< Wuok 8 >
1 Eka Jehova Nyasaye nowacho ne Musa mondo odhi ir Farao kendo onyise niya, Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: “We joga odhi mondo gilama.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Padà tọ Farao lọ kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni Olúwa wí: Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn ó bá à lè sìn mi.
2 Ka idagi weyo joga mondo odhi, to abiro kelo masira mar ogwende e pinyni duto.
Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn ó lọ, èmi yóò fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀pọ̀lọ́ kọlu gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ.
3 Ogwende nopongʼ aora Nael kendo giniwuogi ka gidhi e odi nyaka kor nindo. Bende ginipongʼ nyaka kitandani, ute jodongi kod mag jogi, kaachiel gi kuonde tedo gi dwalo makati.
Odò Naili yóò kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀pọ̀lọ́. Wọn yóò gòkè wá sí ààfin rẹ, àti yàrá rẹ ni orí ibùsùn rẹ. Wọn yóò gòkè wá sí ilé àwọn ìjòyè rẹ àti sí ara àwọn ènìyàn rẹ, àti sí ibi ìdáná rẹ, àti sí inú ìkòkò ìyẹ̀fun rẹ.
4 Ogwendego nochikre kuomi, kuom jogi kendo kuom jodongi duto.”
Àwọn ọ̀pọ̀lọ́ yóò gun ara rẹ àti ara àwọn ìjòyè rẹ, àti ara gbogbo àwọn ènìyàn rẹ.’”
5 Eka Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya; “Nyis Harun kama: ‘Rie ludhi ewi aore, sokni kod yewni, kendo ogwende nowuog maim piny Misri duto.’”
Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Sọ fún Aaroni, ‘Kí ó na ọwọ́ rẹ̀ jáde pẹ̀lú ọ̀pá sí orí àwọn odò kéékèèké àti odò ńlá, àti sí orí àwọn àbàtà kí ó sì mú àwọn ọ̀pọ̀lọ́ gòkè wá sí ilẹ̀ Ejibiti.’”
6 Omiyo Harun norieyo lwete ewi pige mag Misri, kendo ogwende nowuok mopongʼo pinyno.
Ní ìgbà náà ni Aaroni sì na ọwọ́ rẹ̀ jáde sí orí àwọn omi Ejibiti, àwọn ọ̀pọ̀lọ́ sì wá, wọ́n sì bo gbogbo ilẹ̀.
7 To ajuoke bende notimo mana kamano gi tijegi mochido kendo negimiyo ogwende owuok e piny Misri.
Ṣùgbọ́n àwọn onídán ilẹ̀ Ejibiti ṣe bákan náà pẹ̀lú agbára òkùnkùn wọn. Àwọn náà mú kí ọ̀pọ̀lọ́ gún wá sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
8 Farao noluongo Musa kod Harun mi owachonegi niya, “Kwauru Jehova Nyasaye mondo ogol ogwendegi kuoma kod joga, eka anawe jogi mondo odhi otim misengini ni Jehova Nyasaye.”
Farao ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni, ó sì sọ fún wọn pé, “Gbàdúrà sí Olúwa kí ó mú àwọn ọ̀pọ̀lọ́ wọ̀nyí kúrò lọ́dọ̀ mi àti lára àwọn ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ kí àwọn ènìyàn rẹ kí ó lọ láti rú ẹbọ sí Olúwa.”
9 Musa nodwoko Farao niya, “Aweyoni mondo iket kinde mowinjore alemnie kod jodongi gi jogi mondo in kod joodi ogol ogwende kuomu, to mago manie aora Nael to nodongʼ.”
Mose sọ fún Farao pé, “Jọ̀wọ́ sọ fún mi ìgbà ti èmi yóò gbàdúrà fún ọ àti àwọn ìjòyè rẹ àti fún àwọn ènìyàn rẹ, kí àwọn ọ̀pọ̀lọ́ wọ̀nyí bá lè lọ lọ́dọ̀ rẹ àti ní àwọn ilé yín tí wọn yóò sì wà nínú odò Naili nìkan.”
10 Farao nodwoke niya, “Obed kiny.” Musa nodwoke niya, “We obed mana kaka isewachono mondo ingʼe ni onge ngʼat machal kod Jehova Nyasaye ma Nyasachwa.
Farao wí pé, “Ni ọ̀la.” Mose sì dáhùn pé, “Yóò sì rí bí ìwọ ti sọ, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé kò sí ẹni bí Olúwa Ọlọ́run wa.
