ọn yín, Èmi yóò sì mú kí ẹran-ara wá sí ara yín, Èmi yóò sì fi awọ ara bò yín, Èmi yóò sì fi èémí sínú yín, ẹ̀yin yóò sì wà ní ààyè. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
7 Omiyo ne akoro wach kaka ne ochika. To kane oyudo akoro wach kamano, to ne apo ka awinjo ka choke rwadore matek, kendo chokego nochako tudore, ka moro ka moro kuomgi chomore gi wadgi.
Nítorí náà ni mo ṣe sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti pa á láṣẹ fún mi. Bí mo sì ti ń sọtẹ́lẹ̀, ariwo wá, ìró tí ó kígbe sókè, àwọn egungun sì wà papọ̀, egungun sí egungun.
8 Ne angʼicho kendo naneno ka leche gi ringʼo chako bet e chokego, kendo pien noumogi, to kata kamano ne pod gionge gi ngima.
Mo wò ó, iṣan ara àti ẹran-ara farahàn lára wọn, awọ ara sì bò wọ́n, ṣùgbọ́n kò sí èémí nínú wọn.
9 Eka nowacho niya, “Kor wach ni yamo, in wuod dhano, kendo wachne ni, Ma e gima Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho: Kudhi kia e tunge angʼwen mag piny, kendo idonj kuom joma nosenegi mondo gidok mangima.”
Lẹ́yìn náà ni ó sọ fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí èémí; sọtẹ́lẹ̀, ọmọ ènìyàn, kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: wá láti atẹ́gùn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìwọ èémí, kí ó sì mí èémí sínú àwọn tí a pa wọ̀nyí, kí wọn kí ó lè wà ní ààyè.’”
10 Omiyo ne akoro kaka ne ochika, mi much ngima nodonjo kuomgi; kendo negidoko mangima; ma gichungʼ malo gi tiendgi, ka gin oganda lweny maduongʼ miwuoro!
Nítorí náà, mo sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹsẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.
11 Eka nowachona niya, “Wuod dhano, jo-Israel chalo gi chokegi. Giwacho ni, ‘Chokewa otwo kendo genowa orumo; osengʼad karwa oko.’
Lẹ́yìn náà ó sọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Israẹli. Wọ́n sọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’
12 Emomiyo kor wach kendo iwachnegi ni: ‘Ma e gima Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho: Yaye un joga, abiro elo lieteu mi agolu oko kendo aduogu e piny Israel.
Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò ṣí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Israẹli.
13 Eka un, ma un joga, unungʼe ni An e Jehova Nyasaye, ka anael lieteu mi agolu oko kuomgi.
Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti ṣí ibojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nínú ibojì yín.
14 Abiro keto Roho mara kuomu mi udok mangima, kendo abiro miyo udag e pinyu uwegi. Eka unungʼe ni an Jehova Nyasaye ema asewuoyo kendo asetimo kamano. Jehova Nyasaye ema owacho.’”
Èmi yóò fi èémí mi sínú yín, ẹ̀yin yóò sì yè, èmi yóò sì mú kí ẹ fi lélẹ̀ ní ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi sì ti ṣe ni Olúwa wí.’”
15 Wach Jehova Nyasaye nobirona kama:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá:
16 “Wuod dhano, kaw bao moro mopa mondo indikie wechegi ni, ‘Mar jo-Juda gi dhout Israel mamoko mawinjore kode.’ Eka ikaw bao mopa machielo kendo indikie wechegi, ‘Mar Josef (ma en mar Efraim) kod dhout Israel mamoko duto mawinjore kode.’
“Ọmọ ènìyàn, mú igi pátákó kan kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti Juda àti ti Israẹli tí ó ní àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’ Lẹ́yìn náà, kí ó mú igi pátákò mìíràn kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti tí Josẹfu (tí ó túmọ̀ sí ti Efraimu) àti gbogbo ilé Israẹli tí ó ni àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’
17 Riw bepe ariyogo obed bao achiel mondo gibed gimoro achiel e lweti.
So wọ́n papọ̀ sí ara igi kan nítorí náà wọn yóò di ọ̀kan ní ọwọ́ rẹ.
18 “Ka jou openji ni, ‘Donge inyalo nyiswae tiend wachni?’
“Nígbà tí àwọn ara ìlú rẹ bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Ṣé ìwọ kò ní sọ ohun tí èyí túmọ̀ sí fún wa?’
19 To wachnegi ni, ‘Ma e gima Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho: Abiro kawo bap Josef, manie lwet Efraim, kod dhout Israel mamoko duto mawinjore kode, kendo abiro tude gi bap Juda, mi gidok bepe mopa achiel, kendo gibiro doko bepe mopa achiel e lweta.’
Sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò gba igi Josẹfu—èyí tí ó wà ní ọwọ́ Efraimu—àti ti ẹ̀yà Israẹli tí ó parapọ̀ mọ́ ọn, kí ó sì só papọ̀ mọ́ igi Juda, láti sọ wọ́n di igi kan ṣoṣo, wọn yóò sì di ọ̀kan ní ọwọ́ mi.’
20 Lier kete misendikogo e nyim wengegi
Gbé igi pátákó tí ó kọ nǹkan sí i sókè ní iwájú wọn,
21 kendo iwachnegi ni, ‘Ma e gima Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho: Abiro golo jo-Israel oko e dier ogendini kuonde ma gisedhiyoe. Abiro chokogi kagologi koni gi koni mi aduog-gi e pinygi giwegi.
kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Israẹli jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ. Èmi yóò ṣà wọ́n jọ pọ̀ láti gbogbo agbègbè, èmi yóò sì mú wọn padà sí ilẹ̀ ara wọn.
22 Abiro miyo gibed oganda achiel e piny, ewi gode mag Israel. Ruoth achiel ema noritgi kargi duto, kendo ok ginichak gibed pinje ariyo, kata pinjeruodhi ariyo mopogore.
Èmi yóò ṣe wọ́n ní orílẹ̀-èdè kan ní ilẹ̀ náà, ní orí òkè Israẹli, ọba kan ni yóò wà lórí gbogbo wọn, wọn kì yóò sì jẹ́ orílẹ̀-èdè méjì mọ́, tàbí kí a pín wọn sí ìjọba méjì.
23 Ok ginichak gidwanyre gi nyisechegi ma giloso gi kido mamono, kata gi timo gik makwero, nikech anawargi kuom richogi duto mag dok chien, kendo anapwodhgi. Ginibed joga, to anabed Nyasachgi.’
Wọn kì yóò sì tún fi àwọn òrìṣà wọn ba ara wọn jẹ́ mọ́, tàbí ohun ìríra wọn, tàbí ohun ìrékọjá wọn: ṣùgbọ́n èmi yóò gbà wọn là kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àgàbàgebè wọn, èmi yóò sì wẹ̀ wọn mọ́. Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
24 “‘Daudi jatichna nobed ruodhgi kendo giduto ginibed gi jakwath achiel. Gibiro luwo chikena kendo gibiro rito buchena ka gitangʼ.
“‘Dafidi ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ ọba lórí wọn, gbogbo wọn yóò sì ní olùṣọ àgùntàn kan. Wọn yóò sì tẹ̀lé òfin mi, wọn yóò sì ṣe àníyàn láti pa àṣẹ mi mọ́.
25 Gibiro dak e piny mane amiyo jatichna ma Jakobo, ma en piny mane kwereu odakie. Gin kaachiel gi nyithindgi kod nyikwagi, gibiro dak kuno nyaka chiengʼ, kendo Daudi jatichna nobed ruodhgi nyaka chiengʼ.
Wọn yóò gbé ní ilẹ̀ tí mo fún Jakọbu ìránṣẹ́ mi, ilẹ̀ tí àwọn baba yín ń gbé. Àwọn àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn ni yóò máa gbé ibẹ̀ láéláé, ìránṣẹ́ mi Dafidi ni yóò jẹ́ Ọmọ-aládé wọn láéláé.
26 Abiro timo singruok mar kwe kodgi, enobed singruok mochwere. Abiro gurogi motegno kendo abiro miyo kwan-gi medre, kendo abiro keto kara maler mar lemo e diergi nyaka chiengʼ.
Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, yóò sì jẹ́ májẹ̀mú títí ayérayé. Èmi yóò gbé wọn kalẹ̀, èmi yóò sì sọ wọ́n di púpọ̀ ní iye, èmi yóò sì gbé ilé mímọ́ mi kalẹ̀ ní àárín wọn títí láé.
27 Kar dakna nobed kodgi; anabed Nyasachgi, kendo ginibed joga.
Ibùgbé mí yóò wà pẹ̀lú wọn, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.
28 Eka ogendini nongʼe ni an Jehova Nyasaye ema amiyo jo-Israel obedo maler ka kara maler mar lemo obedo e diergi nyaka chiengʼ.’”
Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa sọ Israẹli di mímọ́, nígbà tí ibi mímọ́ mi bá wà ní àárín wọn títí ayérayé.’”

< Ezekiel 37 >