< Ezekiel 13 >
1 Wach Jehova Nyasaye nobirona kama:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 “Wuod dhano, kor wach kuom jokoro mag Israel makoro sani. Wachne joma koro gik ma wigi omiyogi kama: ‘Winjuru wach Jehova Nyasaye!
“Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
3 Ma e gima Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho: Okwongʼ jokoro mofuwo maluwo mana gik ma chunjegi giwegi oparo to onge gima giseneno!
Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
4 Yaye Israel, jokoro magu chalo mana gi ondiegi modak e gunda.
Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
5 Pod ok udhi mondo udhi ulos ohinga mar Israel momukore mondo obed motegno mar kedo lweny e odiechiengʼ mar Jehova Nyasaye.
Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
6 Fweny ma gineno ok gin adier kendo gikoro weche mag miriambo. Giwacho niya, “Jehova Nyasaye osewacho,” to Jehova Nyasaye to ok oorogi, kendo pod gin gi geno ni weche ma gikorogo biro timore.
Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
7 Donge fweny ma useneno en miriambo, kendo gik mukoro gin mag wuond ka uwacho niya, “Jehova Nyasaye osewacho,” to an Jehova Nyasaye pok awacho gimoro?
Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
8 “‘Kuom mano ma e gima Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho: Nikech wecheu mag miriambo kod weche mukoro mag wuond, akwedou.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Abiro kumo jokoro maneno fweny mag miriambo kendo koro weche mag wuond. Ok ginibed e buch joga, kendo nying-gi ok nondiki e kitepe mar dhood Israel, bende ok ginidonji e piny Israel. Eka unungʼe ni An e Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto.
Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
10 “‘Nikech gimiyo joga lal, kagiwacho niya, “Kwe,” to kwe to onge, kendo nikech ka ji ogero kor ot mayom yom moro to giwire gi lowo marachar,
“‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
11 kuom mano, nyis joma wire gi lowo marachar ni obiro podho. Koth maduongʼ biro chue, kendo abiro oro pe madongo dongo, kod yamb ahiti makudho matek.
nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
12 Ka ohinga oruombore piny, to donge ji nopenju niya, “To lowo marachar mane uwirego cha koro ere?”
Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
13 “‘Kuom mano, ma e gima Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho kama: Kuom mirimba mager abiro kelo yamb ahiti, kendo kuom mirimba abiro kelo koth maduongʼ kod pe mi oketh ohingano chuth.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
14 Abiro muko ohinga ma usewiro gi lowo maracharno mi opie piny kendo mise mare ema none kodongʼ. E kinde ma ohingano noruombre piny, to un bende notieku; kendo unungʼe ni An e Jehova Nyasaye.
Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
15 Omiyo ananyis mirimba mager kuom ohinga kod joma ne owire gi lowo marachar. Abiro wachonu ni, “Ohinga oselal nono kaachiel gi jomane owire gi lowo marachar,
Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
16 ma gin jokor wach mag Israel mane okoro wach ni jo-Jerusalem kendo mane nenone fweny mag kwe, ka kwe mane ginenono to ne onge, Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto osewacho.”’
Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
17 “Koro, wuod dhano, chom wangʼi kuom nyi jou makoro weche ma giparo. Kor wach kuomgi,
“Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
18 kendo iwachnegi ni, ‘Ma e gima Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho: Okwongʼ mon mokwoyo bilo ma giritorego e ngʼut lwetgi kendo maloso kitembini ma borgi opogore opogore mar umo wiyegi mondo giket ngima ji e chandruok. Uparo ni dayienu uket ngima joga e chandruok to magu to urito maber?
wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
19 Usemiyo nyinga oyany e dier joga mondo uyudgo mogo matin mar shairi gi ngʼinjo mar makati. Kuom wuondo joga mohero miriambo, usenego jomane ok onego otho to useweyo joma ok owinjore obed mangima.
Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
20 “‘Kuom mano, ma e gima Jehova Nyasaye Manyalo Gik Moko Duto wacho: Adagi bilo muritorugo mamiyo uketo ngima ji e chandruok mana ka winy mochik gobadho, kendo abiro yudhogi oko e lwetu, mi agony joma usemako otony ka winyo.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
21 Abiro yiecho kitembini ma uumogo lela wengeu mi ares joga e lwetu, kendo ok ginichak gibed e bwo tekou. Eka unungʼe ni An e Jehova Nyasaye.
Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
22 Nikech ne uchando chuny joma kare gi miriambou, ka an to ne ok amiyogi kuyo, kendo nikech ne ujiwo joma timbegi richo mondo kik gilokre giwe timbegi maricho eka gires ngimagi,
Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
23 emomiyo ok unuchak une fweny mag miriambo kendo kata koro mag wuondo ji ok unutim. Abiro reso joga e lwetu. Kendo ka atimo kamano eka unungʼe ni An e Jehova Nyasaye.’”
nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”