11 Ogwende nodar kawuok e uteni, e ute jodongi kod ute mag jogi; to e aora Nael ok giniwuogie.”
Àwọn ọ̀pọ̀lọ́ yóò fi ìwọ àti àwọn ilé yín àti ìjòyè rẹ, àti àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, wọn yóò sì wà nínú Naili nìkan.”
12 Bangʼ ka Musa kod Harun noseweyo Farao, Musa noywak ni Jehova Nyasaye nikech ogwende mane osekelo kuom Farao.
Lẹ́yìn tí Mose àti Aaroni tí kúrò ní iwájú Farao, Mose gbé ohùn ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ sókè sí Olúwa nípa àwọn ọ̀pọ̀lọ́ tí ó ti rán sí Farao.
13 Kendo Jehova Nyasaye notimo mana kaka Musa nokwaye. Ogwende notho ei udi kod laru gi pewe.
Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose tí béèrè. Àwọn ọ̀pọ̀lọ́ sì kú nínú ilé àti ní ìta, gbangba àti nínú oko.
14 Negichokore pidhe pidhe kendo negipongʼo piny.
Wọ́n sì kó wọn jọ ni òkìtì òkìtì gbogbo ilẹ̀ sì ń rùn.
15 Kane Farao oneno ni oseyudo thuolo, noketo chunye matek mine ok onyal winjo Musa kod Harun, mana kaka Jehova Nyasaye nowacho.
Ṣùgbọ́n ni ìgbà tí Farao rí pé ìtura dé, ó sé ọkàn rẹ̀ le kò sì fetí sí Mose àti Aaroni gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí.
16 Eka Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya, “Nyis Harun kama: ‘Rie ludhi mondo ichwadgo buru ma e lowo,’ kendo buru ma e lowo mar piny Misri duto biro lokore kikun.”
Olúwa sọ fún Mose pé, “Sọ fún Aaroni, ‘Na ọ̀pá rẹ jáde kí ó sì lu eruku ilẹ̀,’ jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti ni erùpẹ̀ ilẹ̀ yóò ti di kòkòrò-kantíkantí.” (Kòkòrò kan tí ó ní ìyẹ́ méjì tí ó ṣì ń ta ni.)
17 Negitimo mano kendo ka Harun norieyo bade mane otingʼogo luth mi ochwado buru ma e lowo, kikun nopor kuom ji kod jamni. Buru ma e piny Misri duto nolokore kikun.
Wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, nígbà tí Aaroni na ọwọ́ rẹ́ jáde pẹ̀lú ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, tí ó sì lu eruku ilẹ̀, kòkòrò-kantíkantí sì wà lára àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko wọn. Gbogbo eruku jákèjádò ilẹ̀ Ejibiti ni ó di kòkòrò-kantíkantí.
18 To ka ajuoke notemo mondo gin bende gihon kikun kuom tichgi mochido, to ne ok ginyal, kendo kikun nopor kuom ji gi jamni.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn onídán gbìdánwò láti da kòkòrò-kantíkantí pẹ̀lú agbára òkùnkùn wọn, wọn kò le è ṣé. Nígbà tí kòkòrò-kantíkantí sì wà lára àwọn ẹranko wọn,
19 Ajuoke nowacho ne Farao niya, “Ma en lwet Nyasaye!” To kata kamano chuny Farao ne tek kendo ne ok onyal winjo wach Musa gi Harun mana kaka Jehova Nyasaye nowacho.
àwọn onídán sì sọ fún Farao pé, “Ìka Ọlọ́run ni èyí.” Ṣùgbọ́n àyà Farao sì yigbì, kò sì fetísílẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
20 Eka Jehova Nyasaye nowacho ne Musa niya, “Chiew gokinyi ahinya mondo irom gi Farao ka odhi e aora Nael mondo inyise kama: Ma e gima Jehova Nyasaye wacho: We joga odhi mondo gilama.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù kí o sì ko Farao lójú bí ó ṣe ń lọ sí odò, kí o sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó bá à lè sìn Mi.
21 To ka ok iweyo joga mondo odhi, to abiro kelo lwangʼni kuomi, kuom jodongi, kuom jogi kod ei uteu duto. Ute jo-Misri biro pongʼ gi lwangʼni kata mana e lowo kama gintie bende biro pongʼ.
Bí ìwọ kò bá jẹ́ kí àwọn ènìyàn Mi kí ó lọ, èmi yóò rán ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣinṣin sí ara rẹ àti sí ara àwọn ìjòyè rẹ, àti sí ara àwọn ènìyàn rẹ̀, sí àwọn ilẹ̀ rẹ̀. Gbogbo ilé àwọn ará Ejibiti ni yóò kún fún eṣinṣin àti orí ilẹ̀ tí wọ́n wà pẹ̀lú.
22 “‘To chiengʼno ok anahon lwangʼni e piny Goshen kama joga odakie, mi iningʼe ni an Jehova Nyasaye kare anie pinyni.
“‘Ṣùgbọ́n ni ọjọ́ náà, Èmi yóò ya ilẹ̀ Goṣeni sọ́tọ̀, níbi tí àwọn ènìyàn mi ń gbé, ọ̀wọ́ eṣinṣin kankan ki yóò dé ibẹ̀. Kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, mo wà ni ilẹ̀ yìí.
23 Abiro keto pogruok e kind joga kod jogi. Hononi kiny notimre kiny.’”
Èmi yóò pààlà sáàárín àwọn ènìyàn mi àti àwọn ènìyàn rẹ. Àwọn iṣẹ́ ìyanu yìí yóò ṣẹlẹ̀ ni ọ̀la.’”
24 Kendo Jehova Nyasaye notimo mano. Kweth mag lwangʼni mopoto noolore e od Farao, kendo ei ut jodonge bende piny Misri duto ne lwangʼnigo oketho.
Olúwa sì ṣe èyí. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣinṣin sì ya wọ ààfin Farao àti sí ilé àwọn ìjòyè rẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ Ejibiti bàjẹ́ pẹ̀lú ọ̀wọ́ eṣinṣin wọ̀n-ọn-nì.
25 Eka Farao noluongo Musa kod Harun mowachonegi niya, “Dhiuru utim misango ni Nyasachu e piny Misri ka.”
Nígbà náà ni Farao ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa lọ kí ẹ sì rú ẹbọ sí Ọlọ́run yín ní ilẹ̀ yìí.”
26 To Musa nodwoko niya, “Mano ok nyal bedo kare. Misengini ma wachiwo ni Jehova Nyasaye ma Nyasachwa nyalo bedo gima kwero ni jo-Misri. To ka wachiwo misengini makwerogo e wangʼ-gi, donge gibiro goyowa gi kite?
Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Èyí ló tọ́, ẹbọ tí a ó rú sí Olúwa Ọlọ́run wa yóò jẹ́ ohun ìríra sí àwọn ará ilẹ̀ Ejibiti. Bí a bá ṣe ìrúbọ ti yóò jẹ́ ìríra ni ojú wọn ṣé wọn, ó ní sọ òkúta lù wá?
27 Nyaka wakaw wuodh ndalo adek e thim mondo wachiw misengini ni Jehova Nyasaye ma Nyasachwa mana kaka ochikowa.”
A gbọdọ̀ lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ó ti pàṣẹ fún wa.”
28 Farao nodwoko niya, “Abiro yienu mondo udhi uchiw misengini ni Jehova Nyasaye ma Nyasachu e thim to mana ka ok udhi mabor. Omiyo lamnauru.”
Nígbà náà ni Farao wí pé, “Èmi yóò jẹ́ ki ẹ lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín nínú aginjù, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ rìn jìnnà jù. Ẹ gbàdúrà fún mi.”
29 Musa nodwoko niya, “Bangʼ kinde matin ka asewuok, to abiro lamoni Jehova Nyasaye, kendo kiny lwangʼni nowe Farao, jodonge kod joge. Makmana ni Farao kik chak riambi kotamo jo-Israel dhi timo misengini ni Jehova Nyasaye.”
Mose dáhùn ó wí pé, “Bí èmi bá ti kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa, àwọn ọ̀wọ́ eṣinṣin yóò fi Farao, àwọn ìjòyè rẹ, àti àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀ ní ọ̀la ṣùgbọ́n ǹjẹ́ ìdánilójú wa pé Farao kò tún ni lo ẹ̀tàn láti má jẹ́ kí àwọn ènìyàn kí ó lọ rú ẹbọ sí Olúwa.”
30 Bangʼe Musa noweyo Farao mi olamo Jehova Nyasaye,
Nígbà náà ni Mose kúrò ni ọ̀dọ̀ Farao, ó sì gbàdúrà sí Olúwa;
31 kendo Jehova Nyasaye notimo kaka Musa nokwayo: Lwangʼni noweyo Farao kod jodonge kaachiel gi joge: Kata lwangʼni achiel ne ok odongʼ.
Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti béèrè. Àwọn ọ̀wọ́ eṣinṣin kúrò lára Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti lára àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú, eṣinṣin kan kò sì ṣẹ́kù.
32 To kata mana e kindeni Farao nomedo bedo gi tok teko kendo ne ok onyal weyo jo-Israel mondo odhi.
Ṣùgbọ́n ni àkókò yìí náà, Farao sé ọkàn rẹ le, kò sì jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ.